< Wyjścia 9 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza: Wnijdź do Faraona, a mów do niego: Tak mówi Pan, Bóg Hebrejczyków: Wypuść lud mój, aby mi służył;
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sọ fún Farao, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu sọ, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn Mí.”
2 Bo jeźli go ty nie będziesz chciał wypuścić, ale jeszcze zatrzymywać go będziesz:
Bí ìwọ bá kọ̀ láti jẹ́ kí wọn ó lọ, tí ó sì dá wọn dúró.
3 Oto, ręka Pańska będzie na bydle twojem, które jest na polu, na koniach, na osłach, na wielbłądach, na wołach i na owcach, powietrze bardzo ciężkie.
Ọwọ́ Olúwa yóò mú ààrùn búburú wá sí ara ẹran ọ̀sìn nínú oko, sí ara ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìbákasẹ, màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́ yín.
4 I uczyni Pan rozdział między trzodami Izraelskiemi, i między trzodami Egipskiemi, aby nic nie zdechło ze wszystkiego, co jest synów Izraelskich.
Ṣùgbọ́n Olúwa yóò pààlà sí àárín ẹran ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti Israẹli àti ti àwọn ara Ejibiti tí yóò fi jẹ́ pé kò sí ẹran ọ̀sìn ti ó jẹ́ ti ará Israẹli tí yóò kùú.’”
5 I postanowił Pan czas, mówiąc: Jutro uczyni Pan tę rzecz na ziemi.
Olúwa sì dá àkókò kan wí pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò ṣe èyí ni ilẹ̀ yìí.”
6 I uczynił Pan tę rzecz nazajutrz, że wyzdychały wszystkie bydła Egipskie; ale z bydła synów Izraelskich nie zdechło ani jedno.
Olúwa sí ṣe é ni ọjọ́ kejì. Gbogbo ẹran ọ̀sìn ará Ejibiti kú, ṣùgbọ́n ẹyọ kan kò kú lára ẹran ọ̀sìn àwọn Israẹli.
7 I posłał Farao, a oto, nie zdechło z bydła Izraelskiego i jedno; ale ociężało serce Faraonowe, i nie wypuścił ludu.
Farao rán àwọn ènìyàn rẹ̀ láti lọ ṣe ìwádìí, wọ́n sì rí pé ẹyọ kan kò kú lára àwọn ẹran ọ̀sìn ará Israẹli. Síbẹ̀ náà, Farao kò yí ọkàn rẹ̀ padà àti pé kò jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ.
8 Zatem rzekł Pan do Mojżesza i do Aarona: Weźmijcie pełne garści wasze popiołu z pieca, a niech go rozrzuci Mojżesz ku niebu przed oczyma Faraonowemi.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni, “Ẹ bu ẹ̀kúnwọ́ eérú gbígbóná láti inú ààrò, kí Mose kù ú sí inú afẹ́fẹ́ ni iwájú Farao.
9 I obróci się w proch po wszystkiej ziemi Egipskiej, i będzie na ludziach, i na bydle wrzodem czyniącym pryszczele, po wszystkiej ziemi Egipskiej.
Yóò sì di eruku lẹ́búlẹ́bú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, yóò sì di oówo ti ń tú pẹ̀lú ìléròrò sí ara àwọn ènìyàn àti ẹran jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti.”
10 Wzięli tedy popiołu z pieca, i stanęli przed Faraonem, i rozrzucił go Mojżesz ku niebu; i stał się wrzodem, pryszczele czyniącym na ludziach i na bydle;
Nígbà náà ni wọ́n bú eérú gbígbóná láti inú ààrò, wọ́n dúró ní iwájú Farao. Mose sì ku eérú náà sínú afẹ́fẹ́, ó sì di oówo tí ń tú pẹ̀lú ìléròrò ni ara àwọn ènìyàn àti lára ẹran.
11 I nie mogli czarownicy stać przed Mojżeszem dla wrzodu; bo był wrzód na czarownikach i na wszystkich Egipczanach.
Àwọn onídán kò le è dúró níwájú Mose nítorí oówo ti ó wà lára wọn àti ni ara gbogbo àwọn ara Ejibiti.
12 I zatwardził Pan serce Faraonowe, i nie usłuchał ich, jako był powiedział Pan Mojżeszowi.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sé ọkàn Farao le, kò sì gbọ́ ti Mose àti Aaroni, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
13 I rzekł Pan do Mojżesza: Wstań rano, a stań przed Faraonem, i mów do niego: Tak mówi Pan, Bóg Hebrejczyków: Wypuść lud mój, aby mi służył:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Dìde ni òwúrọ̀ kùtùkùtù, kí o sì tọ Farao lọ, kí o sì wí fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Heberu wí, Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn bá à lè sìn mí,
14 Bo tą razą Ja posyłam wszystkie plagi moje na serce twoje, i na sługi twoje, i na lud twój, abyś wiedział, że nie masz mnie podobnego po wszystkiej ziemi.
nítorí nígbà yìí ni èmi yóò rán àjàkálẹ̀-ààrùn ti ó ní agbára gidigidi sí ọ, sí àwọn ìjòyè rẹ àti sí àwọn ènìyàn rẹ, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé, kò sí ẹni bí èmi ni gbogbo ayé.
15 Bo teraz ściągnę rękę moję a uderzę cię i lud twój powietrzem, i wytracony będziesz z ziemi.
Ó ti yẹ kí n ti na ọwọ́ mi jáde láti kọlù ọ́ àti àwọn ènìyàn rẹ pẹ̀lú ààrùn búburú ti kò bá ti run yín kúrò ni orí ilẹ̀.
16 A zaiste, dla tegom cię zachował, abym okazał na tobie moc moję, i żeby opowiadane było imię moje po wszystkiej ziemi.
Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni èmi ṣe mú ọ dúró, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.
17 Jeszczeż się ty wynosisz przeciw ludowi memu, nie chcąc go wypuścić?
Síbẹ̀ ìwọ tún gbógun ti àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì jẹ́ kí wọn lọ.
18 Oto, Ja spuszczę o tym czasie jutro grad bardzo ciężki, jakiemu nie było podobnego w Egipcie ode dnia, którego jest założon, aż do tego czasu.
Nítorí náà, ni ìwòyí ọ̀la, Èmi yóò rán òjò o yìnyín tí irú rẹ̀ kò tí i rọ̀ rí ni Ejibiti láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ títí di àkókò yìí.
19 A tak poślij teraz, zgromadź bydło twoje, i wszystko, co masz na polu; bo na każdego człowieka, i na bydlę, które znalezione będzie na polu, a nie będzie zegnane w dom, spadnie na nie grad, i pozdychają.
Pàṣẹ nísinsin yìí láti kó ẹran ọ̀sìn yín àti ohun gbogbo ti ẹ ni ní pápá wá sí abẹ́ ààbò, nítorí òjò yìnyín yóò rọ̀ sí orí àwọn ènìyàn àti ẹran ti a kò kó wá sí abẹ́ ààbò tí wọ́n sì wà ni orí pápá, wọn yóò sì kú.’”
20 Kto się tedy uląkł słowa Pańskiego z sług Faraonowych, kazał uciekać sługom swym, i z bydłem swojem do domu;
Àwọn ti ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Olúwa lára àwọn ìjòyè Farao yára lọ láti kó àwọn ẹrú àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn wá sí abẹ́ ààbò.
21 Ale kto nie przyłożył serca swego do słowa Pańskiego, ten zostawił sługi swe i bydło swe na polu.
Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.
22 I rzekł Pan do Mojżesza: Wyciągnij rękę twą ku niebu, że będzie grad po wszystkiej ziemi Egipskiej, na ludzi, i na bydło, i na wszelakie zioła polne w ziemi Egipskiej.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”
23 A tak wyciągnął Mojżesz laskę swą ku niebu, a Pan dał gromy i grad, i zstąpił ogień na ziemię, i spuścił Pan grad na ziemię Egipską.
Nígbà tí Mose gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bùsi orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Ejibiti.
24 I był grad, i ogień zmieszany z gradem ciężkim bardzo, jakiemu nie był podobny we wszystkiej ziemi Egipskiej, jako w niej mieszkać poczęto.
Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bùsi orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì burú jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Ejibiti ti di orílẹ̀-èdè.
25 I potłukł on grad po wszystkiej ziemi Egipskiej, cokolwiek było na polu, od człowieka aż do bydlęcia; i wszystko ziele polne potłukł grad, i wszystko drzewo polne połamał;
Jákèjádò gbogbo ilẹ̀ Ejibiti ni yìnyín ti pa gbogbo ohun tí ó wà ni orí pápá; ènìyàn àti ẹranko, ó wò gbogbo ohun ọ̀gbìn lulẹ̀ ó sì fa gbogbo igi ya pẹ̀lú.
26 Tylko w ziemi Gosen, gdzie synowie Izraelscy mieszkali, nie było gradu.
Ilẹ̀ Goṣeni ni ibi ti àwọn Israẹli wà nìkan ni òjò yìnyín náà kò rọ̀ dé.
27 Posłał tedy Farao, a wezwał Mojżesza i Aarona, mówiąc do nich: Zgrzeszyłem i tym razem; Pan jest sprawiedliwy, ale ja i lud mój niezbożniśmy.
Nígbà náà ni Farao pe Mose àti Aaroni sì ọ̀dọ́ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Èmi ti ṣẹ̀ ní àkókò yìí; Olúwa jẹ́ olódodo ṣùgbọ́n èmi àti àwọn ènìyàn mi ni aláìṣòdodo.
28 Módlcież się Panu, ( boć dosyć jest, ) aby przestały gromy Boże i grad; a wypuszczę was, i nie będziecie tu mieszkać dalej.
Èyí ti òjò yìnyín àti àrá rọ̀ yìí tó gẹ́ẹ́, gbàdúrà sí Olúwa kí ó dáwọ́ rẹ̀ dúró. Èmi yóò jẹ́ kí ẹ lọ, n kò tún ni dá a yín dúró mọ́.”
29 I rzekł Mojżesz do niego: Gdy wynijdę z miasta, wyciągnę ręce swe do Pana, a gromy ustaną, i grad nie będzie więcej, abyś wiedział, że Pańska jest ziemia;
Mose dá a lóhùn pé, “Bí mo bá ti jáde kúrò ní àárín ìlú, èmi yóò gbé ọwọ́ mi sókè sí Olúwa, sísán àrá yóò dáwọ́ dúró, yìnyín kò sì ni rọ̀ mọ́, kí ìwọ kí ó lè mọ̀ pé Olúwa ni ó ni ilẹ̀.
30 Ale ty i słudzy twoi, wiem, że się jeszcze nie boicie oblicza Pana Boga.
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
31 Len tedy i jęczmień potłuczony jest; bo jęczmień był niedostały, a len podrastał.
(A sì lu ọ̀gbọ̀ àti ọkà barle bolẹ̀; nítorí barle wà ní ìpẹ́, ọ̀gbọ̀ sì rudi.
32 Pszenica jednak i żyto potłuczone nie były; bo późne były.
Alikama àti ọkà ni a kò lù bolẹ̀, nítorí tí wọ́n kò tí ì dàgbà.)
33 Wyszedłszy tedy Mojżesz od Faraona z miasta, wyciągnął ręce swe do Pana; i przestały gromy i grad, a deszcz nie padał na ziemię.
Nígbà náà ni Mose jáde kúrò ni iwájú Farao, ó kúrò ni àárín ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
34 A widząc Farao, że przestał deszcz, i grad, i gromy, przyczynił grzechu, a obciążył serce swe, sam i słudzy jego.
Nígbà tí Farao rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣì sé àyà wọn le.
35 I zatwardziało serce Faraonowe, i nie wypuścił synów Izraelskich, jako był powiedział Pan przez Mojżesza.
Àyà Farao sì le, bẹ́ẹ̀ ni kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mose.

< Wyjścia 9 >