< Wyjścia 31 >

1 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa wí fún Mose pé,
2 Otom wezwał z imienia Besaleela, syna Urowego, syna Churowego z pokolenia Judy.
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 I napełniłem go Duchem Bożym, mądrością, i rozumem, i umiejętnością we wszelakiem rzemiośle.
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 Ku dowcipnemu wymyślaniu, cokolwiek może być urobione ze złota, i z srebra, i z miedzi.
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 Do rzezania kamienia na osadzenie, i na wyrobienie drzewa ku wystawieniu każdej roboty.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 A oto, Ja przydałem mu Acholijaba, syna Achysamechowego z pokolenia Dan, a w serce każdego dowcipnego dałem mądrość, aby zrobili wszystko com ci przykazał.
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 Namiot zgromadzenia, i skrzynię świadectwa, i ubłagalnią, która ma być nad nią, i wszystkie naczynia namiotu.
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 Stół także i naczynia jego, i świecznik czysty ze wszystkiem naczyniem jego, i ołtarz do kadzenia.
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 Także ołtarz do całopalenia ze wszystkiem naczyniem jego, i wannę ze stolcem jej.
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 Także szaty do służby, i szaty święte Aaronowi kapłanowi, i szaty synom jego ku sprawowaniu kapłaństwa.
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 I olejek pomazywania, i kadzenie wonne do świątnicy; według wszystkiego, jakom ci rozkazał, uczynią.
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa wí fún Mose pé,
13 Ty też powiedz synom Izraelskim, mówiąc: Przecię sabbatów moich przestrzegać będziecie; bo ten znak jest między mną i między wami w narodziech waszych, abyście wiedzieli, żem Ja Pan, który was poświęcam.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 Przetoż przestrzegajcie sabbatu, święty bowiem jest wam. Kto by go zgwałcił, śmiercią umrze; bo każdy, coby weń robotę odprawował, wytracona będzie dusza jego, z pośrodku ludu swego.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Przez sześć dni odprawowana będzie robota; ale w dzień siódmy sabbat jest, odpocznienie święte Panu; każdy, kto by robił robotę w dzień sabbatu, śmiercią umrze.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 Przetoż będą strzec synowie Izraelscy sabbatu, zachowując sabbat w narodziech swych ustawą wieczną.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Między mną i między syny Izraelskimi znakiem jest wiecznym; bo w sześciu dniach uczynił Pan niebo i ziemię, a dnia siódmego przestał i odpoczął.
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 I dał Pan Mojżeszowi dokonawszy mowy z nim na górze Synaj dwie tablice świadectwa, tablice kamienne, pisane palcem Bożym.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

< Wyjścia 31 >