< Wyjścia 30 >

1 Uczynisz też ołtarz dla kadzenia; z drzewa sytym uczynisz go.
“Ìwọ yóò sì ṣe pẹpẹ igi kasia kan; máa jó tùràrí lórí rẹ̀.
2 Na łokieć wzdłuż, i na łokieć wszerz, czworograniasty będzie, a na dwa łokcie wzwyż; z niego wychodzić będą rogi jego.
Kí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé, kí ó jẹ́ ìdajì mita ní gígùn, ìdajì mita ní fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga rẹ̀—kí ìwo rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
3 A powleczesz go szczerem złotem, wierzch jego i ściany jego w około, i rogi jego. Uczynisz też koronę złotą około niego.
Ìwọ yóò sì bo òkè rẹ̀, gbogbo ìhà rẹ̀ àti ìwo rẹ̀ pẹ̀lú u kìkì wúrà, ìwọ yóò sì ṣe wúrà gbà á yíká.
4 I dwa kolce złote uczynisz też pod koroną we dwu kątach jego, po obu stronach jego, a przez nie przewleczesz drążki, aby noszony był na nich.
Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì fún pẹpẹ náà níṣàlẹ̀ ìgbátí méjèèjì ní òdìkejì ìhà rẹ̀—láti gbá àwọn òpó rẹ̀ mú, láti lè máa fi gbé e.
5 A uczynisz drążki one z drzewa sytym, i powleczesz je złotem.
Ìwọ yóò sì ṣe òpó igi kasia, ìwọ yóò sì bọ́ wọ́n pẹ̀lú wúrà.
6 I postawisz go przed zasłoną, za którą jest skrzynia świadectwa przed ubłagalnią, która jest nad świadectwem, gdzie się z tobą schodzić będę.
Ìwọ yóò gbé pẹpẹ náà sí iwájú aṣọ ìkélé, èyí tí ó wà níwájú àpótí ẹ̀rí níwájú ìtẹ́ àánú èyí tí ó wà lórí àpótí ẹ̀rí níbi ti èmi yóò ti máa bá ọ pàdé.
7 A będzie kadził na nim Aaron kadzeniem z wonnych rzeczy na każdy poranek; przygotowawszy lampy, będzie kadził.
“Aaroni yóò sì máa jó tùràrí dídùn lórí pẹpẹ náà ní àràárọ̀, nígbà tí ó tún àwọn fìtílà náà ṣe.
8 Także gdy rozpali Aaron lampy między dwoma wieczorami, kadzić będzie kadzeniem ustawicznem przed Panem w narodziech waszych.
Aaroni yóò sì tún jó tùràrí nígbà tí ó bá tan fìtílà ní àṣálẹ́, bẹ́ẹ̀ ní tùràrí yóò máa jó títí láé níwájú Olúwa fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
9 Nie włożycie nań kadzidła obcego, ani całopalenia, ani ofiary suchej; ani ofiary mokrej ofiarować będziecie na nim.
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mú àjèjì tùràrí wá sórí pẹpẹ yìí tàbí ẹbọ sísun kankan tàbí ọrẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ da ẹbọ ohun mímu sórí i rẹ̀.
10 Tylko wykona oczyszczenie Aaron nad rogami jego raz w rok; przez krew ofiary za grzech, w dzień oczyszczenia, raz w rok oczyszczenie odprawi na nim w narodziech waszych; bo to rzecz najświętsza Panu.
Aaroni yóò sì máa ṣe ètùtù sórí àwọn ìwo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan lọ́dún. Òun yóò sì máa ṣe ètùtù ọdọọdún yìí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ètùtù fún ìran tó ń bọ̀. Mímọ́ jùlọ ni sí Olúwa.”
11 Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
12 Gdy zbierzesz główną sumę synów Izraelskich, z tych, którzy mają iść w liczbę, da każdy okup za duszę swą Panu, gdy je liczyć będziesz, aby nie przyszła na nie plaga, gdy zliczeni będą.
“Nígbà tí ìwọ bá ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti mọ iye wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gbọdọ̀ mú ìràpadà ọkàn rẹ̀ wá fún Olúwa ní ìgbà tí o bá ka iye wọn. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn kì yóò súnmọ́ wọn, nígbà tí o bá ń ka iye wọn.
13 To dawać będą: każdy, który idzie w liczbę, da pół sykla według sykla świątnicy dwadzieścia pieniędzy sykiel waży; pół sykla będzie podarek Panu.
Olúkúlùkù ẹrù tí ó bá kọjá lọ sọ́dọ̀ àwọn tí a ti kà yóò san ìdajì ṣékélì, gẹ́gẹ́ bí ṣékélì ibi mímọ́, èyí tí ó wọn ogún gera. Ìdajì ṣékélì yìí ní ọrẹ fún Olúwa.
14 Ktokolwiek idzie w liczbę ode dwudziestu lat i wyżej, odda podarek Panu.
Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá sínú àwọn tí a kà láti ẹni ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni yóò fi ọrẹ fún Olúwa.
15 Bogaty nie da więcej, a ubogi nie da mniej nad pół sykla, gdy będą dawać ofiarę Panu, dla oczyszczenia dusz swoich.
Àwọn olówó kì yóò san ju ìdajì ṣékélì lọ, àwọn tálákà kò sì gbọdọ̀ dín ní ìdajì ṣékélì nígbà tí ẹ̀yin bá mú ọrẹ wá fún Olúwa láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.
16 A wybrawszy pieniądze oczyszczenia od synów Izraelskich, dasz je na potrzeby namiotu zgromadzenia, co będzie synom Izraelskim na pamiątkę przed Panem, ku oczyszczeniu dusz waszych.
Ìwọ yóò sì gba owó ètùtù náà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ yóò sì fi lélẹ̀ fún ìsìn àgọ́ àjọ. Yóò jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli níwájú Olúwa, láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.”
17 Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
18 Uczynisz też wannę miedzianą, i stolec jej miedziany do umywania, a postawisz ją między namiotem zgromadzenia, i między ołtarzem, i nalejesz w nią wody.
“Ìwọ yóò sì ṣe agbada idẹ kan, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ idẹ, fún wíwẹ̀. Ìwọ yóò sì gbé e sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì pọn omi sínú rẹ̀.
19 I umywać będą Aaron i synowie jego z niej ręce swoje i nogi swoje.
Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn pẹ̀lú omi tí ó wà nínú rẹ̀.
20 Gdy wchodzić będą do namiotu zgromadzenia, umywać się będą wodą, aby nie pomarli; także gdyby mieli przystępować do ołtarza, aby służyli, i zapalili ofiarę ognistą Panu.
Nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ inú àgọ́ àjọ, wọ́n yóò wẹ̀ pẹ̀lú omi nítorí kí wọ́n má ba à kú. Bákan náà, nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi pẹpẹ láti ṣe ìsìn, láti mú ẹbọ ti a fi iná sun wá fún Olúwa,
21 I będą umywali ręce swoje i nogi swoje, aby nie pomarli; i będzie im to ustawą wieczną, jemu i nasieniu jego, w rodzaju ich.
wọn yóò sì wẹ ọwọ́ wọn àti ẹsẹ̀ wọn, nítorí kí wọn máa ba à kú. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún Aaroni àti irú àwọn ọmọ rẹ̀ fún ìrandíran wọn.”
22 Rzekł jeszcze Pan do Mojżesza, mówiąc:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Ty też weźmij sobie wonnych rzeczy przednich: Myrry co najczystszej pięćset łutów, a cynamonu wonnego połowę tego, to jest, dwieście i pięćdziesiąt łutów, i tatarskiego ziela dwieście i pięćdziesiąt;
“Ìwọ yóò mú ààyò tùràrí olóòórùn sí ọ̀dọ̀ rẹ; ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì (kilogiramu mẹ́fà) tí òjìá ṣíṣàn, ìdajì bí ó bá yẹ àádọ́ta lé nígba ṣékélì tí kinamoni dídùn, àti kénì dídùn àádọ́ta lé nígba ṣékélì,
24 Kasyi też pięćset łutów według sykla świątnicy, i oliwy z drzew oliwnych hyn.
kasia ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì gbogbo rẹ̀ ní ìlànà ṣékélì ibi mímọ́ àti hínì òróró olifi kan (lita mẹ́rin).
25 I uczynisz z tego olejek pomazywania świętego, maść najwyborniejszą, robotą aptekarską: olejek to pomazywania świętego będzie.
Ṣe ìwọ̀nyí ní òróró mímọ́ ìkunra, tí a pò gẹ́gẹ́ bí olùṣe òórùn dídùn tì í ṣe. Yóò jẹ òróró mímọ́ ìtasórí.
26 I pomażesz nim namiot zgromadzenia, i skrzynię świadectwa.
Ìwọ yóò sì lò ó láti ya àgọ́ sí mímọ́ àti àpótí ẹ̀rí náà,
27 Także stół i wszystkie naczynia jego, i świecznik, i naczynia jego, i ołtarz, na którym kadzą;
tábìlì àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà àti ohun èlò rẹ̀, àti pẹpẹ tùràrí,
28 Ołtarz też do całopalenia ze wszystkiem naczyniem jego, i wannę z stolcem jej.
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, àti agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
29 A poświęcisz je, aby najświętsze były; cokolwiek się ich dotknie, poświęcone będzie.
Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn wọn yóò di mímọ́.
30 Aarona też, i syny jego pomażesz, i poświęcisz je, aby mi sprawowali urząd kapłański.
“Ìwọ yóò sì ta òróró sí orí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè sìn mí bí àlùfáà.
31 A synom Izraelskim tak powiesz, mówiąc: Olejek pomazywania świętego mnie będzie świętym w narodziech waszych;
Ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Èyí ni yóò ṣe òróró mímọ́ ìtasórí mi fún ìrandíran tó ń bọ̀.
32 Ciało człowiecze nie będzie nim mazane, a według złożenia jego nie uczynicie temu podobnego: bo święty jest, i święty wam będzie.
Má ṣe dà á sí ara ènìyàn kí o má sì ṣe ṣe òróró kankan ni irú rẹ̀. Mímọ́ ni, ẹ̀yin sì gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
33 Ktobykolwiek uczynił taką maść, a namazałby nią kogo obcego, wytracony będzie z ludu swego.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá po irú rẹ̀, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá fi sára àlejò yàtọ̀ sí àlùfáà, a ó gé e kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
34 I rzekł Pan do Mojżesza: Weźmij sobie rzeczy wonnych, balsamu, i onychy, i galbanu wonnego, i kadzidła czystego, wszystkiego w równej wadze;
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú tùràrí olóòórùn dídùn sọ́dọ̀ rẹ, onika, àti galibanumu àti kìkì tùràrí dáradára, òsùwọ̀n kan fún gbogbo rẹ,
35 A uczynisz z tego kadzenia wonne robotą aptekarską; to zmieszanie czyste i święte będzie.
ṣe tùràrí olóòórùn dídùn tí a pò, iṣẹ́ àwọn olóòórùn, tí ó ní iyọ̀, ó dára, ó sì jẹ́ mímọ́.
36 A utłukłszy to miałko, kłaść będziesz z niego przed świadectwem w namiocie zgromadzenia, gdzie się z tobą schodzić będę; najświętsze to będzie.
Ìwọ yóò sì lọ díẹ̀ nínú rẹ̀ kúnná, ìwọ yóò sì gbé e síwájú ẹ̀rí ní àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti pàdé yín. Yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ fún yín.
37 Kadzenia też, które byś czynił według złożenia tego, nie uczynicie sobie; toć będzie świętą rzeczą dla Pana.
Ẹ má ṣe ṣe tùràrí kankan ní irú èyí fúnra yín; ẹ kà á ní mímọ́ sí Olúwa.
38 Ktobykolwiek uczynił co podobnego, aby woniał z niego, wytracony będzie z ludu swego.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe irú rẹ̀ láti máa gbádùn òórùn rẹ̀, òun ni a ó gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”

< Wyjścia 30 >