< Estery 7 >
1 A tak przyszedł król i Haman na ucztę do Estery królowej.
Ọba àti Hamani sì lọ sí àpèjẹ pẹ̀lú Esteri ayaba,
2 I rzekł zasię król do Estery drugiego dnia, napiwszy się wina: Cóż za prośba twoja, królowo Ester? a będzieć dano; co za żądość twoja? Choćbyś też i o połowę królestwa prosiła, stanieć się.
bí wọ́n sì ṣe ń mu wáìnì ní ọjọ́ kejì yìí, ọba sì tún béèrè pé, “Esteri ayaba, kí ni ẹ̀bẹ̀ rẹ? A ó sì fi fún ọ. Kí ni ìbéèrè rẹ? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ ìdajì ìjọba à mi, n ó fi fún ọ.”
3 Tedy odpowiedziała królowa Ester, i rzekła: Jeźlim znalazła łaskę przed oczyma twemi, o królu! a jeźli się królowi podoba, niech mi będzie darowany żywot mój na prośbę moję, i naród mój na żądość moję.
Nígbà náà ni ayaba Esteri dáhùn, “Bí èmi bá rí ojúrere rẹ, ìwọ ọba, bí ó bá sì tẹ́ ọláńlá à rẹ lọ́rùn, fún mi ní ẹ̀mí mi, èyí ni ẹ̀bẹ̀ mi. Kí o sì pa àwọn ènìyàn mi mọ́—èyí ni ìbéèrè mi.
4 Albowiemeśmy zaprzedani, ja i naród mój, abyśmy byli wygładzeni, wymordowani i wytraceni. Gdybyśmy za niewolników i niewolnice sprzedani byli, milczałabym, choćby i tak ten nieprzyjaciel nasz nie mógł nagrodzić tej szkody królowi.
Nítorí a ti ta èmi àti àwọn ènìyàn mi fún àwọn tí yóò pa wá run, à ti ṣe ìdájọ́ wa fún pípa àti píparẹ́. Bí a bá tilẹ̀ tà wá bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ǹ bá dákẹ́, nítorí irú ìpọ́njú bẹ́ẹ̀ kò tó èyí tí à ń yọ ọba lẹ́nu sí.”
5 Tedy odpowiedział król Aswerus, i rzekł do Estery królowej: Któż to jest? a gdzie ten jest, którego serce tak nadęte jest, aby to śmiał uczynić?
Ọba Ahaswerusi bi Esteri ayaba léèrè pé, “Ta a ni ẹni náà? Níbo ni ẹni náà wà tí kò bẹ̀rù láti ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀?”
6 Irzekła Ester: Mąż przeciwnik, a nieprzyjaciel najgorszy jest ten Haman. I strwożył się Haman przed królem i królową.
Esteri sọ wí pé, “Alátakò àti ọ̀tá náà ni Hamani aláìníláárí yìí.” Nígbà náà ni Hamani wárìrì níwájú ọba àti ayaba.
7 Tedy król wstał w popędliwości swojej od onej uczty, a szedł do ogrodu przy pałacu; ale Haman został, aby prosił o żywot swój Estery królowej; bo wiedział, że mu zgotowane było nieszczęście od króla.
Ọba sì dìde pẹ̀lú ìbínú, ó fi wáìnì sílẹ̀ ó sì jáde lọ sí àgbàlá ààfin. Ṣùgbọ́n nígbà tí Hamani, ti rí i dájú pé ọba ti pinnu láti pa òun, ó dúró lẹ́yìn láti bẹ Esteri ayaba nítorí ẹ̀mí rẹ̀.
8 Potem król wrócił się z ogrodu, który był przy pałacu, do domu, gdzie pił wino; a Haman upadł był na łoże, na którem siedziała Tedy rzekł król: Izali jeszcze i gwałt chce uczynić królowej u mnie w domu? A gdy te słowa wyszły z ust królewskich, zaraz twarz Hamanową nakryto.
Bí ọba ṣe padà dé láti àgbàlá ààfin wá sí gbọ̀ngàn àsè náà, Hamani ṣubú sórí àga tí Esteri ayaba fẹ̀yìn tì. Ọba sì pariwo pé, “Yóò ha tún tẹ́ ayaba níbí yìí, nínú ilé, ní ojú mi bí?” Ní kété tí ọba sọ ọ̀rọ̀ yìí jáde, wọ́n da aṣọ bo Hamani lójú.
9 Wtem rzekł Harbona, jeden z komorników, przed królem: Oto jeszcze szubienica, którą był zgotował Haman na Mardocheusza, który się starał o dobre królewskie, stoi przy domu Hamanowym wzwyż na pięćdziesiąt łokci. I rzekł król: Powieście go na niej.
Nígbà náà Harbona ọ̀kan nínú àwọn ìwẹ̀fà tó ń dúró níwájú ọba, sọ wí pé, “Igi tí ó ga tó ìwọ̀n ẹsẹ̀ bàtà marunlélaadọrin ni Hamani ti rì sí ẹ̀gbẹ́ ilé e rẹ̀. Ó ṣe é fún Mordekai, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti ṣe ìrànlọ́wọ́ fún ọba.” Ọba wí pé, ẹ so ó rọ̀ sórí i rẹ́!
10 I powieszono Hamana na onej szubienicy, którą był zgotował Mardocheuszowi. A tak uspokoił się gniew królewski.
Wọ́n sì so Hamani sórí igi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún Mordekai, ìbínú ọba sì rọ̀.