< Kaznodziei 2 >
1 Rzekłem ja do serca mego: Nuże teraz doświadczę cię w weselu, używajże dobrych rzeczy; ale i toć marność.
Mo rò nínú ọkàn mi, “Wá nísinsin yìí, èmi yóò sì dán ọ wò pẹ̀lú ìgbádùn láti ṣe àwárí ohun tí ó dára.” Ṣùgbọ́n eléyìí náà jásí asán.
2 Śmiechowi rzekłem: Szalejesz, a weselu: Cóż to czynisz?
“Mo wí fún ẹ̀rín pé òmùgọ̀ ni. Àti fún ìre-ayọ̀ pé kí ni ó ń ṣe?”
3 Przemyślałem w sercu swem, abym pozwolił wina ciału memu, (serce jednak swoje sprawując mądrością) i abym się trzymał głupstwa dotąd, ażbym obaczył, coby lepszego było synom ludzkim czynić pod niebem, przez wszystkie dni żywota ich.
Mo tiraka láti dun ara mi nínú pẹ̀lú ọtí wáìnì, àti láti fi ọwọ́ lé òmùgọ̀—ọkàn mi sì ń tọ́ mi pẹ̀lú ọgbọ́n. Mo fẹ́ wo ohun tí ó yẹ ní ṣíṣe fún ènìyàn ní abẹ́ ọ̀run ní ìwọ̀nba ọjọ́ ayé rẹ̀.
4 Wielkiem sprawy wykonał; pobudowałem sobie domy, nasadziłem sobie winnic;
Mo ṣe àwọn iṣẹ́ ńlá ńlá. Mo kọ́ ilé púpọ̀ fún ara mi, mo sì gbin ọgbà àjàrà púpọ̀.
5 Naczyniłem sobie ogrodów, i sadów, i naszczepiłem w nich drzew wszelakiego owocu;
Mo ṣe ọgbà àti àgbàlá, mo sì gbin onírúurú igi eléso sí inú wọn.
6 Pobudowałem sobie stawy ku odwilżaniu przez nie lasu, w którym rośnie drzewo;
Mo gbẹ́ adágún láti máa bu omi rin àwọn igi tí ó ń hù jáde nínú ọgbà.
7 Nabyłem sobie sług i dziewek, i miałem czeladź w domu moim; do tego i stada wołów, i wielkie trzody owiec miałem nad wszystkich, którzy byli przedemną w Jeruzalemie.
Mo ra àwọn ẹrú ọkùnrin àti àwọn ẹrú obìnrin, mo sì tún ní àwọn ẹrú mìíràn tí a bí sí ilé mi. Mo sì tún ní ẹran ọ̀sìn ju ẹnikẹ́ni ní Jerusalẹmu lọ.
8 Zgromadziłem też sobie srebro i złoto, i klejnoty od królów i krain. Sporządziłem też sobie śpiewaków i śpiewaczki, i inne rozkosze synów ludzkich, i muzyczne naczynia rozliczne.
Mo kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara mi àti àwọn ohun ìṣúra ti ọba àti ìgbèríko. Mo ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin, àti dídùn inú ọmọ ènìyàn, aya àti obìnrin púpọ̀.
9 A tak stałem się wielkim i możniejszym nad wszystkich, którzy byli przede mną w Jeruzalemie; nadto mądrość moja zostawała przy mnie.
Mo di ẹni ńlá ju ẹnikẹ́ni tí ó wà ní Jerusalẹmu ṣáájú mi. Nínú gbogbo èyí, ọgbọ́n mi kò fi mí sílẹ̀.
10 A wszystkiego, czego pożądały oczy moje, nie zabraniałem im, anim odmawiał sercu memu żadnego wesela; ale serce moje weseliło się ze wszystkiej pracy mojej. A toć był dział mój ze wszystkiej pracy mojej.
Èmi kò jẹ́ kí ojú mi ṣe aláìrí ohun tí ó bá ń fẹ́. N kò sì jẹ́ kí ọkàn mi ó ṣe aláìní ìgbádùn. Ọkàn mi yọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ mi, èyí sì ni èrè fún gbogbo wàhálà mi.
11 Lecz gdym się obejrzał na wszystkie sprawy swoje, które czyniły ręce moje, i na prace, którem podejmował pracując: oto wszystko marność, i utrapienie ducha, i niemasz nic pożytecznego pod słońcem.
Síbẹ̀, nígbà tí mo wo gbogbo ohun tí ọwọ́ mi ti ṣe àti ohun tí mo ti ṣe wàhálà láti ní: gbogbo rẹ̀, asán ni. Ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́, kò sí èrè kan ní abẹ́ oòrùn; ọgbọ́n àti òmùgọ̀, asán ni.
12 Przetoż obróciłem się do tego, abym się przypatrywał mądrośći, i szaleństwu, i głupstwu; (bo cóżby człowiek czynił ten, który nastanie po królu? to, co już inni czynili.)
Nígbà náà ni mo tún bẹ̀rẹ̀ sí ọgbọ́n, àti ìsínwín àti àìgbọ́n kí ni ọba tí ó jẹ lẹ́yìn tí ọba kan kú le è ṣe ju èyí tí ọba ìṣáájú ti ṣe lọ.
13 I obaczyłem, iż jest pożyteczniejsza mądrość niżeli głupstwo, tak jako jest pożyteczniejsza światłość, niżeli ciemność.
Mo sì ri wí pé ọgbọ́n dára ju òmùgọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ ti dára ju òkùnkùn lọ.
14 Mądry ma oczy w głowie swej, ale głupi w ciemnościach chodzi; a wszakżem poznał, że jednakie przygody na wszystkich przychdzą.
Ojú ọlọ́gbọ́n ń bẹ lágbárí rẹ̀, nígbà tí aṣiwèrè ń rìn nínú òkùnkùn, ṣùgbọ́n mo wá padà mọ̀ wí pé ìpín kan náà ni ó ń dúró de ìsọ̀rí àwọn ènìyàn méjèèjì.
15 Dlategom rzekł w sercu mojem: Mali mi się tak dziać, jako się głupiemu dzieje, przeczżem go ja tedy mądrośćią przeszedł? Przetożem rzekł w sercu mojem: I toć jest marność.
Nígbà náà ni mo rò nínú ọkàn wí pé, “Irú ìpín tí òmùgọ̀ ní yóò bá èmi náà pẹ̀lú kí wá ni ohun tí mo jẹ ní èrè nípa ọgbọ́n?” Mo sọ nínú ọkàn mi wí pé, “Asán ni eléyìí pẹ̀lú.”
16 Albowiem nie na wieki będzie pamiątki mądrego i głupiego, dlatego, iż to, co teraz jest, we dni przyszłe wszystkiego zapomną; a jako umiera mądry, tak i głupi.
Nítorí pé ọlọ́gbọ́n ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí i òmùgọ̀, a kì yóò rántí rẹ̀ fún ìgbà pípẹ́; gbogbo wọn ni yóò di ohun ìgbàgbé ní ọjọ́ tó ń bọ̀. Ikú tí ó pa aṣiwèrè náà ni yóò pa ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
17 Przetoż mi żywot omierzł; bo mi się nie podoba żadna rzecz, która się dzieje pod słońcem; albowiem wszystkie są marnością, i utrapieniem ducha.
Nítorí náà, mo kórìíra ìwàláàyè, nítorí pé iṣẹ́ tí wọn ń ṣe ní abẹ́ oòrùn ti mú ìdààmú bá mi. Gbogbo rẹ̀ asán ni, ó dàbí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
18 Nawet omierzła mi i wszystka praca moja, którąm podejmował pod słońcem, przeto, że ją zostawić muszę człowiekowi, który nastanie po mnie.
Mo kórìíra gbogbo ohun tí mo ti ṣiṣẹ́ fún ní abẹ́ oòrùn, nítorí pé mo ní láti fi wọ́n sílẹ̀ fún ẹni tí ó wà lẹ́yìn mi ni.
19 A kto wie, będzieli mądrym, czyli głupim? a wszakże będzie panował nad wszystką pracą moją, którąm prowadził, i w którejm był mądry pod słońcem. Aleć i to marność.
Ta ni ó wá mọ̀ bóyá ọlọ́gbọ́n ènìyàn ni yóò jẹ́ tàbí aṣiwèrè? Síbẹ̀ yóò ní láti ṣe àkóso lórí gbogbo iṣẹ́ tí mo tí ṣe yìí pẹ̀lú.
20 I przypadłem na to, abym zwątpił w sercu mojem o wszystkiej pracy, którąm się mądrze bawił pod słońcem.
Nítorí náà, ọkàn mi bẹ̀rẹ̀ sí ní kábámọ̀ lórí gbogbo àìsimi iṣẹ́ ṣíṣe mi ní abẹ́ oòrùn.
21 Nie jeden zaiste człowiek pracuje mądrze, i umiejętnie, i sprawiedliwie; a wszakże to innemu, który nie robił na to, za dział zostawi. I toć marność i wielka bieda.
Nítorí pé ènìyàn le è ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní abẹ́ oòrùn, tí ó sì ti kọ́ ṣe iṣẹ́ fúnra rẹ̀. Asán ni eléyìí pẹ̀lú àti àdánù ńlá.
22 Bo cóż ma człowiek ze wszystkiej pracy swej, i z usiłowania serca swego, które podejmuje pod słońcem?
Kí ni ohun tí ènìyàn rí gbà fún gbogbo wàhálà àti ìpọ́njú tí ó fi ṣiṣẹ́ lábẹ́ oòrùn?
23 Ponieważ wszystkie dni jego są bolesne, a zabawa jego jest frasunek, tak iż i w nocy nie odpoczywa serce jego. I toć jest marność.
Gbogbo ọjọ́ rẹ, iṣẹ́ rẹ kún fún ìrora, àti ìbànújẹ́, kódà ọkàn rẹ̀ kì í ní ìsinmi ní alẹ́. Asán ni eléyìí pẹ̀lú.
24 Izali nie lepsza człowiekowi, aby jadł i pił, i dobrze uczynił duszy swojej z pracy swojej? alemci widział, że i to z ręki Bożej pochodzi.
Ènìyàn kò le è ṣe ohunkóhun tí ó dára jù pé kí ó jẹ kí ó sì mu, kí ó sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú iṣẹ́ rẹ̀. Mo rí wí pé eléyìí pẹ̀lú wá láti ọwọ́ Ọlọ́run.
25 Albowiem któżby słuszniej miał jeść, i pożywać tego nad mię?
Nítorí wí pé láìsí òun, ta ni ó le jẹ tàbí kí ó mọ adùn?
26 Bo człowiekowi, który mu się podoba, daje mądrość, umiejętność, i wesele; ale grzesznikowi daje frasunek, aby zbierał i zgromadzał, coby zostawił temu, który się podoba Bogu. I toć jest marność, a utrapienie ducha.
Fún ẹni tí ó bá tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn ni Ọlọ́run yóò fún ní ọgbọ́n, ìmọ̀ àti ìdùnnú, ṣùgbọ́n fún ẹni dẹ́ṣẹ̀, Ó fún un ní iṣẹ́ láti ṣà àti láti kó ohun ìní pamọ́ kí ó sì fi fún ẹni tí ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn. Eléyìí pẹ̀lú, asán ni, ó dàbí ẹni gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́.