< Kaznodziei 12 >

1 Pamiętaj tedy na stworzyciela swego we dni młodości twojej, pierwej niżeli nastaną złe dni, i nadejdą lata, o których rzeczesz: Nie podobają mi się.
Rántí Ẹlẹ́dàá rẹ ní ọjọ́ èwe rẹ, nígbà tí ọjọ́ ibi kò tí ì dé àti tí ọdún kò tí ì ní súnmọ́ etílé, nígbà tí ìwọ yóò wí pé, “Èmi kò ní ìdùnnú nínú wọn,”
2 Pierwej niż się zaćmi słońce, i światło, i miesiąc i gwiazdy, a nawrócą się obłoki po dżdżu.
kí oòrùn àti ìmọ́lẹ̀ àti òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tó ṣókùnkùn, àti kí àwọsánmọ̀ tó padà lẹ́yìn òjò;
3 W dzień, którego się poruszą stróże domowi, i zachwieją się mężowie duży i ustaną melący, przeto, iż ich mało będzie, i zaćmią się wyglądający oknami;
nígbà tí olùṣọ́ ilé yóò wárìrì tí àwọn ọkùnrin alágbára yóò tẹríba, nígbà tí àwọn tí ó ń lọ dákẹ́ nítorí pé wọn kò pọ̀, tí àwọn tí ń wo òde láti ojú fèrèsé yóò ṣókùnkùn;
4 I zawrą się drzwi z dworu z słabym głosem mełcia; i powstanie na głos ptaszy, i ustaną wszystkie córki śpiewające.
nígbà tí ìlẹ̀kùn sí ìgboro yóò tì tí ariwo ọlọ yóò dákẹ́; nígbà tí àwọn ènìyàn yóò dìde sí ariwo àwọn ẹyẹ ṣùgbọ́n gbogbo orin wọn yóò máa lọ ilẹ̀.
5 Nawet i wysokiego miejsca bać się będą, i będą się lękać na drodze, gdy zakwitnie migdałowe drzewo, także i szarańcza będzie mu ciężka, i żądza go ominie; bo człowiek idzie do domu wiecznego, a płaczący po ulicach chodzić będą,
Nígbà tí ènìyàn yóò bẹ̀rù ibi gíga àti ti ìfarapa ní ìgboro; nígbà tí igi almondi yóò tanná àti tí ẹlẹ́ǹgà yóò wọ́ ara rẹ̀ lọ tí ìfẹ́ kò sì ní ru sókè mọ́ nígbà náà ni ènìyàn yóò lọ ilé rẹ́ ayérayé tí àwọn aṣọ̀fọ̀ yóò máa rìn kiri ìgboro.
6 Pierwej niż się przerwie sznur srebrny, i niż się stłucze czasza złota, a rozsypie się wiadro nad zdrojem, a skruszy się koło nad studnią;
Rántí rẹ̀ kí okùn fàdákà tó já, tàbí kí ọpọ́n wúrà tó fọ́; kí iṣà tó fọ́ níbi ìsun, tàbí kí àyíká kẹ̀kẹ́ kí ó tó kán níbi kànga.
7 I wróci się proch do ziemi, jako przedtem był, a duch wróci się do Boga, który go dał.
Tí erùpẹ̀ yóò sì padà sí ilẹ̀ ibi tí ó ti wà, tí ẹ̀mí yóò sì padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run tí ó fi í fún ni.
8 Marność nad marnościami, mówi kaznodzieja, a wszystko marność.
“Asán! Asán!” ni Oniwaasu wí. “Gbogbo rẹ̀ asán ni!”
9 A czem więcej kaznodzieja był mędrszym, tem więcej nauczał umiejętności ludu, a rozważał i wywiadywał się, i składał wiele przypowieści.
Kì í ṣe wí pé Oniwaasu jẹ́ ọlọ́gbọ́n nìkan, ṣùgbọ́n ó tún kọ́ àwọn ènìyàn ní ìmọ̀. Ó rò ó dáradára ó sì ṣe àwárí, ó sì gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe kalẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ.
10 Starał się kaznodzieja, jakoby znalazł powieści wdzięczne, i napisał, co jest dobrego, i słowa prawdziwe.
Oniwaasu wádìí láti rí àwọn ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀nà, ohun tí ó kọ sì dúró ṣinṣin ó sì jẹ́ òtítọ́.
11 Słowa mądrych podobne ościeniom, i podobne gwoździom wbitym; słowa tych, którzy je złożyli, podane są od pasterza jednego.
Ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹ̀gún, àkójọpọ̀ ọ̀rọ̀ wọn sì dàbí ìṣó tí a kàn pọ̀ dáradára, tí olùṣọ́-àgùntàn kan fi fún ni.
12 A tak, synu mój! z tych słów się dostatecznie upomnieć miożesz; albowim składaniu wielu ksiąg końca niemasz, a wiele czytać, jest spracowanie ciała.
Àti síwájú láti inú èyí, ọmọ mi, gba ìmọ̀ràn. Nínú ìwé púpọ̀, òpin kò sí, ìwé kíkà púpọ̀ a máa mú ara ṣàárẹ̀.
13 Suma wszystkiego, coś słyszał: Boga się bój, a przykazań jego przestrzegaj, bo na tem człowiekowi wszystko zależy;
Nísinsin yìí, òpin gbogbo ọ̀rọ̀ tí a gbọ́ ni pé, bẹ̀rù Ọlọ́run, kí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́, nítorí èyí ni ojúṣe gbogbo ènìyàn.
14 Ponieważ każdy uczynek, i każdą rzecz tajną, lub dobrą, lub złą, Bóg na sąd przywiedzie.
Nítorí Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olúkúlùkù iṣẹ́ àti ohun ìkọ̀kọ̀, kì bá à ṣe rere kì bá à ṣe búburú.

< Kaznodziei 12 >