< Powtórzonego 9 >

1 Słuchaj Izraelu! ty przejdziesz dziś Jordan, abyś wszedłszy posiadł narody większe, i możniejsze, niżeś ty, miasta wielkie, i wymurowane aż pod niebo;
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 Lud wielki i wysokiego wzrostu syny Enakowe, które ty znasz, i o którycheś słyszał, gdy mówiono: Któż się ostoi przed syny Enakowymi?
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 Przetoż wiedz dzisiaj, że Pan, Bóg twój, który idzie przed tobą, jest ogień trawiący: on je wytraci, i on je poniży przed tobą, że je wypędzisz, a wygładzisz je prędko, jakoć to obiecał Pan.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Nie mówże w sercu swem, gdy je wypędzi Pan, Bóg twój, przed tobą, powiadając: Dla sprawiedliwości mojej wprowadził mię Pan, abym posiadł tę ziemię; ale dla niezbożności narodów onych Pan wygnał je przed twarzą twoją.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Nie dla sprawiedliwości twojej, ani dla prostości serca twego ty wnijdziesz, abyś posiadł ziemię ich; ale dla niezbożności narodów tych Pan, Bóg twój, wypędza ich przed twarzą twoją, i aby utwierdził Pan słowo, które przysiągł ojcom twoim Abrahamowi, Izaakowi, i Jakóbowi.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Wiedzże tedy, że nie dla sprawiedliwości twojej, Pan, Bóg twój, daje tobie tę wyborną ziemię, abyś ją posiadł, gdyżeś ty lud twardego karku.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Pamiętaj, a nie zapominaj, żeś do gniewu pobudzał Pana, Boga twego, na puszczy; od onego dnia, jakoś wyszedł z ziemi Egipskiej, ażeście przyszli na to miejsce, odpornymiście byli Panu.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Także i przy górze Horeb pobudziliście do gniewu Pana, i rozgniewał się Pan na was, aby was wygładził.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Gdym wstąpił na górę, abym wziął tablice kamienne, tablice przymierza, które uczynił Pan z wami, i trwałem na górze czterdzieści dni, i czterdzieści nocy, chleba nie jedząc, ani wody pijąc:
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 Tedy mi dał Pan dwie tablice kamienne, napisane palcem Bożym, na których te wszystkie słowa były, które mówił Pan do was na górze z pośrodku ognia, w dzień zgromadzenia waszego.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 A gdy wyszło czterdzieści dni, i czterdzieści nocy, dał mi Pan one dwie tablice kamienne, tablice przymierza;
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 I rzekł Pan do mnie: Wstań, znijdź stąd rychło; albowiem się popsował lud twój, któryś wywiódł z Egiptu; odstąpili prędko z drogi, którąm im rozkazał, i uczynili sobie litego bałwana.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 I rzekł Pan do mnie, mówiąc: Widziałem ten lud, a oto, lud twardego karku jest.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 Puść mię a wytracę je, i wygładzę imię ich pod niebem, a ciebie uczynię w naród możniejszy, i większy niźli ten.
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 Tedym się obrócił, i zstąpiłem z góry, (a góra ona pałała ogniem), dwie tablice przymierza niosąc w obu rękach moich.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 A gdym ujrzał, iżeście zgrzeszyli przeciw Panu, Bogu waszemu, uczyniwszy sobie cielca litego i odstąpiliście byli prędko z drogi, którą wam rozkazał Pan:
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Tedy wziąwszy ja one dwie tablice, porzuciłem je z obu rąk moich, a stłukłem je przed oczyma waszemi.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 Potem upadłem przed Panem jako i pierwej, przez czterdzieści dni i czterdzieści nocy, chlebam nie jadł, i wodym nie pił dla waszych wszystkich grzechów, któremiście zgrzeszyli, czyniąc złość przed oczyma Pańskiemi, i draźniąc go.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Bom się bał onej popędliwości i gniewu, którym się był zapalił Pan przeciwko wam, aby was wytracił; i wysłuchał mię Pan i tym razem.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Na Aarona też rozgniewał się był Pan bardzo, chcąc go zatracić; tedym się też za Aaronem modlił tegoż czasu.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 A grzech wasz, któryście byli uczynili, to jest cielca, porwałem, i spaliłem go ogniem, i skruszyłem go, tłukąc dobrze, aż się w proch obrócił, i wrzuciłem proch jego w potok, który płynął z onej góry.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 Potem w Tabera i w Massa, w Kibrot Hataawa pobudziliście do gniewu Pana.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 A gdy was Pan wysłał z Kades Barne, mówiąc: Idźcie, a posiądźcie tę ziemię, którąm wam dał, odporniście byli słowu Pana, Boga waszego, aniście mu wierzyli, aniście usłuchali głosu jego,
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 Owa odporniście byli Panu od dnia tego, jakom was poznał.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 Dla tego upadłszy przed Panem, czterdzieści dni i czterdzieści nocy leżałem; bo już był Pan rzekł, że was wytracić miał.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 I modliłem się Panu, i rzekłem: Panie Boże, nie zatracajże ludu twego, i dziedzictwa twego, któreś odkupił wielmożnością twoją, któreś wywiódł z Egiptu ręką możną.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Wspomnij na służebniki twoje, Abrahama, Izaaka, i Jakóba; nie patrz na zatwardziałość ludu tego, i na niezbożność jego, ani na grzech jego,
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 By snać nie rzekli obywatele ziemi tej, z którejś nas wywiódł: Przeto że nie mógł Pan wprowadzić ich do ziemi, którą im obiecał, albo iż je miał w nienawiści, wywiódł je, aby je pobił na puszczy.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 Albowiem oni są ludem twoim, i dziedzictwem twojem, któreś wywiódł w mocy twojej wielkiej, i w ramieniu twojem wyciągnionem.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”

< Powtórzonego 9 >