< Powtórzonego 7 >
1 Gdy cię wprowadzi Pan, Bóg twój, do ziemi, do której wchodzisz, abyś ją posiadł i wytraci narodów wiele przed twarzą twoją, Hetejczyka, i Gergiezejczyka, i Amorejczyka, i Chananejczyka, i Ferezejczyka, i Hewejczyka i Jebuzejczyka, siedem narodów, większych, i możniejszych, niżliś ty;
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
2 A poda je Pan, Bóg twój, tobie, iż je porazisz: tedy wytracisz je do szczątku, nie będziesz brał z nimi przymierza, ani się zlitujesz nad nimi;
nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
3 Ani się spowinowacisz z nimi: córki swej nie dasz synowi jego, i córki jego nie weźmiesz synowi swemu;
Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
4 Boby zwiodła syna twego, żeby nie szedł za mną, a służyliby bogom cudzym; za czem zapaliłby się gniew Pański przeciwko wam, a wytraciłby was prędko.
torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
5 Ale owszem to im uczyńcie: Ołtarze ich poobalacie, a słupy ich pokruszycie, i gaje ich poświęcone wyrąbicie, a ryte ich bałwany ogniem popalicie:
Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
6 Albowiemeś ty lud święty Panu, Bogu twemu; ciebie obrał Pan, Bóg twój, abyś mu był osobliwym ludem ze wszystkich narodów, które są na ziemi.
Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
7 Nie przeto, że was więcej nad inne narody, przyłączył się Pan do was, i obrał was, gdyż was było najmniej ze wszystkich narodów;
Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
8 Ale iż was umiłował Pan, i strzedz chciał onej przysięgi, którą przysiągł ojcom waszym, wywiódł was Pan ręką możną, i wykupił was z domu niewoli, z ręki Faraona, króla Egipskiego.
Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
9 A tak wiedz, że Pan, Bóg twój, jest Bóg, Bóg wierny, chowający przymierze, i miłosierdzie tym, którzy go miłują i strzegą przykazań jego, do tysięcznego pokolenia;
Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
10 A oddający tym, którzy go mają w nienawiści, każdemu w twarz jego, aby go wytracił; nie omieszka temu, który go ma w nienawiści, w twarz jego odda mu.
Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
11 Przetoż przestrzegaj przykazania, i ustaw, i sądów, które ja dziś rozkazuję tobie, abyś je czynił.
Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
12 I stanie się, że jeźli słuchać sądów tych, a przestrzegać, i czynić je będziecie, tedy też dotrzyma Pan, Bóg twój, tobie przymierza, i miłosierdzia, które poprzysiągł ojcom twoim.
Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
13 I umiłuje cię; i ubłogosławi cię i rozmnoży cię; bo pobłogosławi owocowi żywota twego, i owocowi ziemi twojej, zbożu twojemu, i winu twojemu, i oliwie twojej, płodowi krów twoich, i trzodom owiec twoich w ziemi, o którą przysiągł ojcom twoim, że ją da tobie.
Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
14 Błogosławionym będziesz nad wszystkie narody; nie będzie u ciebie niepłodny, i niepłodna, ani między bydłem twojem.
A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
15 Oddali też Pan od ciebie każdą niemoc, i wszelkie choroby egipskie złe, o których wiesz; nie dopuści ich na cię, ale je przepuści na wszystkie, którzy cię nienawidzą.
Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
16 I wytracisz wszystkie narody, które Pan, Bóg twój, poda tobie; nie sfolguje im oko twoje, ani będziesz chwalił bogów ich; boćby to było sidłem.
Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
17 Jeźlibyś rzekł w sercu swem: Większe są te narody niźli ja, jakoż je będę mógł wygnać?
Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
18 Nie bój się ich; ale pilnie pamiętaj na to, co uczynił Pan, Bóg twój, Faraonowi, i wszystkim Egipczanom;
Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
19 Na one kuszenia wielkie, które widziały oczy twoje, i na znaki, na cuda, i na rękę możną, i na ramię wyciągnione, którem cię wywiódł Pan, Bóg twój; takci uczyni Pan, Bóg twój, wszystkim narodom, których się ty twarzy boisz.
Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
20 Nad to pośle Pan, Bóg twój, na nie sierszenie, aż wygubi ostatki ich, i te, którzy by się pokryli przed tobą.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
21 Nie lękajże się twarzy ich, albowiem Pan, Bóg twój, jest w pośrodku ciebie, Bóg wielki i straszny.
Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
22 I wyniszczy Pan, Bóg twój, narody one przed tobą, po lekku i po trosze;
Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
23 Nie będziesz ich mógł wytracić prędko, by się snać nie namnożyło przeciw tobie bestyi polnych.
Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
24 I poda je tobie Pan, Bóg twój, i zetrze je starciem wielkiem, aż będą wyniszczeni. A poda króle ich w ręce twoje, i wygubisz imię ich pod niebem; nie ostoi się żaden przed tobą, aż je wytracisz.
Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
25 Obrazy ryte bogów ich popalisz ogniem; nie będziesz pożądał srebra, ani złota, które jest na nich, abyś je miał sobie brać, byś się snać nie usidlił w niem, ponieważ to obrzydliwość jest Panu, Bogu twemu.
Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
26 Nie wnośże obrzydliwości w dom twój, abyś się nie stał przeklęstwem, jako i ona; wielce się nią brzydzić będziesz, i bardzo ją sobie obmierzysz, ponieważ przeklęstwem jest.
Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.