< Powtórzonego 4 >
1 Teraz tedy, o Izraelu, słuchaj ustaw, i sądów, których ja was uczę, abyście je czyniąc żyli, a wszedłszy posiedli ziemię, którą Pan, Bóg ojców waszych, dawa wam.
Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
2 Nie przydacie do słowa, które ja wam rozkazuję, ani ujmiecie z niego, abyście strzegli przykazań Pana, Boga waszego, które ja wam rozkazuję.
Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
3 Oczy wasze widziały, co uczynił Pan dla Baal fegora, jako każdego męża, który się udawał za Baal fegorem, wytracił Pan, Bóg twój, z pośrodku was.
Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
4 A wy, którzyście trwali przy Panu, Bogu waszym, żyjecie wszyscy aż do dnia dzisiejszego.
Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
5 Patrzcież, żem was nauczał ustaw i sądów, jako mi rozkazał Pan, Bóg mój, abyście tak czynili w ziemi tej, do której wchodzicie, abyście ją dziedzicznie posiedli.
Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
6 Przestrzegajcież ich tedy, a czyńcie je; to bowiem jest mądrość wasza, i rozum wasz przed oczyma narodów; którzy usłyszawszy o tych wszystkich ustawach, rzeką: Tylko ten lud mądry, i rozumny, i naród wielki jest.
Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
7 Albowiem któryż naród tak wielki jest, coby mu byli bogowie tak bliscy, jako Pan, Bóg nasz, we wszystkiem, ilekroć go wzywamy?
Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
8 Albo któryż naród tak wielki, któryby miał ustawy i sądy tak sprawiedliwe, jako wszystek ten zakon, który ja przedkładam wam dziś?
Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
9 A wszakże miej się na pieczy, a strzeż duszy twej pilnie, byś snać nie zapomniał na te rzeczy, które widziały oczy twoje i aby snać nie odstąpiły od serca twego po wszystkie dni żywota twego; i oznajmisz je synom twym, i synom synów twoich.
Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
10 Nie zapominaj, żeś onego dnia stał przed oblicznością Pana, Boga twego, na Horeb, gdy mówił Pan do mnie: Zgromadź mi lud, abym im powiedział słowa moje, których się uczyć będą, aby się mnie bali po wszystkie dni, pokąd żyć będą na ziemi, i synów swoich nauczając tego.
Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
11 Tedyście przystąpili, a stanęliście pod górą, a ona góra pałała ogniem aż do samego nieba, a była na niej ciemność, obłok i mgła.
Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
12 I mówił Pan do was z pośród ognia; głos słów słyszeliście, aleście podobieństwa żadnego nie widzieli oprócz głosu.
Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
13 I oznajmił wam przymierze swoje, które rozkazał wam, abyście je czynili, to jest dziesięć słów, które napisał na dwóch tablicach kamiennych.
Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
14 Mnie też rozkazał Pan na on czas, abym was nauczał ustaw i sądów, abyście je czynili w ziemi, do której idziecie, abyście ją dziedzicznie posiedli.
Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
15 A tak strzeżcie pilnie dusz waszych, (gdyżeście nie widzieli żadnego podobieństwa, dnia, którego mówił Pan do was na Horebie z pośrodku ognia, )
Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
16 Abyście się snać nie popsowali, i nie czynili sobie rytego bałwana, albo obrazu wszelkiego podobieństwa, kształtu mężczyzny albo niewiasty;
kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
17 Albo kształtu jakiego zwierzęcia, które jest na ziemi, kształtu wszelkiego ptaka skrzydlastego, który lata po powietrzu;
tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
18 Kształtu wszystkiego tego, co się płaza po ziemi, kształtu wszelkiej ryby, która jest w wodzie pod ziemią.
tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
19 Ani podnoś oczu swych ku niebu, żebyś widząc słońce i miesiąc, i gwiazdy ze wszystkiemi zastępy niebieskiemi, nie dał się uwieść, abyś się im kłaniał, i służyłbyś im, ponieważ je oddał Pan, Bóg twój, na posługę wszystkim ludziom pod wszystkiem niebem.
Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
20 Aleć was wziął Pan, i wywiódł was jako z żelaznego pieca, z Egiptu, abyście byli jego ludem dziedzicznym, jako dziś jesteście.
Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
21 A Pan rozgniewał się na mię dla was, a przysiągł, że nie przejdę przez Jordan, ani wnijdę do onej wybornej ziemi, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie w dziedzictwo.
Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
22 Bo ja umrę w tej ziemi, ja nie przejdę za Jordan; ale wy przejdziecie, i dziedzicznie osiądziecie tę dobrą ziemię.
Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
23 Strzeżcież się, byście snać nie zapomnieli przymierza Pana, Boga waszego, które uczynił z wami, a nie czynili sobie rytego obrazu na kształt jakiejkolwiek rzeczy, jakoć rozkazał Pan, Bóg twój.
Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
24 Albowiem Pan, Bóg twój, jest ogień trawiący, Bóg zawisny.
Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
25 Gdy spłodzisz syny i wnuki, a zstarzejecie się w ziemi onej, jeźlibyście się popsowali, a czynilibyście sobie ryte bałwany na kształt jakiejkolwiek rzeczy, i uczynilibyście co złego przed oczyma Pana, Boga waszego, drażniąc go:
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
26 Biorę na świadectwo przeciwko wam dziś niebo i ziemię, iż pewnie w rychle wyginiecie z ziemi, do której pójdziecie przez Jordan, abyście dziedzicznie ją posiedli; nie przedłużycie dni waszych w niej, bo pewnie wytraceni będziecie.
Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
27 I rozproszy was Pan między narody, a zostanie was mało między narody, do których zaprowadzi was Pan.
Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
28 Tamże będziecie służyli bogom, robocie rąk ludzkich, drewnu i kamieniowi, które ani widzą, ani słyszą, ani wąchają.
Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
29 A wszakże i tam jeźli szukać będziesz Pana, Boga twego, tedy znajdziesz, będzieszli go szukał całem sercem twojem, i całą duszą swoją.
Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
30 Gdy ucisk przyjdzie na cię, a najdą cię te wszystkie rzeczy w ostatnie dni, tedy, nawróciszli się do Pana, Boga twego, a posłusznym będziesz głosowi jego,
Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
31 (Albowiem Bóg miłosierny Pan, Bóg twój jest) nie opuści cię, ani cię skazi, ani zapomni na przymierze ojców twoich, które im przysiągł.
Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
32 Pytaj się teraz na dni starodawne, które były przed tobą, ode dnia, którego stworzył Bóg człowieka na ziemi; a od jednego końca nieba aż do drugiego końca nieba stałali się kiedy rzecz podobna tej tak wielkiej? albo słuchanoli kiedy co takowego?
Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
33 Słyszałli kiedy który naród głos Boga mówiącego z pośrodku ognia, jakoś ty słyszał, a żyw został?
Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
34 Albo kusiłli się który bóg przyjść a wziąć sobie naród z pośrodku innego narodu przez pokusy, przez znaki, i przez cuda, i przez wojny, i przez mocną rękę, i przez ramię wyciągnione, i w strachach wielkich, według wszystkiego, jako uczynił dla was Pan, Bóg wasz, w Egipcie przed oczyma twemi?
Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
35 Tobie to ukazano, abyś wiedział, iż Pan jest Bóg, a nie masz innego oprócz niego.
A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
36 Dał ci z nieba słyszeć głos swój, aby cię wyćwiczył, a na ziemi ukazał ci ogień swój wielki, a słowa jego słyszałeś z pośrodku ognia.
Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
37 A iż umiłował ojce twoje, obrał nasienie ich po nich, i wywiódł cię przed sobą mocą swoją wielką z Egiptu,
torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
38 Aby wygnał narody wielkie i możniejsze nad cię przed twarzą twoją, i wprowadził cię, a dał ci ziemię ich w dziedzictwo, jako to dziś widzisz.
Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
39 Wiedzże tedy dziś, a wspomnij na to w sercu twojem, iż Pan jest Bogiem na niebie wysoko, i na ziemi nisko nie masz innego.
Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
40 A tak przestrzegaj ustaw jego, i przykazań jego, które ja dziś rozkazuję tobie, abyć się dobrze wodziło, i synom twoim po tobie; abyś też przedłużył dni na ziemi, którą Pan, Bóg twój, da tobie, po wszystkie dni.
Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
41 Tedy oddzielił Mojżesz trzy miasta z tej strony Jordanu na wschód słońca.
Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
42 Aby tam uciekał mężobójca, któryby zabił bliźniego swego z nieobaczenia, nie mając go w nienawiści przedtem, aby uciekłszy do jednego z tych miast, żyw został;
Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
43 Beser na puszczy, w równinie w ziemi Rubenitów, i Ramot w Galaad między Gadyty, i Golam w Bazan między Manassytami.
Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
44 Tenci jest zakon, który przedłożył Mojżesz synom Izraelskim.
Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
45 Te są świadectwa, i ustawy, i sądy, które mówił Mojżesz do synów Izraelskich, gdy wyszli z Egiptu;
Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
46 Z tej strony Jordanu, w dolinie przeciw Betfegor, w ziemi Sehona, króla Amorejskiego, który mieszkał w Hesebon, którego poraził Mojżesz, i synowie Izraelscy, gdy szli z Egiptu;
Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
47 I osiedli ziemię jego, i ziemię Oga, króla Basańskiego, dwóch królów Amorejskich, którzy byli z tej strony Jordanu na wschód słońca;
Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
48 Od Aroer, które jest nad brzegiem potoku Arnon, i aż do góry Syon, która jest Hermon;
Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
49 I wszystkie pola nad Jordanem na wschód słońca, i aż do morza pustego, pod górą Fazga.
Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.