< Powtórzonego 3 >

1 Potem obróciwszy się szliśmy drogą ku Basan; i wyciągnął przeciwko nam Og, król Basański, sam, i wszystek lud jego, ku bitwie w Edrej.
Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
2 Tedy rzekł Pan do mnie: Nie bój się go; bom go dał w ręce twoje, i wszystek lud jego, i ziemię jego, i uczynisz mu, jakoś uczynił Sehonowi, królowi Amorejskiemu, który mieszkał w Hesebon.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
3 Dał tedy Pan, Bóg nasz, w ręce nasze i Oga, króla Basańskiego, i wszystek lud jego, i poraziliśmy go, tak że nie zostało po nim nikogo.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
4 Wzięliśmy też wszystkie miasta jego na on czas; nie było miasta, którego byśmy im nie wzięli, sześćdziesiąt miast, wszystkę krainę Argob królestwa Ogowego w Basan.
Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
5 Te wszystkie miasta opatrzone były murami wysokiemi, bramami, i zaworami, oprócz miasteczek murem nie obtoczonych bardzo wiele.
Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
6 I spustoszyliśmy je, jakośmy uczynili Sehonowi, królowi Hesebońskiemu, wytraciwszy wszystkie miasta, męże, niewiasty i dzieci.
Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
7 Tylko wszystkie bydła i łupy z miast rozebraliśmy między się.
Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
8 Wzięliśmy też na on czas ziemię z ręki dwóch królów Amorejskich, która leży z tej strony Jordanu, od rzeki Arnon aż do góry Hermon.
Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
9 (Sydończycy zowią Hermon Szyryjon, a Amorejczycy zowią go Sanir.)
(Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
10 Wszystkie miasta w równinie, i wszystko Galaad, i wszystko Basan aż do Selcha, i Edrej, miasta królestwa Ogowego w Basan.
Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
11 Bo tylko sam Og, król Basański pozostał był z olbrzymów; oto, łoże jego łoże żelazne, azaż jeszcze nie jest w Rabbat, synów Ammonowych? dziewięć łokci długość jego, a cztery łokcie szerokość jego na łokieć męski.
(Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
12 Gdyśmy tedy ziemię tę posiedli na on czas, od Aroer, które jest nad potokiem Arnon, i połowę góry Galaad, i miasta jej dałem Rubenitom, i Gadytom.
Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
13 A ostatek Galaadu, i wszystko Basan, królestwa Ogowego, dałem połowie pokolenia Manasesowego, wszystkę krainę Argob, i wszystko Basan, które zowią ziemią olbrzymów.
Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
14 Jair, syn Manasesów, posiadł wszystkę krainę Argob aż do granicy Jessury i Machaty; przetoż nazwał ją od imienia swego Basan Hawot Jair, aż do dzisiejszego dnia.
Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
15 Machirowi zaś dałem Galaad.
Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
16 A Rubenitom i Gadytom dałem krainę od Galaadu aż do potoku Arnon, pół potoku z pograniczem, aż do potoku Jabok, granicy synów Ammonowych;
ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
17 Przytem równinę i Jordan z pograniczem od Cyneret aż do morza pustego, które jest morze słone, pod górą Fazga na wschód słońca.
Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
18 I rozkazałem wam na on czas, mówiąc: Pan, Bóg wasz, dał wam tę ziemię, abyście ją dziedzicznie posiedli, a tak zbrojno pójdziecie przed bracią waszą, syny Izraelskimi, wszyscy mężowie duży.
Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
19 Tylko żony wasze, i dziatki wasze, i bydła wasze, (gdyż wiem, że dobytku siła macie, ) zostaną w mieściech waszych, którem wam dał.
Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
20 Aż da odpoczynek Pan braci waszej, jako i wam, że i oni posiędą ziemię onę, którą Pan, Bóg wasz, dawa im za Jordanem: tedy się wróci każdy do osiadłości swojej, którą wam dał.
títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
21 Jozuemu też przykazałem na on czas, mówiąc: Oczy twoje widziały wszystko, co uczynił Pan, Bóg wasz, onym dwom królom; toż uczyni Pan, wszystkim królestwom, do których ty pójdziesz.
Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
22 Nie bójcież się ich, ponieważ Pan, Bóg wasz, jest, który walczy za was.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
23 I prosiłem Pana na on czas, mówiąc:
Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
24 Panie Boże, tyś począł okazywać słudze twemu wielkość twoję, i rękę twoję możną; bo któż jest Bogiem na niebie, albo na ziemi, któryby czynić mógł według spraw twoich, i według możności twoich?
“Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
25 NIech przejdę proszę, abym oglądał tę wyborną ziemię, która jest za Jordanem, górę onę wyborną i z Libanem.
Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
26 Ale się rozgniewał Pan na mię dla was, i nie wysłuchał mię, i rzekł Pan do mnie: Dosyć masz, nie mówże już więcej do mnie o to.
Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
27 Wstąp na wierzch góry Fazga, a podnieś oczy swe ku zachodowi, i ku północy, i ku południowi, i ku wschodowi, a przypatrz się oczyma swemi; bo nie przejdziesz przez ten Jordan;
Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
28 Ale porucz to Jozuemu, i umocnij go, a potwierdź go; albowiem on pójdzie przed tym ludem, a on poda im w dziedzictwo ziemię, którą oglądasz.
Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
29 A tak mieszkaliśmy w dolinie przeciw Betfegor.
Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.

< Powtórzonego 3 >