< Powtórzonego 1 >

1 Teć są słowa, które mówił Mojżesz do wszystkiego Izraela przed Jordanem na puszczy, na równinie przeciw morzu czerwonemu, między Faran, i między Tofel, i Laban, i Haserot, i Dyzahab.
Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
2 A jest jedenaście dni drogi od Horebu przez górę Seir aż do Kades Barne.
(Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
3 I stało się czterdziestego roku, jedenastego miesiąca, pierwszego dnia tegoż miesiąca, że opowiedział Mojżesz synom Izraelskim to wszystko, co mu był rozkazał Pan do nich.
Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
4 Gdy poraził Sehona, króla Amorejskiego, który mieszkał w Hesebon, i Oga, króla Basańskiego, który mieszkał w Astarot w Edrej.
Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
5 Przed Jordanem w ziemi Moabskiej począł Mojżesz wykładać ten zakon, mówiąc:
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
6 Pan, Bóg nasz, mówił do nas na górze Horeb, i rzekł: Dosycieście mieszkali na tej górze.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
7 Obróćcież się, a ciągnąc idźcie do góry Amorejskiej, i na wszystkie miejsca pograniczne jej, na równiny, na góry, i na doliny, i ku południowi, i ku brzegu morskiemu, ku ziemi Chananejskiej, i do Libanu, aż do wielkiej rzeki, rzeki Eufrates.
Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
8 Oto, dałem wam tę ziemię; wnijdźcież a posiądźcie tę ziemię, o którą przysiągł Pan ojcom waszym, Abrahamowi, Izaakowi i Jakóbowi, iż im ją dać miał, i nasieniu ich po nich.
Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
9 I rzekłem do was na on czas, mówiąc: Nie mogę sam nosić was.
Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
10 Pan, Bóg wasz, rozmnożył was, a otoście dziś jako gwiazdy niebieskie w mnóstwie swojem.
Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
11 Pan, Bóg ojców waszych, niech rozmnoży was nad to, jakoście teraz, tysiąc kroć więcej; i niech was błogosławi, jako wam obiecał.
Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
12 Jakoż sam znosić mam ciężką pracę około was, i brzemię wasze, i swary wasze?
Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
13 Obierzcie z siebie męże mądre i umiejętne a doświadczone w pokoleniach waszych, a postanowię je przełożonymi nad wami.
Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
14 Tedyście mi odpowiedzieli, i rzekliście: Dobra rzecz, którąś rozkazał uczynić.
Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
15 I obrałem przedniejsze z pokoleń waszych, męże mądre, i doświadczone, i postanowiłem je przełożonymi nad wami: tysiączniki, i setniki, i pięćdziesiątniki, i dziesiątniki, i rządce w pokoleniach waszych.
Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
16 I rozkazałem sędziom waszym na on czas, mówiąc: Wysłuchywajcie spraw między bracią waszą, i sądźcie sprawiedliwie między mężem i między bratem jego, i między przychodniem jego.
Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
17 Nie miejcie względu na osoby przy sądzie; tak małego jako wielkiego wysłuchywajcie; nie bójcie się nikogo, albowiem sąd Boży jest; a jeźliby co przytrudniejszem było na was, odniesiecie do mnie, a ja tego przesłucham.
Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
18 I przykazałem wam na on czas wszystko, coście czynić mieli.
Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
19 Potem ruszywszy się z Horeb przeszliśmy wszystkę onę pustynią wielką i straszną, którąście widzieli, idąc drogą ku górze Amorejskiej, jako nam był rozkazał Pan, Bóg nasz, i przyszliśmy aż do Kades Barne
Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
20 I rzekłem do was: Przyszliście aż do góry Amorejczyka, którego Pan, Bóg nasz, dawa nam.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
21 Oto, podawa Pan, Bóg twój, tobie tę ziemię; idźże, a posiądź ją, jakoć powiedział Pan, Bóg ojców twoich, nie bój się ani się lękaj.
Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
22 I przyszliście do mnie wszyscy, a mówiliście: Poślijmy męże przed sobą, którzy by nam przeszpiegowali ziemię, i dali nam pewną sprawę, którą byśmy drogą do niej wnijść mieli, i miasta, do których byśmy weszli.
Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
23 Co gdy mi się podobało, obrałem z was dwanaście mężów, po jednym mężu z każdego pokolenia.
Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
24 Którzy odszedłszy weszli na górę, a przyszli aż do doliny Eschol, i przeszpiegowali ziemię.
Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
25 Nabrali też z sobą owocu onej ziemi, i przynieśli do nas, i dali nam o tem sprawę, a powiedzieli: Dobra jest ziemia, którą nam dawa Pan, Bóg nasz.
Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
26 Aleście nie chcieli iść: leczeście byli odpornymi słowu Pana, Boga waszego.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
27 I szemraliście w namieciech waszych, mówiąc: Iż nas Pan miał w nienawiści, wywiódł nas z ziemi Egipskiej, aby nas podał w ręce Amorejczyka, i wygubił nas.
Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
28 Dokądże iść mamy? Bracia nasi zepsowali nam serce, mówiąc: Lud ten większy i roślejszy jest, niźli my, miasta wielkie, i wymurowane aż ku niebu, a nad to, syny olbrzymów widzieliśmy tam.
Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
29 Alem ja mówił do was: Nie lękajcie się, ani się ich bójcie.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
30 Pan, Bóg wasz, który idzie przed wami, walczyć będzie za was, tak jako wam uczynił w Egipcie przed oczyma waszemi.
Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
31 Także i na puszczy, gdzieś widział, jako cię nosił Pan, Bóg twój, jako nosi ojciec syna swego, w onej wszystkiej drodze, którąście szli, ażeście przyszli na to miejsce.
àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
32 Lecz ani tak uwierzyliście Panu, Bogu waszemu.
Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
33 Który chodził przed wami w drodze, przepatrując wam miejsce do stanowienia obozu, w nocy w ogniu, aby wam ukazał drogę którą byście iść mieli, we dnie zaś w obłoku.
tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
34 I usłyszał Pan głos słów waszych, a rozgniewał się bardzo, i przysiągł, mówiąc:
Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
35 Zaiste żaden z ludu tego narodu złego, nie ogląda onej ziemi dobrej, którąm przysiągł dać ojcom waszym;
“Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
36 Oprócz Kaleba, syna Jefunowego, ten ją ogląda, i temu dam ziemię, którą deptał, i synom jego, przeto że cale szedł za Panem.
Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
37 Także i na mię rozgniewał się Pan dla was, mówiąc: I ty tam nie wnijdziesz.
Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
38 Jozue, syn Nunów, któryć służy, ten tam wnijdzie, tegoż utwierdzaj; bo ją on w dziedzictwo poda Izraelowi.
ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
39 Dziatki też wasze, o którycheście mówili, że będą podane na łup, także synowi wasi, którzy dziś nie wiedzą dobrego ani złego, ci tam wnijdą i onym ją dam, a oni ją dziedzicznie posiędą;
Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
40 Ale wy obróciwszy się, idźcie na puszczą, drogą ku morzu czerwonemu.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
41 A odpowiadając mówiliście do mnie: Zgrzeszyliśmy Panu; pójdziemy, i walczyć będziemy według tego wszystkiego, jako nam rozkazał Pan, Bóg nasz; i ubrał się każdy z was we zbroje swoje, a chcieliście wnijść na górę.
Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
42 Lecz Pan rzekł do mnie: Powiedz im: Nie wstępójcie, ani walczcie; bom nie jest w pośrodku was, abyście nie byli porażeni od nieprzyjaciół waszych.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
43 Co gdym wam opowiedział, nie słuchaliście, aleście odporni byli słowu Pańskiemu, i hardzieście postąpili sobie, a weszliście na górę.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
44 Tedy wyciągnął Amorejczyk, który mieszkał na onej górze, przeciwko wam, i gonili was, jako zwykły pszczoły, i porazili was w Seir aż do Horma.
Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
45 I wróciwszy się, płakaliście przed Panem; lecz nie wysłuchał Pan głosu waszego, a nie nakłonił uszu swoich do was.
Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
46 Mieszkaliście tedy w Kades przez wiele dni według liczby dni, którycheście tam mieszkali.
Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

< Powtórzonego 1 >