< Daniela 7 >
1 Roku pierwszego Balsazara, króla Babilońskiego, miał Danijel sen i widzenia swoje na łożu swem; tedy spisał on sen, i sumę rzeczy powiedział.
Ní ọdún àkọ́kọ́ Belṣassari ọba Babeli, Daniẹli lá àlá kan, ìran náà sì wá sí ọkàn an rẹ̀ bí ó ṣe sùn sórí ibùsùn un rẹ̀, ó sì kọ àlá náà sílẹ̀.
2 A mówiąc Danijel rzekł: Widziałem w widzeniu mojem w nocy, a oto cztery wiatry niebieskie potykały się na morzu wielkiem;
Daniẹli sọ pé, “Nínú ìran mi lóru mo wò ó, mo sì rí afẹ́fẹ́ ọ̀run mẹ́rin tí ó ń ru omi Òkun ńlá sókè.
3 A cztery bestyje wielkie występowały z morza, różne jedna od drugiej.
Ẹranko ńlá mẹ́rin tí ó yàtọ̀ sí ara wọn, jáde láti inú Òkun náà.
4 Pierwsza podobna lwowi, mając skrzydła orle; i przypatrywałem się, aż wyrwane były skrzydła jej, któremi się podnosiła od ziemi, tak, że na nogach jako człowiek stanęła, a serce człowiecze jej dane jest.
“Ẹranko kìn-ín-ní dàbí i kìnnìún, ó sì ní ìyẹ́ apá a idì, mo sì wò títí a fi fa ìyẹ́ apá rẹ̀ náà tu, a sì gbé e sókè kúrò ní ilẹ̀, a mú kí ó fi ẹsẹ̀ dúró bí ènìyàn, a sì fi àyà ènìyàn fún un.
5 Potem oto bestyja druga podobna niedźwiedziowi; i stanęła przy jednej stronie, a trzy żebra były w paszczęce jej między zębami jej, i tak mówiono do niej: Wstań, nażryj się dostatkiem mięsa.
“Mo sì tún rí ẹranko kejì, ó rí bí irú ẹranko ńlá beari kan tí ó ń gbé ilẹ̀ òtútù; o gbé ara sókè ní apá kan, ó sì ní egungun ìhà mẹ́ta láàrín ẹ̀yìn in rẹ̀, wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Dìde kí o sì jẹ ẹran tó pọ̀!’
6 Potemem widział, a oto inna bestyja podobna lampartowi, która miała cztery skrzydła ptasze na grzbiecie swym, cztery też głowy miała ta bestyja, i dano jej władzę wielką.
“Lẹ́yìn ìgbà náà, mo tún rí ẹranko kẹta ó rí bí àmọ̀tẹ́kùn. Ẹranko náà ní ìyẹ́ bí i ti ẹyẹ ní ẹ̀yìn, ó sì ní orí mẹ́rin, a sì fún un ní agbára láti ṣe ìjọba.
7 Potemem widział w widzeniach nocnych, a oto bestyja czwarta straszna i sroga i bardzo mocna, mająca zęby żelazne wielkie, która pożerała i kruszyła, a ostatek nogami swemi deptała; a ta była różna od wszystkich bestyj, które były przed nią, i miał a dziesięć rogów.
“Lẹ́yìn èyí, nínú ìran mi ní òru mo tún rí ẹranko kẹrin, ó dẹ́rùbà ni, ó dáyà fo ni, ó sì lágbára gidigidi. Ó ní eyín irin ńlá; ó ń jẹ, ó sì ń fọ́ túútúú, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀. Ó yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ẹranko ti ìṣáájú, ó sì ní ìwo mẹ́wàá.
8 Pilniem się przypatrywał rogom, a oto róg pośledni mały wyrastał między niemi, i trzy z tych rogów pierwszych wyłamane są przed nim; a oto w onym rogu były oczy podobne oczom człowieczym, i usta mówiące rzeczy wielkie.
“Bí mo ṣe ń ronú nípa ìwo náà, nígbà náà ni mo rí ìwo mìíràn, tí ó kéré tí ó jáde wá ní àárín wọn; mẹ́ta lára àwọn ìwo ti àkọ́kọ́ sì fàtu níwájú u rẹ̀. Ìwo yìí ní ojú bí i ojú ènìyàn àti ẹnu tí ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
9 I przypatrywałem się, aż one stolice postawione były, a Starodawny usiadł, którego szata była jako śnieg biała, a włosy głowy jego jako wełna czysta, stolica jego jako płomienie ogniste, a koła jej jako ogień gorejący.
“Bí mo ṣe ń wò, “a gbé ìtẹ́ ọba kan kalẹ̀, ẹni ìgbàanì jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀. Aṣọ rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú; irun orí rẹ̀ funfun bí òwú, ìtẹ́ ọba rẹ̀ rí bí ọwọ́ iná. Àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ ń jó bí i iná.
10 Rzeka ognista płynąc wychodziła od oblicza jego. Tysiąc tysięcy służyło mu, a dziesięć kroć tysiąc tysięcy stało przed nim; sąd zasiadł, a księgi otworzone były.
Odò iná ń sàn, ó ń jáde ní iwájú rẹ̀ wá. Àwọn ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún ń ṣe ìránṣẹ́ fún un; ọ̀nà ẹgbẹẹgbàárùn-ún nígbà ẹgbàárùn-ún dúró níwájú rẹ̀. Àwọn onídàájọ́ jókòó, a sì ṣí ìwé wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀.
11 Tedym się przypatrywał, skoro się głos począł tych słów wielkich, które on róg mówił; przypatrywałem się, aż była ta bestyja zabita, i zginęło ciało jej, a podane było na spalenie ogniem.
“Nígbà náà ni mo bẹ̀rẹ̀ sí ní wò, nítorí àwọn ọ̀rọ̀ ìgbéraga tí ìwo náà ń sọ, mo wò títí a fi pa ẹranko náà, a sì pa á run, a sì jù ú sínú iná tí ń jó.
12 Także i pozostałym bestyjom odjęta jest władza ich: bo długość żywota dana im była aż do czasu, a to do zamierzonego czasu.
A sì gba ìjọba lọ́wọ́ àwọn ẹranko yòókù, ṣùgbọ́n a fún wọn láààyè láti wà fún ìgbà díẹ̀.
13 Widziałem też w widzeniu nocnem, a oto przychodził w obłokach niebieskich podobny synowi człowieczemu, a przyszedł aż do Starodawnego, i przywiedziono go przed obliczność jego.
“Nínú ìran mi ní òru mo wò, mo rí ẹnìkan tí ó dúró sí iwájú u mi, ó rí bí ọmọ ènìyàn, ó ń bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ ọ̀run, ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ ẹni ìgbàanì, a sì mú u wá sí iwájú rẹ̀.
14 I dał mu władzę i cześć i królestwo, aby mu wszyscy ludzie, narody i języki służyli; władza jego władza wieczna, która nie będzie odjęta, a królestwo jego, które nie będzie skażone.
A sì fi ìjọba, ògo àti agbára ilẹ̀ ọba fún un; gbogbo ènìyàn, orílẹ̀-èdè àti èdè gbogbo wọn wólẹ̀ fún un. Ìjọba rẹ̀, ìjọba ayérayé ni, èyí tí kò le è kọjá, ìjọba rẹ̀ kò sì le è díbàjẹ́ láéláé.
15 I zatrwożył się we mnie Danijelu duch mój w pośród ciała mego, a widzenia, którem widział, przestraszyły mię.
“Ọkàn èmi Daniẹli, dàrú, ìran tí ó wá sọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
16 Tedym przystąpił do jednego z tych, którzy tam stali, a pewnościm się dowiadywał od niego o tem wszystkiem, i powiedział mi, i wykład mów oznajmił mi.
Mo lọ bá ọ̀kan nínú àwọn tí ó dúró níbẹ̀, mo sì bi í léèrè òtítọ́ ìtumọ̀ nǹkan wọ̀nyí. “Ó sọ fún mi, ó sì túmọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún mi:
17 Te bestyje wielkie, których są cztery, są cztery królowie, którzy powstaną z ziemi.
‘Àwọn ẹranko ńlá mẹ́rin yìí, ni ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde ní ayé.
18 Ci ujmą królestwo świętych najwyższych miejsc, którzy posiąść mają królestwo aż na wieki, i aż na wieki wieczne.
Ṣùgbọ́n, ẹni mímọ́ ti Ọ̀gá-ògo ni yóò gba ìjọba náà, yóò sì jogún un rẹ títí láé àti títí láéláé.’
19 Tedym pragnął wziąć sprawę o bestyi czwartej, która była różna od wszystkich innych, bardzo straszna, której zęby były żelazne, a paznogcie jej miedziane; która pożerała i kruszyła, a ostatek nogami swemi deptała.
“Nígbà náà, ni mo fẹ́ mọ ìtumọ̀ òtítọ́ ẹranko kẹrin, tí ó yàtọ̀ sí àwọn yòókù, èyí tí ó dẹ́rùba ni gidigidi, tí ó ní eyín irin àti èékánná idẹ, ẹranko tí ó ń run tí ó sì ń pajẹ, tí ó sì ń fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀.
20 Także o onych rogach dziesięciu, które były na głowie jej, i o poślednim, który był wyrósł, przed którym wypadły trzy; o tym rogu mówię, który miał oczy i usta mówiące wielkie rzeczy, a na wejrzeniu był większy nad inne rogi.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì fẹ́ mọ̀ nípa ìwo mẹ́wàá orí rẹ̀ àti nípa ìwo yòókù tí ó jáde, nínú èyí tí mẹ́ta lára wọn ṣubú, ìwo tí ó ní ojú, tí ẹnu rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
21 I przypatrywałem się, a oto róg ten walczył z świętymi, i przemagał ich;
Bí mo ṣe ń wò, ìwo yìí ń bá àwọn ènìyàn mímọ́ jagun, ó sì borí i wọn,
22 Aż przyszedł Starodawny a podany jest sąd świętym najwyższych miejsc, a czas przyszedł, aby to królestwo święci otrzymali.
títí ẹni ìgbàanì fi dé, ó sì ṣe ìdájọ́ ìdáláre fún àwọn ẹni mímọ́ Ọ̀gá-ògo, àsìkò náà sì dé nígbà tí àwọn ẹni mímọ́ náà jogún ìjọba.
23 I rzekł tak: Bestyja czwarta, czwarte królestwo znaczy na ziemi, które będzie różne od wszystkich królestw, a pożre wszystkę ziemię, a podepcze a pokruszy ją;
“Ó ṣe àlàyé yìí fún mi pé, ‘Ẹranko kẹrin ni ìjọba kẹrin tí yóò wà ní ayé. Yóò yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ìjọba yòókù yóò sì pa gbogbo ayé run, yóò tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, yóò sì fọ́ ọ́ sí wẹ́wẹ́.
24 A dziesięć rogów to znaczy, że z królestwa onego dziesięć królów powstanie; a po nich powstanie pośledni, który będzie różny od pierwszych, i trzech królów poniży;
Ìwo mẹ́wàá ni ọba mẹ́wàá tí yóò wá láti inú ìjọba yìí. Lẹ́yìn tí wọn ní ọba mìíràn yóò dìde, ti yóò yàtọ̀ sí tí àwọn ti ìṣáájú, yóò sì borí ọba mẹ́ta.
25 A słowa przeciw Najwyższemu mówić będzie, i święte najwyższych miejsc zetrze; nadto będzie zamyślał, aby odmienił czasy i prawa, gdyż wydane będą w ręce jego aż do czasu i czasów, i pół czasu.
Yóò sọ̀rọ̀ odi sí Ọ̀gá-ògo, yóò sì pọ́n ẹni mímọ́ lójú, yóò sì gbèrò láti yí ìgbà àti òfin padà. A ó fi àwọn ẹni mímọ́ lé e lọ́wọ́ fún ìgbà díẹ̀, ní ọdún méjì àti ààbọ̀.
26 Potem zasiądzie sąd, a tam władzę jego odejmą, aby był zniszczony i wytracony aż do końca.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn onídàájọ́ yóò jókòó, nígbà náà ni a ó gba agbára rẹ̀, a ó sì pa á rùn pátápátá títí ayé.
27 A królestwo i władza, i dostojeństwo królewskie pod wszystkiem niebem dane będzie ludowi świętych najwyższych miejsc, którego królestwo będzie królestwo wieczne, a wszystkie zwierzchności jemu służyć i onego słuchać będą.
Nígbà náà, ni a ó gba ìjọba, agbára àti títóbi ìjọba rẹ̀ ní abẹ́ gbogbo ọ̀run, a ó sì fi fún àwọn ẹni mímọ́, àwọn ènìyàn Ọ̀gá-ògo. Ìjọba rẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba títí ayé, gbogbo aláṣẹ ni yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i, wọn yóò sì máa sìn ín.’
28 Aż dotąd koniec tych słów. A mnie Danijela myśli moje wielce zatrwożyły, a jasność moja zmieniła się przy mnie; wszakżem to słowo w sercu mojem zachował.
“Báyìí ni àlá náà ṣe parí, ọkàn èmi Daniẹli sì dàrú gidigidi, nítorí èrò ọkàn mi yìí, ojú mi sì yípadà ṣùgbọ́n mo pa ọ̀ràn náà mọ́ ní ọkàn mi.”