< Daniela 4 >

1 Nabuchodonozor król, wszystkim ludziom, narodom, i językom, którzy mieszkają po wszystkiej ziemi: Pokój się wam niech rozmnoży!
Nebukadnessari ọba, sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ àti onírúurú èdè, tí ó ń gbé ní àgbáyé. Kí àlàáfíà máa pọ̀ sí i fún un yín. Kí ẹ ṣe rere tó pọ̀!
2 Znaki i dziwy, które uczynił ze mną Bóg najwyższy, zdało mi się za rzecz przystojną opowiedzieć.
Ó jẹ́ ìdùnnú fún mi láti fi iṣẹ́ àmì àti ìyanu tí Ọlọ́run Ọ̀gá-Ògo ti ṣe fún mi hàn.
3 O jakoż są wielkie znaki jego! a dziwy jego jako mocne! królestwo jego królestwo wieczne, i władza jego od narodu do narodu.
Báwo ni àmì rẹ̀ ti tóbi tó,
4 Ja Nabuchodonozor żyjąc w pokoju w domu moim, i kwitnąc na pałacu moim,
Èmi Nebukadnessari wà ní ààfin mi, pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn àti àlàáfíà.
5 Miałem sen, który mię przestraszył, i myśli, którem miał na łożu mojem, a widzenia, którem widział, zatrwożyły mię.
Mo lá àlá kan èyí tí ó bà mí lẹ́rù. Nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, ìran tí ó jáde lọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
6 A przetoż wydany jest ode mnie dekret, aby przywiedziono przed mię wszystkich mędrców Babilońskich, którzyby mi wykład snu tego oznajmili.
Nígbà náà, ni mo pàṣẹ pé kí a mú gbogbo àwọn amòye Babeli wá, kí wọn wá sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
7 Tedy przyszli mędrcy i praktykarze Chaldejscy, i wieszczkowie; i powiedziałem im sen, a wszakże wykładu jego nie mogli mi oznajmić;
Nígbà tí àwọn apidán, àwọn apògèdè, àwọn awòràwọ̀ àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, mo sọ àlá náà fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
8 Aż na ostatek przyszedł przed mię Danijel, którego imię Baltazar według imienia boga mego, a w którym jest duch bogów świętych, a sen powiedziałem przed nim,
Ní ìkẹyìn Daniẹli wá síwájú mi, mo sì sọ àlá náà fún. (Ẹni tí à ń pè ní Belṣassari gẹ́gẹ́ bí orúkọ òrìṣà mi àti pé ẹ̀mí àwọn ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ̀.)
9 Mówiąc: Baltazarze, przedniejszy z mędrców! Ja wiem, iż duch bogów świętych jest w tobie, a żadna tajemnica nie jest ci trudna; widzenia snu mego, którym miał, posłuchaj, a wykład jego powiedz mi.
Mo wí pé, “Belṣassari, olórí àwọn amòye, èmi mọ̀ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ, kò sì ṣí àṣírí kan tí ó ṣòro jù fún ọ. Sọ àlá mi kí o sì túmọ̀ rẹ̀ fún mi.
10 Te są widzenia, którem widział na łożu mojem: Widziałem, a oto drzewo w pośrodku ziemi, którego wysokość zbytnia była.
Èyí ni ìran náà tí mo rí nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, mo rí igi kan láàrín ayé, igi náà ga gidigidi.
11 Wielkie było ono drzewo i mocne, a wysokość jego dosięgała nieba, a okazałe było aż do granic wszystkiej ziemi;
Igi náà tóbi, ó sì lágbára, orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run; a sì rí i títí dé òpin ayé.
12 Gałęzie jego piękne, a owoc jego obfity, i pokarm dla wszystkich był na niem; pod sobą dawało cień zwierzowi polnemu, a na gałęziach jego mieszkało ptastwo niebieskie, a z niego miało pożywienie wszelkie ciało.
Ewé rẹ̀ lẹ́wà, èso rẹ̀ sì pọ̀, ó sì ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn. Abẹ́ ẹ rẹ̀ ni àwọn ẹranko igbó fi ṣe ibùgbé, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé ní ẹ̀ka rẹ̀, nínú rẹ̀ ni gbogbo alààyè ti ń jẹ.
13 Widziałem nadto w widzeniach moich na łożu mojem, a oto stróż i Święty z nieba zstąpiwszy,
“Lórí ibùsùn mi, mo rí ìran náà, olùṣọ́ kan dúró síwájú u mi, àní ẹni mímọ́ kan, ó ń bọ̀ wá láti ọ̀run
14 Wołał ze wszystkiej mocy, i tak rzekł: Podrąbcie to drzewo, i obetnijcie gałęzie jego, a otłuczcie liście jego, i rozrzućcie owoc jego; niech się rozbieży zwierz, który jest pod niem, i ptastwo z gałęzi jego;
ó kígbe sókè wí pé, ‘Gé igi náà kí o sì gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò; gbọn ewé rẹ̀ ká, kí o sì fọ́n èso rẹ̀ dànù. Jẹ́ kí àwọn ẹranko tí ó wà lábẹ́ rẹ̀ sá àti àwọn ẹyẹ tí ó wà ní ẹ̀ka rẹ̀ kúrò.
15 Wszakże pień korzenia jego w ziemi zostawcie, a niech będzie związany łańcuchem żelaznym i miedzianym na trawie polnej, aby rosą niebieską był skrapiany, a z zwierzętami niech się pasie w trawie ziemskiej;
Ṣùgbọ́n fi kùkùté àti gbòǹgbò rẹ̀ tí a fi irin àti idẹ dè ṣẹ́kù sórí ilẹ̀ àti sí orí koríko igbó. “‘Jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, kí ó sì jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà pẹ̀lú àwọn ẹranko igbó láàrín ilẹ̀ ayé.
16 Serce jego od człowieczego niech się odmieni, a serce zwierzęce niech mu dane będzie, a siedm lat niech pominą nad nim.
Jẹ́ kí ọkàn rẹ̀ kí ó yí padà kúrò ní ti ènìyàn, kí a sì fún un ní ọkàn ẹranko, títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.
17 Ta rzecz według wyroku stróżów, a to żądanie według mowy świętych stanie się, aż do tego przyjdzie, że poznają ludzie, iż Najwyższy panuje nad królestwem ludzkiem, a daje je, komu chce, a najpodlejszego z ludzi stanowi nad niem.
“‘Olùṣọ́ ni ó gbé ìpinnu náà jáde, àṣẹ sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹni mímọ́, kí gbogbo alààyè le mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo ni olórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹnikẹ́ni tí ó wù ú, òun sì ń gbé onírẹ̀lẹ̀ lórí i wọn.’
18 Ten sen widziałem ja król Nabuchodonozor; a ty, Baltazarze! powiedz wykład jego, gdyż wszyscy mędrcy królestwa mego nie mogli mi tego wykładu oznajmić; ale ty możesz, bo duch bogów świętych jest w tobie.
“Èyí ni àlá tí èmi Nebukadnessari ọba lá. Ní ìsinsin yìí ìwọ Belṣassari, sọ ohun tí ó túmọ̀ sí fún mi, nítorí kò sí amòye kan ní ìjọba mi, tí ó lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi. Ṣùgbọ́n ìwọ lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀, nítorí tí ẹ̀mí Ọlọ́run mímọ́ wà ní inú rẹ.”
19 Tedy Danijel, którego imię Baltazar, zdumiewał się przez jednę godzinę, a myśli jego trwożyły go. A odpowiadając król rzekł: Baltazarze! sen i wykład jego niech cię nie trwoży. Odpowiedział Baltazar, i rzekł: Panie mój! ten sen niech przyjdzie na tych, którzy cię nienawidzą, a wykład jego na nieprzyjaciół twoich.
Nígbà náà ni Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belṣassari) páyà gidigidi fún ìgbà díẹ̀, èrò inú rẹ̀ sì bà á lẹ́rù. Nígbà náà ni ọba wí pé, “Belṣassari, má ṣe jẹ́ kí àlá náà tàbí ìtumọ̀ rẹ̀ kí ó dẹ́rùbà ọ́.” Belṣassari sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, kí àlá yìí jẹ́ ti àwọn ọ̀tá a rẹ, kí ìtumọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ti àwọn aṣòdì sí.
20 Drzewo, któreś widział rosłe i mocne, którego wysokość dosięgała nieba, a które okazałe było wszystkiej ziemi,
Igi tí ìwọ rí, tí ó dàgbà, tí ó sì lágbára, tí orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run, tí ó lẹ́wà àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso, tí ó ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn, tí ó ṣe ààbò lórí ẹranko igbó àti èyí tí ẹ̀ka rẹ̀ pèsè ààyè fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
21 Którego gałąź piękna, a owoc jego obfity, a pokarm dla wszystkich na niem, pod którem mieszkał zwierz polny, a na gałęziach jego przebywało ptastwo niebieskie,
Èyí tí ewé e rẹ̀ lẹ́wà, tí èso rẹ̀ si pọ̀, nínú èyí tí oúnjẹ sì wà fún gbogbo ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí àwọn ẹranko igbó ń gbé, lórí ẹ̀ka èyí ti àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní ibùgbé wọn.
22 Tyś jest tym, o królu! któryś się rozwielmożył i zmocnił, a wielkość twoja urosła, i podniosła się aż do nieba, a władza twoja aż do kończyn ziemi.
Ìwọ ọba ni igi náà, ìwọ ti dàgbà, o sì lágbára, títóbi i rẹ ga ó sì kan ọ̀run, ìjọba rẹ sì gbilẹ̀ títí dé òpin ayé.
23 A iż król widział stróża i Świętego zstępującego z nieba a mówiącego: Podrąbcie to drzewo, a zepsujcie je, wszakże pień i z korzeniem jego w ziemi zostawcie, aby rosą niebieską był skrapiany a z zwierzętami polnemi niech się pasie, ażby się wypeł niło siedm lat nad nim;
“Ìwọ ọba, rí ìránṣẹ́ ẹni mímọ́ kan, tí ó ń bọ̀ láti ọ̀run ó sì sọ pé, ‘Gé igi náà kí o sì run ún, ṣùgbọ́n fi kùkùté rẹ tí a dè pẹ̀lú irin àti idẹ sílẹ̀ nínú koríko igbó, nígbà tí gbòǹgbò rẹ̀ sì wà nínú ilẹ̀ kí o sì jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sórí i rẹ̀, jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà láàrín ẹranko búburú títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.’
24 Tenci jest wykład, o królu! i ten dekret Najwyższego, który wyszedł na króla, pana mego;
“Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ ọba àti àṣẹ tí Ọ̀gá-ògo mú wá sórí ọba olúwa mi.
25 Bo cię wyrzucą od ludzi, a z zwierzem polnym będzie mieszkanie twoje, a trawą jako wół paść się będziesz, a rosą niebieską skrapiany będziesz, aż się wypełni siedm lat nad tobą, dokądbyś nie poznał, że Najwyższy panuje nad królestwem ludzkiem, a że je daje, komu chce.
A ó lé ọ jáde kúrò láàrín ènìyàn, ìwọ yóò sì máa gbé láàrín ẹranko búburú, ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run yóò sì sẹ̀ sára rẹ. Ìgbà méje yóò sì kọjá lórí rẹ, títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
26 A iż rozkazano zostawić pień i z korzeniem onego drzewa, znaczy, że królestwo twoje tobie zostanie, gdy poznasz, że niebiosa panują.
Bí wọ́n ṣe pàṣẹ pé kí wọn fi kùkùté àti gbòǹgbò igi náà sílẹ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé a ó dá ìjọba rẹ padà fún ọ lẹ́yìn ìgbà tí o bá ti mọ̀ wí pé, Ọ̀run jẹ ọba.
27 Przetoż o królu! rada moja niech ci się podoba, a grzechy twoje przerwij sprawiedliwością, a nieprawości twoje miłosierdziem nad utrapionym, owa snać stanie się przedłużenie pokoju twego.
Nítorí náà ọba, jẹ́ kí ìmọ̀ràn mi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọ, kọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ sílẹ̀ kí o sì ṣe rere, àti ìwà búburú rẹ nípa ṣíṣe àánú fún àwọn tálákà. Ó lè jẹ́ pé nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe rere.”
28 Wszystko to przyszło na króla Nabuchodonozora;
Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí Nebukadnessari ọba.
29 Bo po wyjściu dwunastu miesięcy, przechodząc się w Babilonie na pałacu królewskim,
Lẹ́yìn oṣù kejìlá, bí ọba ṣe ń rìn káàkiri lórí òrùlé ààfin ìjọba Babeli,
30 Mówił król i rzekł: Izali nie to jest on Babilon wielki, którym ja w sile mocy mojej zbudował, aby był stolicą królestwa i ku ozdobie sławy mojej?
ó sọ pé, “Èyí ha kọ́ ni Babeli ńlá tí mo kọ́ gẹ́gẹ́ bí ilé ọba, nípa agbára à mi àti fún ògo ọláńlá à mi?”
31 A gdy jeszcze ta mowa była w ustach królewskich, oto głos z nieba przyszedł mówiąc: Tobie się mówi, królu Nabuchodonozorze! że królestwo twoje odeszło od ciebie;
Bí ọba ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ náà lọ́wọ́ ohùn kan wá láti ọ̀run, “Ìwọ Nebukadnessari ọba, ìwọ ni a ti pàṣẹ nípa rẹ̀, a ti gba ìjọba à rẹ kúrò ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.
32 I od ludzi wyrzucą cię, a z zwierzem polnym będzie mieszkanie twoje; trawą jako wół paść się będziesz, ażby się wypełniło siedm lat nad tobą, dokądbyś nie poznał, że Najwyższy panuje nad królestwem ludzkiem, a że je daje, komu chce.
A ó lé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, ìwọ yóò sì lọ máa gbé àárín àwọn ẹranko igbó; ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìgbà méje yóò kọjá lórí i rẹ títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn àti pé ó ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.”
33 Tejże godziny wypełniło się ono słowo nad Nabuchodonozorem; bo go wyrzucono od ludzi, a trawę jadał jako wół, a rosą niebieską ciało jego skrapiane było, aż na nim włosy urosły jako pierze orle, a paznogcie jego jako pazury u ptaków.
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni ohun tí a sọ nípa Nebukadnessari ṣẹlẹ̀ sí i. A lé e kúrò láàrín ènìyàn, ó sì ń jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run sì ń sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí irun orí rẹ̀ fi gùn bí i ti ìyẹ́ ẹyẹ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dàbí i ti ẹyẹ.
34 A po skończeniu onych dni podniosłem ja Nabuchodonozor w niebo oczy moje, a rozum mój do mnie się zaś wrócił, i błogosławiłem Najwyższego, a Żyjącego na wieki chwaliłem i wysławiałem; bo władza jego władza wieczna, a królestwo jego od narodu do narodu.
Ní òpin ìgbà náà, èmi, Nebukadnessari gbé ojú mi sókè sí ọ̀run, iyè mi sì sọjí. Mo fi ọpẹ́ fún Ọ̀gá-ògo; mo fi ọlá àti ògo fún ẹni tí ó wà láéláé.
35 A wszyscy obywatele ziemi jako za nic poczytani są. Według woli swojej postępuje, z wojskiem niebieskiem i z obywatelami ziemi, a niemasz, ktoby wstręt uczynił ręce jego i rzekł mu: Cóż to czynisz?
Gbogbo àwọn ènìyàn ayé
36 Tegoż czasu rozum mój wrócił się do mnie, a do sławy królestwa mego ozdoba moja, i dostojność moja wróciła się do mnie; nadto hetmani moi i książęta moi szukali mię, a na królestwie mojem zmocniłem się, i wielmożność większa mi jest przydana.
Ní àkókò kan náà, iyè mi padà, ọlá àti ògo dídán mi padà tọ̀ mí wá fún ògo ìjọba mi. Àwọn ìgbìmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá mi, wá mi rí, wọ́n sì dá mi padà sórí ìjọba mi, mo sì di alágbára ju ti ìṣáájú lọ.
37 A tak teraz ja Nabuchodonozor chwalę, i wywyższam i wysławiam króla niebieskiego, którego wszystkie sprawy są prawdą, a ścieszki jego sądem, a który chodzących w hardości poniżyć może.
Báyìí, èmi, Nebukadnessari fi ọpẹ́, mo sì gbé Ọlọ́run ga, mo sì fi ògo fún ọba ọ̀run, nítorí pé gbogbo nǹkan tí ó ṣe ló dára, gbogbo ọ̀nà rẹ̀ sì tọ́. Gbogbo àwọn tó sì ń rìn ní ìgbéraga ni ó le rẹ̀ sílẹ̀.

< Daniela 4 >