< Daniela 2 >
1 Roku wtórego królowania Nabuchodonozora miał Nabuchodonozor sen, i strwożył się duch jego, i przerwał mu się sen jego.
Ní ọdún kejì ìjọba Nebukadnessari, ó lá àlá, èyí tí ó mú kí ọkàn an rẹ̀ dàrú, kò sì le è sùn.
2 Tedy król rozkazał zwołać mędrców, i praktykarzy, i czarnoksiężników, i Chaldejczyków, aby oznajmili królowi sen jego; którzy przyszli i stanęli przed obliczem królewskiem.
Nígbà náà ni ọba yára pe àwọn onídán, àwọn aláfọ̀ṣẹ, àwọn oṣó àti àwọn awòràwọ̀; àwọn tó ní ìmọ̀ àti àṣírí i títúmọ̀ ìràwọ̀, ọba pè wọ́n kí wọn wá sọ àlá tí ó lá. Nígbà tí wọ́n dé, tí wọ́n dúró níwájú ọba,
3 I rzekł król do nich: Miałem sen, i strwożył się duch mój, tak, że nie wiem, co mi się śniło.
ọba sì wí fún wọn pé, “Mo ti lá àlá kan èyí tí ó mú kí ọkàn mi dàrú, mo sì fẹ́ mọ ìtumọ̀ àlá náà.”
4 Tedy odpowiedzieli Chaldejczycy królowi po syryjsku: Królu, żyj na wieki! Powiedz sen sługom twoim, a oznajmiemyć wykład jego.
Nígbà náà ni àwọn awòràwọ̀ dá ọba lóhùn ní èdè Aramaiki pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Sọ àlá yìí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ àwa yóò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọ.”
5 Odpowiedział król i rzekł do Chaldejczyków: Ta rzecz już mi z pamięci wypadła; jeźli mi nie oznajmicie snu i wykładu jego, na sztuki rozsiekani będziecie, a domy wasze w gnojowisko obrócone będą;
Ọba dá àwọn awòràwọ̀ lóhùn pé, “Ohun náà ti kúrò lórí mi, tí ẹ̀yin kò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò gé e yín sí wẹ́wẹ́, ilé e yín yóò sì di ààtàn.
6 Ale jeźli mi sen i wykład jego oznajmicie, dary i upominki i uczciwość wielką odniesiecie odemnie; przetoż sen i wykład jego oznajmijcie mi.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò fún un yín ní ẹ̀bùn, ọrẹ àti ọláńlá tí ó pọ̀. Nítorí náà, ẹ sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi.”
7 Odpowiedzieli powtóre, i rzekli: Król niech powie sen sługom swoim, a wykład jego oznajmiemy.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, “Wọ́n tún dáhùn pé, jẹ́ kí ọba sọ àlá náà fún ìránṣẹ́ rẹ̀, àwa yóò sì túmọ̀ rẹ̀.”
8 Odpowiedział król, i rzekł: Zaiste wiem, że umyślnie odwłaczacie, bacząc, że mi ten sen z pamięci wyszedł.
Nígbà náà ni ọba sọ pé, “Èmi mọ̀ dájú wí pé ẹ̀yin fẹ́ fi àkókò ṣòfò nítorí pé ẹ̀yin ti mọ̀ pé nǹkan ti lọ ní orí mi.
9 Jeźliże mi snu nie oznajmicie, pewny jest o was dekret, boście rzecz kłamliwą i przewrotną umyślili mówić przedemną, ażby czas przeminął; przetoż mi sen powiedzcie, a dowiem się, będziecieli mogli wykład jego oznajmić.
Tí ẹ̀yin kò bá lè sọ àlá mi, ìjìyà kan ṣoṣo ló wà fún un yín. Ẹ̀yin ti gbèrò láti pa irọ́ àti láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ ti ó lè si ni lọ́nà fún mi, títí tí nǹkan yóò fi yí wọ́. Nítorí náà ẹ rọ́ àlá náà fún mi, èmi yóò sì mọ̀ pé ẹ lè túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
10 Odpowiedzieli Chaldejczycy królowi, i rzekli: Niemasz człowieka na ziemi, któryby tę rzecz królowi oznajmić mógł; dotego żaden król, książę albo pan o taką się rzecz nie pytał żadnego mędrca, i praktykarza, i Chaldejczyka.
Àwọn awòràwọ̀ sì dá ọba lóhùn pé, “Kò sí ènìyàn kan ní ayé tí ó lè sọ nǹkan tí ọba béèrè! Kò sí ọba náà bí ó ti wù kí ó tóbi àti kí ó lágbára tó, tí í béèrè irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tàbí awòràwọ̀.
11 Bo rzecz, o którą się król pyta, trudna jest, a niemasz nikogo, coby ją mógł królowi oznajmić, oprócz bogów, którzy nie mieszkają z ludźmi.
Nǹkan tí ọba béèrè yìí ṣòro púpọ̀. Kò sí ẹni tí ó lè fihan ọba àfi àwọn òrìṣà, tí wọn kì í gbé láàrín ènìyàn.”
12 Z tej przyczyny zasrożył się król, i rozgniewał się bardzo, a rozkazał wytracić wszystkich mędrców Babilońskich.
Èyí mú kí ọba bínú, ó sì kanra, nítorí náà ó pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn amòye Babeli run.
13 A gdy wyszedł dekret, aby mordowano mędrców, szukano i Danijela i towarzyszów jego, aby ich zamordowano.
Nítorí náà àṣẹ yìí jáde lọ wí pé kí a pa àwọn amòye, wọ́n ránṣẹ́ pe Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti pa wọ́n.
14 tedy Danijel odpowiedział mądrze i roztropnie Aryjochowi, hetmanowi nad żołnierzami królewskimi, który wyszedł, aby zabijał mędrców Babilońskich;
Nígbà tí Arioku, olórí àwọn olùṣọ́ ọba, jáde láti lọ pa àwọn amòye Babeli, Daniẹli sọ̀rọ̀ fún un pẹ̀lú ọgbọ́n àti òye.
15 A odpowiadając rzekł do Aryjocha, hetmana królewskiego: Przecz ten dekret tak prędko wyszedł od króla? I oznajmił tę rzecz Aryjoch Danijelowi.
Ó béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùṣọ́ ọba wí pé, “Èéṣe tí àṣẹ ọba fi yá kánkán bẹ́ẹ̀?” Arioku sì ṣe àlàyé ọ̀rọ̀ náà fún Daniẹli.
16 Skąd Danijel wszedł, i prosił króla, aby mu dał czas na oznajmienie wykładu królowi.
Nígbà náà ni Daniẹli wọlé tọ ọba lọ, ó sì tọrọ kí ọba fún òun ní ààyè, òun yóò fi ìtumọ̀ àlá náà hàn fún ọba.
17 Odszedłszy tedy Danijel do domu swego, oznajmił tę rzecz Ananijaszowi, Misaelowi i Azaryjaszowi, towarzyszom swoim,
Nígbà náà ni Daniẹli padà lọ sí ilé e rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
18 Aby o miłosierdzie prosili Boga niebieskiego dla tej tajemnicy, żeby nie zginęli Danijel i towarzysze jego z pozostałymi mędrcami Babilońskimi.
Ó sọ fún wọn pé kí wọn béèrè fún àánú Ọlọ́run, Olúwa ọ̀run, nítorí àṣírí yìí, kí Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ má ba ṣègbé pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n Babeli yòókù, tí ó wà ní Babeli.
19 Tedy objawiona jest Danijelowi w widzeniu nocnem ta tajemnica, za co Danijel błogosławił Bogu niebieskiemu.
Ní òru, àṣírí náà hàn sí Daniẹli ní ojú ìran. Nígbà náà ni Daniẹli fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run
20 A mówiąc Danijel rzekł: Niech będzie imię Boże błogosławione od wieku aż na wieki; albowiem mądrość i moc jego jest;
Daniẹli wí pé: “Ọpẹ́ ni fún orúkọ Ọlọ́run láé àti láéláé; tirẹ̀ ni ọgbọ́n àti agbára.
21 On sam odmienia czasy i chwile; zrzuca królów i stanowi królów; daje mądrość mądrym, a umiejętnym rozum;
Ó yí ìgbà àti àkókò padà; ó mú ọba jẹ, ó ń mú wọn kúrò. Ó fún àwọn amòye ní ọgbọ́n àti ìmọ̀ fún àwọn tí ó ní òye.
22 On odkrywa rzeczy głębokie i skryte, zna, co jest w ciemnościach, a światłość z nim mieszka.
Ó fi ohun ìjìnlẹ̀ àti àṣírí hàn; ó mọ ohun tí ó pamọ́ nínú òkùnkùn àti ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìmọ́lẹ̀ wà.
23 Ciebie ja, o Boże ojców moich! wysławiam i chwalę, żeś mi dał mądrość i moc, owszem, żeś mi teraz oznajmił to, o cośmy cię prosili; boś nam sen królewski oznajmił.
Mo dúpẹ́, mo sì fi ìyìn fún ọ, ìwọ Ọlọ́run àwọn baba mi: ó ti fún mi ní ọgbọ́n àti agbára ó ti fi àwọn nǹkan tí a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ hàn fún mi nítorí tí ìwọ ti fi àlá ọba hàn wá.”
24 Dla tego Danijel wszedł do Aryjocha, którego był postanowił król, aby wytracił mędrców Babilońskich; a przyszedłszy tak rzekł do niego: Nie trać mędrców Babilońskich, wprowadź mię do króla, a ja ten wykład królowi oznajmię.
Nígbà náà ni Daniẹli tọ́ Arioku lọ, ẹni tí ọba yàn láti pa àwọn amòye Babeli run, Daniẹli wí fún un pé, “Má ṣe pa àwọn amòye Babeli run. Mú mi lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, èmi yóò sísọ ìtumọ̀ àlá rẹ̀ fún un.”
25 Tedy Aryjoch z kwapieniem wprowadził Danijela do króla i tak mu rzekł: Znalazłem męża z więźniów synów Judzkich, który ten wykład królowi oznajmi.
Lẹ́sẹ̀kan náà, Arioku yára mú Daniẹli lọ sí iwájú ọba, ó sọ fún ọba pé, “Èmi ti rí ọkùnrin kan lára àwọn àjèjì tí ó wá láti Juda, ẹni tí ó lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.”
26 Odpowiedział król, i rzekł Danijelowi, któremu imię było Baltazar: Izali mnie ty możesz oznajmić sen, którym widział, i wykład jego?
Ọba béèrè lọ́wọ́ Daniẹli ẹni tí a tún ń pè ní Belṣassari pé, “Ṣé ìwọ lè sọ ohun tí mo rí nínú àlá mi àti ìtumọ̀ ọ rẹ̀ fún mi?”
27 Odpowiedział Danijel królowi, i rzekł: Tajemnicy, o której się król pyta, mędrcy, praktykarze, czarnoksiężnicy i wieszczkowie królowi oznajmić nie mogą;
Daniẹli dá ọba lóhùn pé, “Kò sí awòràwọ̀ kan, apògèdè, onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tí ó lè ṣe àlàyé àṣírí tí ọba béèrè fún
28 A wszakże jest Bóg na niebie, który objawia tajemnice, a on okazał królowi Nabuchodonozorowi, co ma być potomnych dni. Sen twój i widzenia, któreś widział na łożu twojem, te są:
ṣùgbọ́n, Ọlọ́run kan ń bẹ ní ọ̀run tí ó ń fi àṣírí hàn. Ó ti fihan ọba Nebukadnessari, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ọjọ́. Àlá àti ìran tí o rí nígbà tí o dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ ni ìwọ̀nyí:
29 Tobie o królu! przychodziło na myśl na łożu twojem, coby miało być na potem, a ten, który odkrywa tajemnice, oznajmił ci to, co ma być.
“Ọba, bí ìwọ ṣe sùn sórí ibùsùn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn rẹ ń ro àwọn ohun tó ń bọ̀, olùfihàn àṣírí ń fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ fún ọ.
30 Mnie też nie przez mądrość, któraby przy mnie była nad wszystkich ludzi, tajemnica ta objawiona jest, ale przez modlitwę, aby ten wykład królowi oznajmiony był, a iżbyś się myśli serca twego dowiedział.
Ṣùgbọ́n fún èmi, a fi àṣírí yìí hàn mí, kì í ṣe pé mo ní ọgbọ́n tí ó pọ̀ ju ti alààyè kankan lọ, ṣùgbọ́n nítorí kí ọba lè mọ ìtumọ̀ àlá àti kí ó lè mọ ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ̀.
31 Tyś, królu! widział, a oto obraz jeden wielki( obraz to był wielki, a blask jego znaczny )stał przeciwko tobie, który na wejrzeniu był straszny.
“Ìwọ ọba ń wo, ère ńlá kan tí ó dúró níwájú rẹ, ère náà ga, ó sì dára láti wò, ìrísí i rẹ̀ ba ni lẹ́rù jọjọ.
32 Tego obrazu głowa była ze złota szczerego, piersi jego i ramiona jego ze srebra, brzuch jego i biodra jego z miedzi;
Orí ère náà jẹ́ kìkì wúrà, àyà rẹ̀ àti ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ fàdákà, inú àti ẹ̀gbẹ́ itan rẹ̀ jẹ́ idẹ,
33 Golenie jego z żelaza, nogi jego częścią z żelaza, a częścią z gliny.
àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ irin, àwọn àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀.
34 Patrzałeś na to, aż odcięty był kamień, który nie bywał w ręku, a uderzył ten obraz w nogi jego żelazne i gliniane, i skruszył je.
Bí ó ṣe ń wò, òkúta kan wá, tí kò wá láti ọwọ́ ẹnìkankan. Ó kọlu ère náà ní àtẹ́lẹsẹ̀ irin àti amọ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́.
35 Tedy się skruszyło społem żelazo, glina, miedź, srebro i złoto, a było to wszystko jako plewy na bojewisku w lecie, i rozniósł to wiatr, tak, że ich na żadnem miejscu nie znaleziono; a kamień on, który uderzył o obraz, stał się górą wielką i napełnił wszystkę ziemię.
Nígbà náà ni irin, amọ̀, idẹ, fàdákà àti wúrà fọ́ sí wẹ́wẹ́ lẹ́sẹ̀kan náà, ó sì dàbí ìyàngbò tí a fẹ́ kúrò lórí ọkà ní àsìkò ẹ̀ẹ̀rùn. Afẹ́fẹ́ gbé gbogbo rẹ̀ lọ láìṣẹ́ku ọ̀kan mọ́, òkúta tí ó fọ́ ère náà sì di òkè ńlá, ó sì gba gbogbo ayé.
36 Tenci jest sen. Wykład też jego powiemy przed królem:
“Èyí ni àlá náà, nígbà yìí ni a ó wá sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọba.
37 Tyś, królu! królem królów; bo tobie Bóg niebieski królestwo, moc, potęgę i sławę dał;
Ìwọ ọba jẹ́ ọba àwọn ọba. Ọlọ́run ọ̀run ti fi ìjọba agbára, títóbi àti ògo fún ọ;
38 I wszystko, gdzie jedno mieszkają synowie ludzcy, zwierz polny i ptastwo niebieskie, dał w rękę twoję i postanowił cię panem nad tem wszystkiem, a tyś jest tą głową złotą.
ní ọwọ́ rẹ ló fi gbogbo ènìyàn, àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run sí. Ní ibi gbogbo tí wọ́n ń gbé, ó ti fi ọ́ ṣe olórí i wọn. Ìwọ ni orí wúrà náà.
39 Ale po tobie powstanie królestwo insze, podlejsze niżeli twoje, a inne królestwo trzecie miedziane, które panować będzie po wszystkiej ziemi.
“Lẹ́yìn èyí ni ìjọba mìíràn yóò dìde, tí kò ní lágbára tó tìrẹ, lẹ́yìn in rẹ̀, ìjọba kẹta tí yóò dàbí idẹ, èyí tí yóò jẹ ọba lórí i gbogbo ayé.
40 A królestwo czwarte będzie mocne jako żelazo; bo jako żelazo łamie i kruszy wszystko, jako żelazo, mówię, kruszy wszystko, tak i ono połamie i pokruszy wszystko.
Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ìjọba kẹrin yóò wà, ìjọba náà yóò lágbára bí irin, gẹ́gẹ́ bí irin ti í fọ́, tó sì ń lọ gbogbo nǹkan àti bí irin ti í fọ́ nǹkan sí wẹ́wẹ́, bẹ́ẹ̀ ni yóò fọ́ tí yóò sì lọ gbogbo àwọn tókù.
41 A iżeś widział nogi, i palce częścią z gliny garncarskiej a częścią z żelaza, królestwo rozdzielone znaczy, w którem będzie nieco mocy żelaznej, tak jakoś widział żelazo zmięszane z skorupą glinianą;
Bí o ṣe rí i tí àtẹ́lẹsẹ̀ àti ọmọ ìka ẹsẹ̀ jẹ́ apá kan amọ̀ àti apá kan irin, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yóò ṣe pín; ṣùgbọ́n yóò sì ní agbára irin díẹ̀ nínú rẹ̀, bí ó ṣe rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀.
42 Ale palce nóg częścią z żelaza a częścią z gliny znaczą królestwo częścią mocne a częścią do skruszenia snadne.
Bí ọmọ ìka ẹsẹ̀ ṣe jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yìí yóò lágbára lápákan tí kò sì ní lágbára lápákan.
43 A iżeś widział żelazo zmięszane z skorupą glinianą, znaczy, że się spokrewnią z sobą ludzie; a wszakże nie będzie się trzymał jeden drugiego, tak jako żelazo nie może się zmięszać z gliną.
Gẹ́gẹ́ bí o ti rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀, báyìí ni àwọn ènìyàn yóò ṣe dàpọ̀ mọ́ ara wọn ní ti ìgbéyàwó, ṣùgbọ́n wọn kò ní wà ní ìṣọ̀kan, bí irin kò ṣe dàpọ̀ mọ́ amọ̀.
44 Ale za dni tych królów wzbudzi Bóg niebieski królestwo, które na wieki zepsute nie będzie, a królestwo to na inszy naród nie spadnie, ale ono połamie, i koniec uczyni tym wszystkim królestwom, a samo stać będzie na wieki.
“Ní àsìkò àwọn ọba náà, Ọlọ́run ọ̀run yóò gbé ìjọba èyí tí kò le è bàjẹ́ kalẹ̀, èyí tí a kò ní fi lé ẹlòmíràn lọ́wọ́. Yóò sì run gbogbo ìjọba, yóò sì mú wọn wá sí òpin, ṣùgbọ́n ìjọba yìí yóò dúró láéláé.”
45 Tak jakoś widział, iż z góry odcięty był kamień, który nie bywał w ręku, a skruszył żelazo, miedź, glinę, srebro i złoto, przez to Bóg wielki królowi oznajmił, co ma być na potem; i prawdziwy jest ten sen, i wierny wykład jego.
Gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i pé a gé òkúta láti ara òkè, láì ti ọwọ́ ẹnikẹ́ni wá, òkúta èyí tí ó fọ́ irin, idẹ, amọ̀, fàdákà àti wúrà sí wẹ́wẹ́. “Ọlọ́run tí ó tóbi ti fihan ọba, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú. Òtítọ́ ni àlá náà, bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ rẹ̀ ṣe é gbẹ́kẹ̀lé.”
46 Tedy król Nabuchodonozor padł na oblicze swoje, i ukłonił się Danijelowi, a rozkazał, aby mu ofiarę i kadzenia ofiarowali.
Nígbà náà, ni Nebukadnessari ọba dojúbolẹ̀ níwájú u Daniẹli ó sì fi orí balẹ̀ fún un, ó sì pàṣẹ pé kí wọn kí ó mu ọrẹ àti òórùn tùràrí fún Daniẹli.
47 Tedy odpowiadając król Danijelowi rzekł: Zaprawdę Bóg wasz jest Bogiem bogów, a Panem królów, który odkrywa tajemnice, ponieważeś mógł objawić tę tajemnicę.
Ọba wí fún Daniẹli pé, “Dájúdájú Ọlọ́run rẹ ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn ọba gbogbo àti olùfihàn àwọn àṣírí, nítorí tí ìwọ lè fi àṣírí yìí hàn.”
48 Zatem król zacnie wywyższył Danijela, i darów wielkich i wiele dał mu, i uczynił go panem nad wszystką krainą Babilońską, i książęciem nad przełożonymi i nad wszystkimi mędrcami Babilońskimi.
Nígbà náà ni ọba gbé Daniẹli ga, ó sì fún un ní ẹ̀bùn ńlá tí ó pọ̀. Ó sì fi ṣe olórí i gbogbo agbègbè ìjọba Babeli àti olórí gbogbo àwọn amòye Babeli.
49 Ale Danijel prosił króla, aby przełożył nad sprawami krainy Babilońskiej Sadracha, Mesacha i Abednego; a Danijel bywał w bramie królewskiej.
Daniẹli béèrè lọ́wọ́ ọba, ó sì yan Ṣadraki, Meṣaki, àti Abednego gẹ́gẹ́ bí alábojútó ìgbèríko Babeli ṣùgbọ́n Daniẹli fúnra rẹ̀ wà ní ààfin ọba.