< Daniela 12 >

1 Tego czasu powstanie Michał, książę wielki, który się zastawia za synami ludu twego; a będzie czas uciśnienia, jakiego nie było, jako narody poczęły być, aż do tego czasu; tego, mówię, czasu wyswobodzony będzie lud twój, ktokolwiek znaleziony będzie napisany w księgach.
“Ní àkókò náà, ni Mikaeli, ọmọ-aládé ńlá, ẹni tí o ń dáàbò bo àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò dìde. Àkókò ìpọ́njú yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí láti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè títí di àkókò náà. Ṣùgbọ́n ní àkókò náà àwọn ènìyàn rẹ̀, gbogbo àwọn tí a bá ti rí orúkọ wọn nínú ìwé ni a ó gbàlà.
2 A wiele z tych, którzy śpią w prochu ziemi, ocucą się, jedni ku żywotowi wiecznemu, a drudzy na pohańbienie i na wzgardę wieczną.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn tí ó sùn nínú erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò jí: àwọn mìíràn sí ìyè àìnípẹ̀kun, àwọn tókù sí ìtìjú àti sí ẹ̀gàn àìnípẹ̀kun.
3 Ale ci, którzy innych nauczają, świecić się będą jako światłość na niebie, a którzy wielu ku sprawiedliwości przywodzą, jako gwiazdy na wieki wieczne.
Àwọn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n yóò máa tàn bí ìmọ́lẹ̀ ọ̀run, àti àwọn tí ó ń tọ́nisọ́nà sí òdodo, yóò máa tàn bí ìràwọ̀ láé àti láéláé.
4 Ale ty, Danijelu! zamknij te słowa, i zapieczętuj tę księgę aż do czau naznaczonego; bo to wiele ich przebieży, a rozmnoży się umiejętność.
Ṣùgbọ́n ìwọ Daniẹli, pa ìwé náà dé kí o sì pa ọ̀rọ̀ ọ rẹ̀ mọ́ títí àkókò ìgbẹ̀yìn. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò máa lọ sí ìhín sí ọ̀hún láti jẹ́ kí ìmọ̀ wọn di púpọ̀.”
5 I widziałem ja Danijel, a oto drudzy dwaj stali, jeden stąd nad brzegiem rzeki, a drugi z onąd nad drugim brzegiem rzeki;
Nígbà náà, ni èmi Daniẹli, wò, ní iwájú mi àwọn méjì mìíràn dúró, ọ̀kan dúró sí apá ìhín ní etí bèbè odò ẹnìkan náà ní apá òdìkejì ọ̀hún etí i bèbè.
6 I rzekł do męża obleczonego w szatę lnianą, który stał nad wodą onej rzeki: Kiedyż przyjdzie koniec tym dziwnym rzeczom?
Ọ̀kan lára wọn sọ fún ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò pé, “Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó kí àwọn nǹkan ìyanu wọ̀nyí tó wá sí ìmúṣẹ?”
7 I usłyszałem tego męża obleczonego w szatę lnianą, który stał nad wodą onej rzeki, że podniósłszy prawicę swoję i lewicę swoję ku niebu przysiągł przez Żyjącego na wieki, iż po zamierzonym czasie i po zamierzonych czasach i po połowie czasu, i gdy do szczętu rozproszy siłą ręki ludu świętego, tedy się to wszystko wypełni.
Ọkùnrin tí ó wọ aṣọ àlà, ẹni tí ó wà lórí omi odò, gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti ọwọ́ òsì rẹ̀, mo gbọ́ tí ó fi ẹni tí ó wà títí láé búra, ó sọ wí pé, “Yóò ṣe ní àkókò kan, àkókò méjì àti ààbọ̀. Nígbà tí agbára àwọn ẹni mímọ́ yóò ti fọ́ tán pátápátá, gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò sì parí.”
8 A gdym ja to słyszał a nie zrozumiałem, rzekłem: Panie mój! cóż za koniec będzie tych rzeczy?
Èmi gbọ́, ṣùgbọ́n kò yé mi. Nígbà náà ni mo béèrè pé, “Olúwa mi, kí ni yóò jẹ́ àbábọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?”
9 Tedy rzekł: Idź, Danijelu! bo zawarte i zapieczętowane są te słowa aż do czasu zamierzonego.
Ó sì dáhùn pé, “Máa lọ ní ọ̀nà rẹ, Daniẹli nítorí tí a ti pa ọ̀rọ̀ náà dé, a sì ti fi èdìdì dì í di ìgbà ìkẹyìn.
10 Oczyszczonych i wybielonych i doświadczonych wiele będzie, a niezbożni niezbożnie czynić będą; nadto wszyscy niezbożni nie zrozumieją, ale mądrzy zrozumieją.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni a ó fọ̀ mọ́, wọn yóò wà láìlábàwọ́n, a ó sì tún wọn ṣe, ṣùgbọ́n àwọn ẹni búburú yóò máa ṣe búburú lọ, kò sí ẹni búburú tí òye yóò yé ṣùgbọ́n òye yóò yé àwọn ọlọ́gbọ́n.
11 A od tego czasu, którego odjęta będzie ofiara ustawiczna, a postawiona będzie obrzydliwość spustoszenia, będzie dni tysiąc, dwieście i dziewięćdziesiąt.
“Láti àkókò tí a ó mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò, tí a ó sì gbé ìríra tí ó ń fa ìsọdahoro kalẹ̀ yóò sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún àti igba lé àádọ́rùn-ún ọjọ́.
12 Błogosławiony, kto doczeka a dojdzie do tysiąca trzech set trzydziestu i pięciu dni.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó dúró, ti ó sì di òpin ẹgbẹ̀rún àti ọ̀ọ́dúnrún lé àrùndínlógójì ọjọ́.
13 Ale ty idź do miejsca twego, a odpoczniesz, i zostaniesz w losie twoim aż do skończenia dni.
“Ṣùgbọ́n ìwọ, máa lọ ní ọ̀nà rẹ, títí di òpin. Ìwọ yóò sinmi, àti ní òpin ọjọ́ ìwọ yóò dìde láti gba èrè rẹ.”

< Daniela 12 >