< Daniela 11 >

1 Ja tedy roku pierwszego za Daryjusza Medskiego stanąłem, abym go posilił i zmocnił.
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)
2 A teraz ci prawdę oznajmię: Oto jeszcze trzej królowie królować będą w Perskiej ziemi; potem czwarty zbogaci się bogactwy wielkimi nade wszystkich, a gdy się zmocni w bogactwach swoich, pobudzi wszystkich przeciw królestwu Greckiemu.
“Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki.
3 I powstanie król mocny, a będzie panował mocą wielką, a będzie czynił według woli swojej.
Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú.
4 A gdy się on zmocni, będzie skruszone królestwo jego, i będzie rozdzielone na cztery strony świata, wszakże nie między potomków jego, ani będzie państwo jego takie, jakie było; bo wykorzenione będzie królestwo jego, a innym mimo onych dostanie się.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.
5 Tedy się zmocni król z południa i jeden z książąt jego; ten mocniejszy będzie nadeń, i panować będzie, a państwo jego będzie państwo szerokie.
“Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá.
6 Lecz po wyjściu kilku lat złączą się; bo córka króla od południa pójdzie za króla północnego, aby uczyniła przymierze; wszakże nie otrzyma siły ramienia, ani się ostoi z ramieniem swojem, ale wydana będzie ona, i ci, którzy ją przyprowadzą, i syn jej, i ten, co ją zmacniał za onych czasów.
Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.
7 Potem powstanie z latorośli korzenia jej na miejsce jego, który przyciągnie z wojskiem swem, a uderzy na miejsce obronne króla północnego, i przewiedzie nad nimi i zmocni się.
“Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí.
8 Nadto i bogów ich z książętami ich, z naczyniem ich drogiem, srebrnem i złotem w niewolę zawiedzie do Egiptu; a ten będzie bezpieczen przez wiele lat od króla północnego.
Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀.
9 A tak wtargnie w królestwo król od południa, i wróci się do ziemi swojej.
Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí Orílẹ̀-èdè, òun fúnra rẹ̀.
10 Ale synowie jego walczyć będą, i zbiorą mnóstwo wojsk wielkich; a z nagła następując jako powódź przechodzić będzie, potem wracając się, wojskiem nacierać będzie aż na twierdze jego.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.
11 Skąd rozdrażniony będąc król z południa wyciągnie, i będzie walczył z nim, to jest, z królem północnym; a uszykuje mnóstwo wielkie, ale ono mnóstwo będzie podane w rękę jego.
“Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn.
12 A gdy zniesione będzie ono mnóstwo, podniesie się serce jego; a choć porazi wiele tysięcy, przecie się nie zmocni.
Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun.
13 Bo się wróci król północny, i uszykuje większe mnóstwo niż pierwsze; lecz po wyjściu czasu kilku lat z nagła przyjdzie z wielkiem wojskiem i z wielkim dostatkiem.
Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.
14 Onychże czasów wiele ich powstanie przeciwko królowi z południa; ale synowie przestępników z ludu twego będą zniesieni dla utwierdzenia tego widzenia, i upadną.
“Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí.
15 Bo przyciągnie król z północy, i usypie wały, i weźmie miasto obronne, a ramiona południowe nie oprą się, ani lud jego wybrany, i nie stanie im siły, aby dali odpór.
Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró.
16 I uczyni on, który przyciągnie przeciwko niemu, według woli swojej, i nie będzie nikogo, coby się stawił przeciwko niemu; stawi się też w ziemi ozdobnej, która zniszczeje przez rękę jego.
Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́.
17 Potem obróci twarz swoję, aby przyszedł z mocą wszystkiego królestwa swego, i okazał się, jakoby zgody szukał, i uczyni coś; bo mu da córkę piękną, aby go zgubił przez nią; ale ona w tem nie będzie stateczna, i nie będzie z nim przestawała.
Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
18 Zatem obróci twarz swoję do wysep, i wiele ich pobierze; ale wódz wstręt uczyni hańbieniu jego, owszem, ono hańbienie jego nań obróci.
Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀.
19 Dlaczego obróci twarz swoję ku twierdzom ziemi swej; lecz się potknie i upadnie, i nie będzie więcej znaleziony.
Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.
20 I powstanie na miejsce jego taki, który roześle poborców w sławie królewskiej; ale ten po niewielu dniach starty będzie, a to nie w gniewie ani przez wojnę.
“Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.
21 Potem powstanie wzgardzony na jego miejsce, acz nie włożą nań ozdoby królewskiej; wszakże przyszedłszy w pokoju, otrzyma królestwo pochlebstwem.
“Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè.
22 A ramionami jako powodzią wiele ich zachwyceni będą przed obliczem jego, i skruszeni będą, także też i sam wódz, który z nimi przymierze uczynił.
Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun.
23 Bo wszedłszy z nimi w przyjaźń, uczyni zdradę, a przyciągnąwszy zmocni się w małym poczcie ludu.
Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba.
24 Bezpiecznie i do najobfitszych miejsc onej krainy wpadnie, a uczyni to, czego nie czynili ojcowie jego, ani ojcowie ojców jego; łup i korzyść i majętności rozdzieli im, nawet i o miejscach obronnych chytrze przemyśliwać będzie, a to aż do czasu.
Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.
25 Potem wzbudzi moc swoję, i serce swoje przeciw królowi z południa z wojskiem wielkiem, z którem król z południa walecznie się potykać będzie z wojskiem wielkiem i bardzo mocnem; ale się nie oprze, przeto, że wymyśli przeciwko niemu zdradę.
“Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i.
26 Bo ci, którzy jedzą chleb jego, zniszczą go, gdy wojsko onego jako powódź przypadnie, a pobitych wiele polęże.
Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun, a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun.
27 Natenczas obaj królowie w sercu swem myślić będą, jakoby jeden drugiemu szkodzić mógł, a przy jednymże stole kłamstwo mówić będą; ale się im nie nada, gdyż jeszcze koniec na inszy czas odłożony jest.
Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn.
28 Przetoż się wróci do ziemi swojej z bogactwy wielkiemi, a serce jego obróci się przeciwko przymierzu świętemu; co uczyniwszy wróci się do ziemi swojej.
Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀.
29 A czasu zamierzonego wróci się i pociągnie na południe; ale mu się nie tak powiedzie, jako za pierwszym i za ostatnim razem.
“Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú.
30 Bo przyjdą przeciwko niemu okręty z Cytym, skąd on nad tem bolejąc znowu się rozgniewa przeciwko przymierzu świętemu; co uczyniwszy wróci się, a będzie miał porozumienie z onymi, którzy opuścili przymierze święte;
Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.
31 A wojska wielkie przy nim stać będą, które splugawią świątnicę, i twierdze zniosą; odejmą też ustawiczną ofiarę, a postawią obrzydliwość spustoszenia.
“Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀.
32 Tak aby tych, którzy niezbożnie przeciwko przymierzu postępować będą, w obłudzie pochlebstwem utwierdził, a żeby lud znający Boga swego imali, co też uczynią.
Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.
33 Zaczem ci, którzy nauczają lud, którzy nauczają wielu, padać będą od miecza i od ognia, od pojmania i od łupu przez wiele dni.
“Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun.
34 A gdy padać będą, małą pomoc mieć będą; bo się do nich wiele pochlebców przyłączy.
Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn.
35 A z tych, którzy innych nauczają, padać będą, aby doświadczeni i oczyszczeni, i wybieleni byli aż do czasu zamierzonego; bo to jeszcze potrwa aż do czasu zamierzonego.
Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.
36 Tak uczyni król według woli swojej, i podniesie się i wielmożnym się uczyni nad każdego boga, i przeciwko Bogu nad bogami dziwne rzeczy mówić będzie, i poszczęści mu się, aż się dokona gniew, ażby się to, co jest postanowiono, wykonało.
“Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀.
37 Ani na bogów ojców swych nie będzie dbał, ani o miłość niewiast, ani o żadnego boga dbać będzie, przeto, że się nade wszystko wyniesie.
Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ.
38 A na miejscu Boga najmocniejszego czcić będzie boga, którego nie znali ojcowie jego; czcić będzie złotem i srebrem i kamieniem drogiem i rzeczami kosztownemi.
Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.
39 A tak dowiedzie tego, że twierdze Najmocniejszego będą boga obcego; a których mu się będzie zdało, tych rozmnoży sławę, i uczyni, aby panowali nad wielą, a rozdzieli im ziemię miasto zapłaty.
Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.
40 A przy skończeniu tego czasu będzie się z nim potykał król z południa; ale król północny jako burza nań przyjdzie z wozami i z jezdnymi i z wielą okrętów, a wtargnie w ziemię, i jako powódź przejdzie.
“Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.
41 Potem przyciągnie do ziemi ozdobnej, i wiele krain upadnie; wszakże ci ujdą rąk jego, Edomczycy i Moabczycy, i pierwociny synów Ammonowych.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.
42 A gdy rękę swą ściągnie na krainy, ani ziemia Egipska tego ujść nie będzie mogła.
Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là.
43 Bo opanuje skarby złota i srebra, i wszystkie rzeczy drogie Egipskie, a Libijczycy i Murzynowie za nim pójdą.
Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba.
44 W tem wieści od wschodu słońca i od północy przestraszą go; przetoż wyciągnie z popędliwością wielką, aby wygubił i zamordował wielu.
Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá.
45 I rozbije namioty pałacu swego między morzami na górze ozdobnej świętobliwości; a gdy przyjdzie do końca swego, nie będzie miał nikogo na pomocy.
Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo. Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.

< Daniela 11 >