< Amosa 6 >
1 Biada bezpiecznym na Syonie, i ufającym w górze Samaryjskiej! którzy są sławni mimo innych u tych narodów, do których się schodzi dom Izraelski.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
2 Zajdźcie do Chalny, i idźcie z onąd do Emat wielkiego, a zstąpcie do Giet Filistyńskiego, a obaczcie, sąli które królestwa lepsze niżeli te, i jeżeli szersza jest granica ich, niż granica wasza.
Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
3 (Biada wam) którzy mniemacie, że daleki jest dzień zły, a przystawiacie stolicę drapiestwa!
Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
4 Którzy sypiacie na łożach słoniowych, a rozciągacie się na pościelach waszych; którzy jadacie barany z trzody, a cielce tuczone ze stani;
Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
5 Którzy śpiewacie przy lutni, wymyślając sobie naczynia muzyczne, jako Dawid;
Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
6 Którzy pijacie wino czaszami, a drogiemi się maściami namazujecie, i nie bolejecie nad utrapieniem Józefowem.
Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
7 Przetoż teraz pójdą w niewolę na czele pojmanych; a tak odstąpi biesiada od zbyteczników.
Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
8 Przysiągł panujący Pan sam przez się, mówi Pan, Bóg zastępów: Zbrzydziłem sobie pychę Jakóbową i pałace jego mam w nienawiści; przetoż podam miasto i wszystko, co w niem jest, nieprzyjacielowi;
Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
9 A zostanieli dziesięć osób w domu jednym, i ci pomrą.
Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
10 I weźmie każdego z nich stryj jego, i spali go, aby wyniósł kości z domu, a rzecze temu, który jest w gmachach domu: Jestże kto więcej z tobą? I odpowie: Niemasz. Tedy rzecze: Milcz; przeto, że nie wspominali imienia Pańskiego.
Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
11 Bo oto Pan rozkaże, i uderzy na dom wielki rozstąpieniem, a na dom mniejszy rozpadlinami.
Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
12 Izali konie mogą biegać po skale? Izali tam wołami orać mogą? Boście obrócili sąd w truciznę, a owoc sprawiedliwości w piołun;
Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
13 Biada wam! którzy się weselicie, a niemasz z czego, mówiąc: Izaliśmy sobie nie naszą mocą wzięli rogi?
Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
14 Ale oto Ja wzbudzę przeciwko wam, o domie Izraelski! mówi Pan, Bóg zastępów, naród, który was uciśnie od wejścia do Emat aż do strumienia pustyni.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”