< Amosa 3 >

1 Słuchajcie słowa tego, które mówi Pan przeciwko wam, synowie Izraelscy! przeciwko wszystkiemu rodzajowi, którym wywiódł z ziemi Egipskiej, mówiąc:
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 Tylkom was samych poznał ze wszystkich rodzajów ziemi; przetoż was nawiedzę dla wszystkich nieprawości waszych.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Izali dwa społem pójdą nie zgodziwszy się?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Izali zaryczy lew w lesie, gdyby nie miał łupu? Izali wyda lwię głos swój z jaskini swojej, gdyby łapać nie miało?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Izali ptak wpadnie w sidło na ziemi, gdyby sidła nie było? Izali będzie podniesione sidło z ziemi, gdyby nic nie uwięzło?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Izali się ludzie nie lękają, gdy trąba w mieście zabrzmi? izali jest w mieście co złego, którego by Pan nie uczynił?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 Zaiste nic nie czyni panujący Pan, chyba żeby objawił tajemnice swoję sługom swoim, prorokom.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Lew ryczy, któżby się nie bał? Panujący Pan mówi, któżby nie prorokował?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Obwołajcie w pałacach w Azocie i w pałacach ziemi Egipskiej, a mówcie: Zbierzcie się na góry Samaryi, a obaczcie wielkie zamięszania w pośrodku jej, i ucisk cierpiących w niej;
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 I że nie umieją czynić, co jest prawego, mówi Pan, zbierając na pałacach swoich skarby z zdzierstwa i z łupiestwa.
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Przetoż tak mówi panujący Pan: Oto nieprzyjaciel około tej ziemi, a ten odejmie od ciebie siłę twoję, i rozchwycone będą pałace twoje.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Tak mówi Pan: Jako wyrywa pasterz z paszczęki lwiej dwa gnaty albo kęs ucha, tak wyrwani będą synowie Izraelscy, którzy mieszkają w Samaryi na stronie łoża, i na stronie pościeli.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Słuchajcie a oświadczajcie w domu Jakóbowym, mówi panujący Pan, Bóg zastępów.
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 Bo dnia onego, którego Izraela nawiedzę dla przestępstwa jego, nawiedzę też ołtarze w Betel, i odcięte będą rogi ołtarza, tak, że na ziemię upadną;
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 I uderzę dom zimy o dom lata, a zginą domy z kości słoniowych, a domy zacne koniec wezmą, mówi Pan.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< Amosa 3 >