< Dzieje 17 >
1 A przeszedłszy Amfipolim i Apoloniję przyszli do Tesaloniki, gdzie była bóżnica żydowska.
Nígbà tí wọn sì ti kọjá Amfipoli àti Apollonia, wọ́n wá sí Tẹsalonika, níbi tí Sinagọgu àwọn Júù wà.
2 Tedy Paweł według zwyczaju swego wszedł do nich, a przez trzy sabaty kazał im z Pisma.
Àti Paulu, gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀, ó wọlé tọ̀ wọ́n lọ, ni ọjọ́ ìsinmi mẹ́ta ó sì ń bá wọn fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ nínú ìwé mímọ́.
3 Wywodząc i pokazując to, że Chrystus miał cierpieć i powstać od umarłych, a iż ten Jezus jest Chrystusem, którego ja wam opowiadam.
Ó ń túmọ̀, ó sì ń fihàn pé, Kristi kò lè ṣàìmá jìyà, kí o sì jíǹde kúrò nínú òkú; àti pé, “Jesu yìí ẹni tí èmi ń wàásù fún yin, òun ni Kristi náà.”
4 I uwierzyli niektórzy z nich, a przyłączyli się do Pawła i do Syli, i wielkie mnóstwo nabożnych Greków, i niewiast przedniejszych niemało.
A sì yí nínú wọn lọ́kàn padà, wọ́n sì darapọ̀ mọ́ Paulu àti Sila, bákan náà ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn olùfọkànsìn Helleni àti nínú àwọn obìnrin ọlọ́lá, kì í ṣe díẹ̀.
5 Ale Żydowie, którzy nie uwierzyli, zdjęci zazdrością, przywziąwszy do siebie niektórych lekkomyślnych i złych mężów, a zebrawszy kupę uczynili rozruch w mieście, a naszedłszy na dom Jazona, szukali ich, aby ich wywiedli przed lud.
Ṣùgbọ́n àwọn Júù jowú, wọn sì fa àwọn jàgídíjàgan nínú àwọn ọmọ ènìyàn mọ́ra, wọ́n ko ẹgbẹ́ jọ, wọ́n sì ń dá ìlú rú; wọ́n sì kọlu ilé Jasoni, wọ́n ń fẹ́ láti mú Paulu àti Sila jáde tọ àwọn ènìyàn lọ.
6 A nie znalazłszy ich, ciągnęli Jazona i niektórych braci do przełożonych miasta, wołając: Oto ci, którzy wszystek świat wzruszyli i tu też przyszli;
Nígbà tí wọn kò sì rí wọn, wọ́n wọ́ Jasoni, àti àwọn arákùnrin kan tọ àwọn olórí ìlú lọ, wọ́n ń kígbe pé, “Àwọn wọ̀nyí tí o tí dorí ayé kodò títí de ìhín yìí pẹ̀lú.
7 Które przyjął Jazon; a ci wszyscy czynią przeciwko dekretom cesarskim, powiadając, iż jest inszy król, Jezus.
Àwọn ẹni tí Jasoni gbà sí ọ̀dọ̀: gbogbo àwọn wọ̀nyí ni o sí ń hùwà lòdì sí àṣẹ Kesari, wí pé, ọba mìíràn kan wà tí í ṣe Jesu.”
8 A tak wzburzyli pospólstwo i przełożonych miasta, którzy to słyszeli.
Àwọn ènìyàn àti àwọn olórí ìlú kò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí wọ́n gbọ́ nǹkan wọ̀nyí.
9 Ale oni wziąwszy słuszną sprawę od Jazona i od innych, puścili je.
Nígbà tí wọ́n sì gbà onídùúró lọ́wọ́ Jasoni àti àwọn ìyókù, wọ́n fi wọ́n sílẹ̀ lọ.
10 A bracia wnet w nocy wysłali i Pawła, i Sylę do Berei; którzy tam przyszedłszy weszli do bóżnicy żydowskiej.
Lọ́gán àwọn arákùnrin sì rán Paulu àti Sila lọ ṣí Berea lóru. Nígbà tí wọ́n sí dé ibẹ̀, wọ́n wọ inú Sinagọgu àwọn Júù lọ.
11 A cić byli zacniejsi nad one, co byli w Tesalonice, którzy przyjęli słowo Boże ze wszystką ochotą, na każdy dzień rozsądzając Pisma, jeźliby się tak miało.
Àwọn Júù Berea sì ní ìyìn ju àwọn tí Tẹsalonika lọ, ní tí pé wọn fi tọkàntọkàn gbà ọ̀rọ̀ náà. Wọ́n sì ń wá inú ìwé mímọ́ lójoojúmọ́ bí nǹkan wọ̀nyí bá rí bẹ́ẹ̀.
12 Przetoż wiele ich z nich uwierzyło, i Greckich niewiast uczciwych, i mężów niemało.
Nítorí náà púpọ̀ nínú wọn gbàgbọ́; àti nínú àwọn obìnrin Giriki ọlọ́lá, àti nínú àwọn ọkùnrin ti kì í ṣe díẹ̀.
13 A gdy się dowiedzieli oni, co byli z Tesaloniki Żydowie, że i w Berei opowiadane było słowo Boże od Pawła, przyszli i tam, podburzając pospólstwo.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù tí Tẹsalonika mọ̀ pé, Paulu ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Berea, wọ́n wá síbẹ̀ pẹ̀lú, wọ́n rú àwọn ènìyàn sókè.
14 Ale bracia wnet wysłali Pawła, aby szedł jakoby do morza; a Sylas i Tymoteusz tam zostali.
Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rán Paulu jáde lọ́gán láti lọ títí de etí Òkun, ṣùgbọ́n Sila àti Timotiu dúró ní Berea.
15 A ci, którzy prowadzili Pawła, doprowadzili go aż do Aten, a wziąwszy rozkazanie do Syli i do Tymoteusza, żeby co najrychlej przyszli do niego, odeszli.
Àwọn tí ó sin Paulu wá sì mú un lọ títí dé Ateni; nígbà tí wọ́n sì gba àṣẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ wá fún Sila àti Timotiu pé, ki wọn ó yára tọ òun wá, wọ́n lọ.
16 A gdy ich Paweł w Atenach czekał, poruszał się w nim duch jego, widząc ono miasto poddane bałwochwalstwu.
Nígbà tí Paulu dúró dè wọ́n ni Ateni, ẹ̀mí rẹ̀ ru nínú rẹ̀, nígbà tí ó rí pé ìlú náà kún fún òrìṣà.
17 A przetoż miewał rozmowę z Żydami i z ludźmi nabożnymi, w bóżnicy i na rynku na każdy dzień, z kim się mu trafiło.
Nítorí náà ó ń bá àwọn Júù fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ nínú Sinagọgu, àti àwọn olùfọkànsìn, àti àwọn tí ó ń bá pàdé lọ́jà lójoojúmọ́.
18 Tedy niektórzy z Epikurejczyków i Stoików filozofowie spierali się z nim, a niektórzy mówili: Cóż wżdy ten plotkarz mówić chce? A drudzy: Zdaje się być opowiadaczem obcych bogów; bo im Jezusa i zmartwychwstanie opowiadał.
Nínú àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n Epikure ni àti tí àwọn Stoiki kó tì í. Àwọn kan si ń wí pé, “Kín ni aláhesọ yìí yóò rí wí?” Àwọn mìíràn sì wí pé, “Ó dàbí oníwàásù àjèjì òrìṣà, wọ́n sọ èyí nítorí Paulu ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu àti àjíǹde fún wọn.”
19 A porwawszy go, wiedli do Areopagu, mówiąc: Możemyli wiedzieć, co to jest za nowa nauka, którą ty opowiadasz?
Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fà á lọ sí Areopagu, wọ́n wí pé, “A ha lè mọ̀ kín ni ẹ̀kọ́ tuntun tí ìwọ ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí jẹ́?
20 Bo jakieś obce rzeczy przynosisz do uszów naszych; chcemy tedy wiedzieć, co wżdy z tego ma być?
Nítorí tí ìwọ mú ohun àjèjì wá sí etí wa, àwa sì ń fẹ́ mọ̀ kín ni ìtumọ̀ nǹkan wọ̀nyí.”
21 (A wszyscy Ateńczycy i cudzoziemscy goście niczem inszem się nie bawili, tylko powiadaniem albo słuchaniem nowin.)
Nítorí gbogbo àwọn ará Ateni, àti àwọn àjèjì tí ń ṣe àtìpó níbẹ̀ kì í ṣe ohun mìíràn jù kí a máa sọ tàbí kí a máa gbọ́ ohun tuntun lọ.
22 Tedy Paweł stanąwszy w pośrodku Areopagu, rzekł: Mężowie Ateńscy! z każdej miary was widzę nader nabożnych.
Paulu si dìde dúró láàrín Areopagu, ó ní, “Ẹ̀yin ará Ateni, mo wòye pé ní ohun gbogbo ẹ kún fún ẹ̀sìn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
23 Albowiem przechadzając się i przypatrując waszym nabożeństwom, znalazłem też ołtarz, na którym napisano: Nieznajomemu Bogu. Którego tedy nie znając chwalicie, tego ja wam opowiadam.
Nítorí bí mo ti ń kọjá lọ, tí mo wo àwọn ohun tí ẹ̀yin ń sìn, mo sì rí pẹpẹ kan tí a kọ àkọlé yìí sí: Fún Ọlọ́run àìmọ̀. Ǹjẹ́ ẹni tí ẹ̀yin ń sìn ni àìmọ̀ òun náà ni èmi ń sọ fún yin.
24 Bo Bóg, który uczynił świat i wszystko, co na nim, ten będąc Panem nieba i ziemi, nie mieszka w kościołach ręką uczynionych.
“Ọlọ́run náà tí ó dá ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òun náà tí í ṣe Olúwa ọ̀run àti ayé, kì í gbé tẹmpili tí a fi ọwọ́ kọ́.
25 Ani rękoma ludzkiemi chwalony bywa, jakoby czego potrzebował, ponieważ on daje wszystkim żywot i oddech, i wszystko.
Bẹ́ẹ̀ ni a kì í fi ọwọ́ ènìyàn sìn ín, bí ẹni pé ó ń fẹ́ nǹkan, òun ni ó fi ìyè àti èémí àti ohun gbogbo fún gbogbo ènìyàn.
26 I uczynił z jednej krwi wszystek naród ludzki, aby mieszkał po wszystkiem obliczu ziemi, zamierzywszy przedtem rozrządzone czasy i zamierzone granice mieszkania ich;
Ó sì tí tipasẹ̀ ẹnìkan dá gbogbo orílẹ̀-èdè láti tẹ̀dó sí ojú àgbáyé, ó sì ti pinnu àkókò tí a yàn tẹ́lẹ̀, àti ààlà ibùgbé wọn;
27 Aby szukali Pana, owaby go snać namacali i znaleźli, aczkolwiek od każdego z nas nie jest daleko.
Ọlọ́run ṣe eléyìí kí wọn bá le máa wa, bóyá wọn yóò lè ṣàfẹ́rí rẹ̀, kí wọn sì rí í. Bí ó tilẹ̀ jẹ pé kò jìnnà sí olúkúlùkù wa.
28 Albowiem w nim żyjemy i ruszamy się, i jesteśmy, jako i niektórzy z waszych poetów powiedzieli: Żeśmy i my rodziną jego.
Nítorí nínú rẹ̀ ni àwa wà láààyè, tí a ń rìn kiri, tí a sì ní ẹ̀mí wa, bí àwọn kan nínú àwọn akéwì tí ẹ̀yin tìkára yín tí wí pé, ‘Àwa pẹ̀lú sì jẹ́ ọmọ rẹ̀.’
29 Będąc tedy rodziną Bożą, nie mamy rozumieć, żeby złotu albo srebru, albo kamieniowi misternie rytemu, albo wymysłowi człowieczemu, Bóg miał być podobny.
“Ǹjẹ́ bí àwa bá jẹ́ ọmọ Ọlọ́run, kò yẹ fún wa láti rò pé, ẹni tí a wa n sìn dàbí wúrà, tàbí fàdákà, tàbí òkúta, tí a fi ọgbọ́n àti ìmọ̀ ènìyàn ya ère àwòrán rẹ̀.
30 Aczkolwiek tedy przeglądał Bóg czasom tej niewiadomości, ale teraz oznajmuje ludziom wszystkim wszędy, aby pokutowali;
Pẹ̀lúpẹ̀lú ìgbà àìmọ̀ yìí ni Ọlọ́run tí fojú fò dá; ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn níbi gbogbo láti ronúpìwàdà.
31 Przeto iż postanowił dzień, w który będzie sądził wszystek świat w sprawiedliwości przez męża, którego na to naznaczył, upewniając o tem wszystkich, wzbudziwszy go od umarłych.
Níwọ́n bí ó ti dá ọjọ́ kan, nínú èyí tí yóò ṣe ìdájọ́ ayé lódodo nípasẹ̀ ọkùnrin náà tí ó ti yàn, nígbà tí ó ti fi ohun ìdánilójú fún gbogbo ènìyàn, ní ti pé ó jí dìde kúrò nínú òkú.”
32 A usłyszawszy o zmartwychwstaniu jedni się naśmiewali, a drudzy mówili: Będziemy cię znowu o tem słuchać.
Nígbà tí wọ́n ti gbọ́ ti àjíǹde òkú, àwọn mìíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn mìíràn wí pé, “Àwa o tún nǹkan yìí gbọ́ lẹ́nu rẹ̀.”
33 I tak Paweł wyszedł z pośrodku ich.
Bẹ́ẹ̀ ni Paulu sì jáde kúrò láàrín wọn.
34 A mężowie niektórzy przyłączywszy się do niego, uwierzyli, między którymi też był Dyjonizyjusz Areopagitczyk i niewiasta imieniem Damarys, i inni z nimi.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin kan fi ara mọ́ ọn, wọ́n sì gbàgbọ́: nínú àwọn ẹni tí Dionisiu ara Areopagu wà, àti obìnrin kan tí a ń pè ni Damari àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn.