< Dzieje 12 >
1 A pod onże czas, udał się na to Herod król, aby trapił niektóre ze zboru.
Ní àkókò ìgbà náà ni Herodu ọba sì nawọ́ rẹ̀ mú àwọn kan nínú ìjọ, pẹ̀lú èrò láti pọ́n wọn lójú.
2 I zabił Jakóba, brata Janowego, mieczem.
Ó sì fi idà pa Jakọbu arákùnrin Johanu.
3 A widząc, że się to podobało Żydom, umyślił pojmać i Piotra: (a były dni przaśników).
Nígbà tí ó sì rí pé èyí dùn mọ́ àwọn Júù nínú, ó sì nawọ́ mú Peteru pẹ̀lú. Ó sì jẹ́ ìgbà àjọ àìwúkàrà.
4 Którego pojmawszy, podał do więzienia, poruczywszy go szesnastu żołnierzom, aby go strzegli, chcąc go po wielkanocy wywieść ludowi.
Nígbà tí o sì mú un, ó fi i sínú túbú, ó fi lé àwọn ẹ̀ṣọ́ mẹ́rin ti ọmọ-ogun lọ́wọ́ láti máa ṣọ́ ọ. Herodu ń rò láti mú un jáde fún àwọn ènìyàn lẹ́yìn ìrékọjá fún ìdájọ́.
5 Tedy strzeżono Piotra w więzieniu, a modlitwa ustawiczna działa się od zboru do Boga za nim.
Nítorí náà wọn fi Peteru pamọ́ sínú túbú; ṣùgbọ́n ìjọ ń fi ìtara gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run fún un.
6 A gdy go już miał wywieść Herod, onejże nocy spał Piotr między dwoma żołnierzami, związany dwoma łańcuchami, a stróże przed drzwiami strzegli więzienia.
Ní òru náà gan an ti Herodu ìbá sì mú un jáde, Peteru ń sùn láàrín àwọn ọmọ-ogun méjì, a fi ẹ̀wọ̀n méjì dè é, ẹ̀ṣọ́ sí wà ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n ń ṣọ́ túbú náà.
7 A oto Anioł Pański przystąpił, a światłość się rozświeciła w gmachu; a trąciwszy w bok Piotra, obudził go, mówiąc: Wstań rychło! I opadły łańcuchy z rąk jego.
Sì wò ó, angẹli Olúwa farahàn, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ nínú túbú; ó sì lu Peteru pẹ́pẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́, ó jí i, ó ni, “Dìde kánkán!” Ẹ̀wọ̀n sí bọ́ sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ Peteru.
8 I rzekł Anioł do niego: Opasz się, a powiąż obuwie twoje. I uczynił tak. I rzekł mu: Odziej się w płaszcz twój, a pójdź za mną.
Angẹli náà sì wí fún un pé, “Di àmùrè rẹ̀, kí ó sì wọ sálúbàtà rẹ!” Peteru sì ṣe bẹ́ẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Da aṣọ rẹ́ bora, ki ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn!”
9 Tedy wyszedłszy Piotr, szedł za nim, a nie wiedział, że się to działo po prawdzie, co się działo przez Anioła; lecz mniemał, że widzenie widział.
Peteru sì jáde, ó ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn; kò sí mọ̀ pé ohun tí a ṣe láti ọwọ́ angẹli náà jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n ó ṣe bí òun wà lójú ìran.
10 A gdy minęli pierwszą i wtórą straż, przyszli do bramy żelaznej, która wiedzie do miasta; a ta się im sama przez się otworzyła. A wyszedłszy, przeszli jednę ulicę, a zarazem odstąpił Anioł od niego.
Nígbà tí wọ́n kọjá ìṣọ́ èkínní àti èkejì, wọ́n dé ẹnu-ọ̀nà ìlẹ̀kùn irin tí ó lọ sí ìlú. Ó sí tìkára rẹ̀ ṣí sílẹ̀ fún wọn: wọ́n sì jáde, wọ́n ń gba ọ̀nà ìgboro kan lọ; lójúkan náà angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.
11 Tedy Piotr przyszedłszy do siebie rzekł: Teraz znam prawdziwie, iż posłał Pan Anioła swego i wyrwał mię z ręki Herodowej i ze wszystkiego oczekiwania ludu żydowskiego.
Nígbà tí ojú Peteru sì wálẹ̀, ó ní, “Nígbà yìí ni mo tó mọ̀ nítòótọ́ pé, Olúwa rán angẹli rẹ̀, ó sì gbà mi lọ́wọ́ Herodu àti gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn Júù ń retí!”
12 A obaczywszy się, przyszedł do domu Maryi, matki Janowej, którego nazywano Markiem, gdzie się ich było wiele zgromadziło i modlili się.
Nígbà tó sì rò ó, ó lọ sí ilé Maria ìyá Johanu, tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku; níbi tí àwọn ènìyàn púpọ̀ péjọ sí, tí wọn ń gbàdúrà.
13 A gdy Piotr kołatał we drzwi u przysionka, wyszła dzieweczka, imieniem Rode, aby posłuchała:
Bí ó sì ti kan ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà, ọmọbìnrin kan tí a n pè ní Roda wá láti dáhùn.
14 A poznawszy głos Piotrowy, od radości nie otworzyła drzwi, ale wbieżawszy oznajmiła, iż Piotr stoi u drzwi.
Nígbà tí ó sì ti mọ ohùn Peteru, kò ṣí ìlẹ̀kùn nítorí tí ayọ̀ kún ọkàn rẹ̀ gidigidi, ṣùgbọ́n ó súré wọ ilé, ó sísọ pé, Peteru dúró ní ẹnu-ọ̀nà.
15 A oni rzekli do niej: Szalejesz! Wszakże ona twierdziła, iż się tak rzecz ma. A oni rzekli: Anioł jego jest.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ń ṣe òmùgọ̀!” Ṣùgbọ́n ó tẹnumọ́ ọn gidigidi pé bẹ́ẹ̀ ni sẹ́. Wọn sì wí pé, “Angẹli rẹ̀ ni!”
16 Ale Piotr nie przestał kołatać; a gdy otworzyli, ujrzeli go i zdumieli się.
Ṣùgbọ́n Peteru ń kànkùn síbẹ̀, nígbà tí wọn sì ṣí ìlẹ̀kùn, wọ́n rí i, ẹnu sì yá wọ́n.
17 A skinąwszy na nie ręką, aby umilknęli, rozpowiedział im, jako go Pan wywiódł z więzienia i rzekł: Oznajmijcie to Jakóbowi i braciom. A wyszedłszy, szedł na inne miejsce.
Ṣùgbọ́n ó juwọ́ sí wọn pé kí wọn dákẹ́, ó sì ròyìn fún wọn bí Olúwa ti mú òun jáde kúrò nínú túbú. Ó sì wí pé, “Ẹ ro èyí fún Jakọbu àti àwọn arákùnrin yòókù!” Ó sì jáde, ó lọ sí ibòmíràn.
18 A gdy był dzień, stał się rozruch niemały między żołnierzami o to, co by się z Piotrem stało.
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìrúkèrúdò díẹ̀ kọ́ ni ó wà láàrín àwọn ọmọ-ogun nípa ohun tí ó dé bá Peteru.
19 Lecz Herod, gdy się o nim wywiadywał, a nie znalazł go, uczyniwszy sąd o stróżach, kazał je na stracenie wywieść; a wyjechawszy z Judzkiej ziemi do Cezaryi, mieszkał tam.
Nígbà tí Herodu sì wá a kiri, tí kò sì rí i, ó wádìí àwọn ẹ̀ṣọ́, ó pàṣẹ pé, kí a pa wọ́n. Herodu sì sọ̀kalẹ̀ láti Judea lọ sí Kesarea, ó sì wà níbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀.
20 A natenczas Herod myślił o wojnie przeciwko Tyryjczykom i Sydończykom; ale oni jednomyślnie przyszli do niego, a namówiwszy Blasta, podkomorzego królewskiego, prosili o pokój, dlatego iż kraina ich miała żywność z dzierżawy królewskiej.
Herodu sí ń bínú gidigidi sí àwọn ará Tire àti Sidoni; ṣùgbọ́n wọ́n fi ìmọ̀ ṣọ̀kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nígbà tí wọn sì ti tu Bilasitu ìwẹ̀fà ọba lójú, wọn ń bẹ̀bẹ̀ fún àlàáfíà, nítorí pé ìlú ọba náà ni ìlú tí wọ́n ti ń gba oúnjẹ.
21 A dnia pewnego Herod oblekłszy się w szatę królewską i siadłszy na stolicy, uczynił rzecz do nich.
Ni ọjọ́ àfiyèsí kan, Herodu sì wà nínú aṣọ ìgúnwà rẹ̀, ni orí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì ń bá àwọn àjọ ènìyàn sọ̀rọ̀ ní gbangba.
22 A lud wołał: Głos Boży a nie człowieczy.
Àwọn ènìyàn sì hó wí pé, “Ohùn ọlọ́run ni èyí, kì í sì í ṣe ti ènìyàn!”
23 A zarazem uderzył go Anioł Pański, przeto, że nie dał chwały Bogu, a będąc roztoczony od robactwa, zdechł.
Lójúkan náà, nítorí ti Herodu kò fi ògo fún Ọlọ́run, angẹli Olúwa lù ú, ó sì kú, ìdin sì jẹ ẹ́.
24 A słowo Pańskie rozrastało się i rozmnażało.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbilẹ̀, ó sì bí sí i.
25 A Barnabasz i Saul wrócili się z Jeruzalemu, wykonawszy posługę, wziąwszy z sobą Jana, którego nazywano Markiem.
Barnaba àti Saulu sì padà wá láti Jerusalẹmu, nígbà ti wọ́n sì parí iṣẹ́ ìránṣẹ́ wọn, wọn sì mú Johanu ẹni tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku wá pẹ̀lú wọn.