< II Tesaloniczan 3 >

1 Na ostatek, bracia! módlcie się za nas, aby się słowo Pańskie szerzyło i rozsławiało, jako i u was;
Ní àkótán, ará, ẹ máa gbàdúrà fún wa, kí ọ̀rọ̀ Olúwa lè máa tàn káàkiri, kí ó sì jẹ́ èyí tí a bu ọlá fún, gẹ́gẹ́ bí ó ti rí ní ọ̀dọ̀ yín.
2 I abyśmy byli wyrwani od niezbędnych i złych ludzi; albowiem nie wszystkich jest wiara.
Kí ẹ sì máa gbàdúrà fún wa kí a lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn ìkà àti àwọn ènìyàn búburú, nítorí pé kì í ṣe gbogbo ènìyàn ló ní ìgbàgbọ́.
3 Aleć wierny jest Pan, który was utwierdzi i strzec będzie od złego.
Ṣùgbọ́n olódodo ni Olúwa, ẹni tí yóò fi ẹsẹ̀ yín múlẹ̀, tí yóò sì pa yín mọ́ kúrò nínú ibi.
4 A ufamy w Panu o was, iż to, co wam rozkazujemy, i czynicie i czynić będziecie.
Àwa sì ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa ní ti ohun tí ẹ ń ṣe, àti pé àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a pàṣẹ fún un yín ni ẹ̀yin ń ṣe.
5 A Pan niech sprawuje serca wasze ku miłości Bożej i ku cierpliwemu oczekiwaniu Chrystusa.
Kí Olúwa máa tọ́ ọkàn yín ṣọ́nà sí ìfẹ́ Ọlọ́run àti sínú sùúrù Kristi.
6 A rozkazujemy wam, bracia! w imieniu Pana naszego, Jezusa Chrystusa, abyście się odłączyli od każdego brata nieporządnie chodzącego, a nie według podanej nauki, którą wziął od nas.
Ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wa, àwa pàṣẹ fún un yín ará, pé kí ẹ yẹra fún gbogbo àwọn arákùnrin yín tí ń ṣe ìmẹ́lẹ́, tí kò sì gbé ní ìbámu pẹ̀lú ẹ̀kọ́ tí ẹ gbà ní ọ̀dọ̀ wa.
7 Albowiem sami wiecie, jako nas potrzeba naśladować, ponieważeśmy nie żyli między wami nieporządnie;
Nítorí ẹ̀yin náà mọ̀ bí ó ṣe yẹ kí ẹ máa fi ara wé wa. Àwa kì í ṣe ìmẹ́lẹ́ nígbà tí a wà ní ọ̀dọ̀ yín.
8 Aniśmy darmo chleba jedli u kogo, ale z pracą i z kłopotem we dnie i w nocy robiąc, abyśmy nikomu z was ciężkimi nie byli;
Bẹ́ẹ̀ ni àwa kò sì jẹ oúnjẹ ẹnikẹ́ni lọ́fẹ̀ẹ́. Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, àwa ń ṣiṣẹ́ tọ̀sán tòru kí a má ba à di àjàgà sí ẹnikẹ́ni nínú yín lọ́rùn.
9 Nie iżbyśmy tej mocy nie mieli, ale żebyśmy wam sami siebie za przykład podali, abyście nas naśladowali.
Àwa ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, kì í ṣe nítorí pé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti béèrè fún un, ṣùgbọ́n àwa ń fi ara wa ṣe àpẹẹrẹ tí ẹ ó tẹ̀lé.
10 Albowiem gdyśmy byli u was, tośmy wam rozkazali, że jeźli kto nie chce robić, niechajże też nie je.
Nítorí nígbà tí àwa wà lọ́dọ̀ yín, a ṣe àwọn òfin wọ̀nyí fún un yín pé, “Bí ẹnikẹ́ni kò bá fẹ́ ṣiṣẹ́, kí ó má ṣe jẹun.”
11 Bo słyszymy, iż niektórzy między wami nieporządnie chodzą, nic nie robiąc, ale się niepotrzebnemi rzeczami bawiąc.
A gbọ́ pé àwọn kan wà láàrín yín tí wọn jẹ́ ìmẹ́lẹ́. Wọ́n jẹ́ atọjúlékiri.
12 Przetoż takowym rozkazujemy i napominamy ich przez Pana naszego, Jezusa Chrystusa, aby w pokoju robiąc, swój własny chleb jedli.
Ǹjẹ́ irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ ni àwa ń pàṣẹ fún, tí a sì ń rọ̀ nínú Jesu Kristi Olúwa pé kí wọn ó máa ṣiṣẹ́ fún oúnjẹ tí wọ́n ń jẹ.
13 A wy, bracia! nie słabiejcie, dobrze czyniąc.
Ṣùgbọ́n ní tiyín ará, ẹ má ṣe jẹ́ kí agara dá yín ní rere ṣíṣe.
14 A jeźli kto jest nieposłuszny słowu naszemu przez list pisanemu, tego naznaczcie, a nie mieszajcie się z nim, aby się zawstydził;
Bí ẹnikẹ́ni kò bá sì pa òfin wa nínú lẹ́tà yìí mọ́, ẹ sàmì sí ẹni náà. Ẹ má ṣe bá a kẹ́gbẹ́ kí ojú bà á le tì í.
15 Wszakże nie miejcie go za nieprzyjaciela, ale napominajcie jako brata.
Síbẹ̀, ẹ má ṣe kà á sí ọ̀tá, ṣùgbọ́n ẹ máa kìlọ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí arákùnrin yín.
16 A sam Pan pokoju niech wam da pokój zawsze i wszelkim sposobem. Pan niech będzie z wami wszystkimi.
Ǹjẹ́ kí Olúwa àlàáfíà, fúnra rẹ̀ máa fún yín ní àlàáfíà nígbà gbogbo. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú gbogbo yín.
17 Pozdrowienie ręką moją Pawłową, co jest znakiem w każdym liście; tak piszę.
Èmi Paulu fi ọwọ́ ara mi kọ lẹ́tà ìkíni yìí, èyí ṣe àmì ìdámọ̀ nínú gbogbo lẹ́tà. Bí mo ṣe máa ń kọ̀wé nìyìí.
18 Łaska Pana naszego, Jezusa Chrystusa, niech będzie z wami wszystkimi. Amen.
Kí oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa wà pẹ̀lú yín.

< II Tesaloniczan 3 >