< II Samuela 7 >

1 I stało się, gdy siedział król w domu swym, a Pan mu dał odpocznienie zewsząd od wszystkich nieprzyjaciół jego.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 Że rzekł król do Natana proroka: Obacz proszę, ja mieszkam w domu cedrowym, a skrzynia Boża mieszka między kortynami.
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 Tedy rzekł Natan do króla: Cokolwiek jest w sercu twojem, idź, uczyń; bo Pan jest z tobą.
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 Potem onejże nocy stało się słowo Pańskie do Natana, mówiąc:
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 Idź a mów do sługi mego Dawida: Tak mówi Pan: Izali mi ty zbudujesz dom ku mieszkaniu?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 Ponieważem nie mieszkał w domu ode dnia, któregom wywiódł syny Izraelskie z Egiptu, aż do dnia tego, alem chodził w namiocie i w przybytku;
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 I wszędzie, gdziem chodził ze wszystkimi syny Izraelskimi, izalim i słowo rzekł któremu z sędziów Izraelskich, któremum rozkazał paść lud mój Izraelski, mówiąc: Czemużeście mi nie zbudowali domu cedrowego?
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 Przetoż teraz to powiedz słudze memu Dawidowi: Tak mówi Pan zastępów: Jam ciebie wziął z owczarni od owiec, abyś był wodzem nad ludem moim, nad Izraelem;
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 I byłem z tobą wszędy, gdzieśkolwiek chodził, i wygładziłem wszystkie nieprzyjacioły twoje przed tobą, i uczyniłem ci imię wielkie, jako imię wielkich ludzi, którzy są na ziemi.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 I postanowię miejsce ludowi memu Izraelskiemu, i wszczepię go, iż będzie mieszkał na miejscu swem, i nie będzie więcej poruszony, ani go więcej synowie nieprawości trapić będą, jako przedtem.
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 Ode dnia, któregom postanowił sędzie nad ludem moim Izraelskim; i dam ci odpocznienie ode wszystkich nieprzyjaciół twoich. Przetoż opowiadać Pan, że on sam tobie dom zbuduje.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 Gdy się wypełnią dnia twoje, i zaśniesz z ojcy twoimi, wzbudzę nasienie twoje po tobie, które wynijdzie z żywota twego, a umocnię królestwo jego;
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 On zbuduje dom imieniowi memu, a Ja utwierdzę stolicę królestwa jego aż na wieki.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Ja mu będę za ojca, a on mi będzie za syna, który gdy wystąpi, skarzę go rózgą ludzką, i plagami synów człowieczych.
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 Lecz miłosierdzie moje nie będzie odjęte od niego, jakom je odjął od Saula, któregom odrzucił przed twarzą twoją.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 I będzie utwierdzony dom twój, i królestwo twoje aż na wieki przed tobą, a stolica twoja będzie trwała aż na wieki.
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Według wszystkich słów tych, i według wszystkiego widzenia tego, tak mówi Natan do Dawida.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Tedy wszedłszy król Dawid, usiadł przed obliczem Pańskiem, i rzekł: Cożem ja jest Panie Boże, i co za dom mój, żeś mię przywiódł aż dotąd?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 Lecz i to mało było przed oblicznością twoją, Panie Boże; aleś też obietnicę uczynił o domie sługi twego na czas daleki, a to prawie obyczajem ludzkim, Panie Boże!
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 I cóż więcej ma mówić Dawid przed tobą? albowiem ty znasz sługę twego, o Panie Boże.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 Dla słowa twego, a według serca twego uczyniłeś te wszystkie wielkie rzeczy, oznajmując je słudze twemu.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 Przetoż wielmożnym jesteś, Panie Boże; bo nie masz podobnego tobie, i nie masz Boga oprócz ciebie, według wszystkiego, cośmy słyszeli w uszy nasze.
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 I gdzież jest taki lud na ziemi, jako Izrael? dla któregoby Bóg szedł aby go sobie odkupił za lud, i uczynił sobie imię, i sprawił wam wielkie i straszne rzeczy w ziemi twojej, przed obliczem ludu twego, któryś sobie wykupił z Egiptu, z pogaństw a i z bogów ich;
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 I zmocniłeś sobie lud twój Izraelski, abyć był ludem aż na wieki; a ty Panie stałeś się im za Boga.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 Przetoż teraz, o Panie Boże, słowo, któreś powiedział o słudze twoim i o domu jego, utwierdź aż na wieki, a uczyń tak jakoś mówił,
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 Aby uwielbione było imię twoje aż na wieki, żeby mówiono: Pan zastępów Bogiem nad Izraelem, a dom sługi twego Dawida będzie umocniony przed twarzą twoją.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 Albowiem ty Panie zastępów, Boże Izraelski, objawiłeś słudze twemu, mówiąc: Dom zbuduję tobie. Przetoż za słuszną rzecz znalazł sługa twój w sercu swojem, aby się modlił tobie tą modlitwą.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 Teraz tedy, Panie Boże, tyś sam Bóg, a słowa twe są prawdą, i rzekłeś do sługi twojego te dobre rzeczy.
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 Raczże już teraz błogosławić domowi sługi twego, aby trwał na wieki przed tobą; boś ty Panie Boże rzekł: Że błogosławieństwem twojem będzie ubłogosławion dom sługi twego na wieki.
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”

< II Samuela 7 >