< II Samuela 23 >
1 A teć są ostateczne słowa Dawidowe. Rzekł Dawid, syn Isajego, rzekł mówię mąż, który był zacnie wywyższony, pomazaniec Boga Jakóbowego, i wdzięczny w pieśniach Izraelskich;
Wọ̀nyí sì ni ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi. “Dafidi ọmọ Jese, àní ọkùnrin tí a ti gbéga, ẹni àmì òróró Ọlọ́run Jakọbu, àti olórin dídùn Israẹli wí pé,
2 Duch Pański mówił przez mię, a słowa jego przechodziły przez język mój.
“Ẹ̀mí Olúwa sọ ọ̀rọ̀ nípa mi, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ ní ahọ́n mi.
3 Mówił Bóg Izraelski do mnie, mówiła skała Izraelska: Ten, który panować będzie nad ludem, będzie sprawiedliwy, panować będzie w bojaźni Bożej.
Ọlọ́run Israẹli ni, àpáta Israẹli sọ fún mi pé, ‘Ẹnìkan ti ń ṣe alákòóso ènìyàn lódodo, tí ń ṣàkóso ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
4 Będzie jako bywa światłość poranna, gdy słońce rano bez obłoków wschodzi, a jako od jasności po deszczu wyrasta ziele z ziemi.
Yóò sì dàbí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nígbà tí oòrùn bá là, òwúrọ̀ tí kò ní ìkùùkuu, nígbà tí koríko tútù bá hù wá láti ilẹ̀ lẹ́yìn òjò.’
5 A choć nie taki jest dom mój przed Bogiem, jednak przymierze wieczne postanowił ze mną, utwierdzone we wszystkiem i obwarowane. A w temci jest wszystko zbawienie moje, i wszystka uciecha moja, aczkolwiek temu jeszcze wzrostu nie dawa.
“Lóòtítọ́ ilé mi kò rí bẹ́ẹ̀ níwájú Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ó ti bá mi dá májẹ̀mú àìnípẹ̀kun, tí a túnṣe nínú ohun gbogbo, tí a sì pamọ́; nítorí pé gbogbo èyí ni ìgbàlà, àti gbogbo ìfẹ́ mi, ilé mi kò lè ṣe kí ó má dàgbà.
6 Ale nipobożni wszyscy będą jako cierń wyrwani, którego rękoma nie biorą.
Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọ Beliali yóò dàbí ẹ̀gún ẹ̀wọ̀n tí a ṣá tì, nítorí pé a kò lè fi ọwọ́ kó wọn.
7 Lecz kto się go jedno chce dotknąć, obwaruje się żelazem i drzewem włóczni, albo ogniem wypala go do szczętu na miejscu jego.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí yóò tọ́ wọn yóò fi irin àti ọ̀pá ọ̀kọ̀ ṣagbára yí ara rẹ̀ ká; wọ́n ó jóná lúúlúú níbìkan náà.”
8 Teć są imiona mocarzów, które miał Dawid: Jozeb Basebet Tachmojczyk, najprzedniejszy między trzema; który się z uciechą rzucił na ośm set ludu z włócznią, aby je zabił w jednej potrzebie.
Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn akọni ọkùnrin tí Dafidi ní: Joṣebu-Basṣebeti ará Takemoniti ni olórí àwọn balógun, òun sì ni akọni rẹ̀ tí ó pa ẹgbẹ̀rin ènìyàn lẹ́ẹ̀kan náà.
9 A po nim był Eleazar, syn Dodona, syna Ahohowego, między trzema mocarzami, którzy byli z Dawidem; a sromotnie lżyli Filistyny, którzy się byli zebrali ku bitwie, gdy byli odciągnęli mężowie Izraelscy.
Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Eleasari ọmọ Dodo ará Ahohi, ọ̀kan nínú àwọn alágbára ọkùnrin mẹ́ta ti ó wà pẹ̀lú Dafidi, nígbà tí wọ́n pe àwọn Filistini ní ìjà, àwọn ọkùnrin Israẹli sì ti lọ kúrò.
10 Ten powstawszy bił Filistyny, tak iż ustała ręka jego, i zdrętwiała ręka jego przy mieczu. Tedy sprawił Pan wielkie wybawienie dnia onego, tak, że się lud wrócił za nim, tylko aby korzyści zebrał.
Òun sì dìde, ó sì kọlu àwọn Filistini títí ọwọ́ fi kún un, ọwọ́ rẹ̀ sì lẹ̀ mọ́ idà; Olúwa sì ṣiṣẹ́ ìgbàlà ńlá lọ́jọ́ náà, àwọn ènìyàn sì padà bọ̀ lẹ́yìn rẹ̀ láti kó ìkógun.
11 A po nim był Semma, syn Agi, Hararczyk; albowiem gdy się byli Filistynowie zebrali do kupy, kędy była część pola pełnego soczewicy, a lud inny był uciekł przed Filistynami:
Ẹni tí ó tẹ̀lé e ni Ṣamma ọmọ Agee ará Harari, àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ láti piyẹ́, oko kan sì wà níbẹ̀ tí ó kún fun lẹntili, àwọn ọmọ-ogun Israẹli sì sá kúrò níwájú àwọn Filistini.
12 Tedy stanąwszy w pośród onej części pola, bronił go, i pobił Filistyny. A tak sprawił Pan wielkie wybawienie.
Ṣamma sì dúró láàrín méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbà á sílẹ̀, ó sì pa àwọn Filistini Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.
13 Wyszli też oni trzej z trzydziestu przedniejszych, a przyszli we żniwa do Dawida, do jaskini Odollam, gdy się wojsko Filistyńskie było obozem położyło w dolinie Refaim.
Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀, wọ́n sì tọ Dafidi wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Adullamu, ọ̀wọ́ àwọn Filistini sì dó sí àfonífojì Refaimu.
14 A Dawid na ten czas był na miejscu obronnem: straż też Filistyńska na ten czas była w Betlehem.
Dafidi sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Filistini sì wà ní Bẹtilẹhẹmu nígbà náà.
15 Tedy pragnął Dawid, i rzekł: O by mi się kto dał napić wody z studni Betlehemskiej, która jest u bramy!
Dafidi sì ń pòǹgbẹ, ó wí báyìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kànga tí ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè.”
16 Przetoż wpadli ci trzej mocarze do obozu Filistyńskiego, i naczerpali wody z studni Betlehemskiej, która była u bramy; którą nieśli, i przynieśli do Dawida. Ale jej on nie chciał pić, lecz ją wylał przed Panem.
Àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta sì la ogún àwọn Filistini lọ, wọ́n sì fa omi láti inú kànga Bẹtilẹhẹmu wá, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu-bodè, wọ́n sì mú tọ Dafidi wá, òun kò sì fẹ́ mu nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tú u sílẹ̀ fún Olúwa.
17 I rzekł: Nie daj mi tego Panie, abym to miał uczynić. Izali to nie krew mężów, którzy szli z niebezpieczeństwem dusz swoich? I nie chciał jej pić. Toć uczynili oni trzej mocarze.
Òun sì wí pé, “Kí a má rí, Olúwa, tí èmi ó fi ṣe èyí; ṣé èyí ni ẹ̀jẹ̀ àwọn ọkùnrin tí ó lọ tí àwọn tí ẹ̀mí wọn lọ́wọ́?” Nítorí náà òun kò sì fẹ́ mú un. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ṣe.
18 Także Abisaj brat Joaba, syn Sarwii był przedniejszym między trzema. Ten podniósł włócznią swą przeciwko trzema stom, i zabił je, i był sławnym między trzema.
Abiṣai, arákùnrin Joabu, ọmọ Seruiah, òun náà ni pàtàkì nínú àwọn mẹ́ta. Òun ni ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè sí ọ̀ọ́dúnrún ènìyàn, ó sì pa wọ́n, ó sì ní orúkọ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta.
19 Z tych trzech będąc najsławniejszym, był ich hetmanem; wszakże onych trzech pierwszych nie doszedł.
Ọlọ́lá jùlọ ni òun jẹ́ nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, ó sì jẹ́ olórí fún wọn, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ìṣáájú.
20 Banajas też syn Jojady, syn męża rycerskiego, zacny w swych sprawach, z Kabseel; ten zabił dwóch mocarzów Moabskich, tenże szedłszy zabił lwa w pośrodku studni, we dni śnieżne.
Benaiah, ọmọ Jehoiada, ọmọ akọni ọkùnrin kan tí Kabṣeeli, ẹni tí ó pọ̀ ní iṣẹ́ agbára, òun pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu; ó sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ó sì pa kìnnìún kan nínú ihò lákoko òjò-dídì.
21 Tenże zabił męża Egipczanina, męża na podziw wielkiego, który Egipczanin miał w ręku włócznią; a on szedł ku niemu z kijem, a wydarłszy włócznią z ręki Egipczanina, zabił go włócznią jego.
Ó sì pa ará Ejibiti kan, ọkùnrin tí ó dára láti wò, ará Ejibiti náà sì ní ọ̀kọ̀ kan ní ọwọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n Benaiah sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ, pẹ̀lú ọ̀pá ní ọwọ́, ó sì gba ọ̀kọ̀ náà lọ́wọ́ ará Ejibiti náà, ó sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ pa á.
22 Toć uczynił Banajas, syn Jojady, który też był sławny między onymi trzema mocarzami.
Nǹkan wọ̀nyí ní Benaiah ọmọ Jehoiada ṣe, ó sì ní orúkọ nínú àwọn ọkùnrin alágbára mẹ́ta náà.
23 Z tych trzydziestu był najsławniejszym; wszakże onych trzech nie doszedł; i postawił go Dawid nad drabantami swoimi.
Nínú àwọn ọgbọ̀n náà, òun ní ọlá jùlọ, ṣùgbọ́n òun kò tó àwọn mẹ́ta ti ìṣáájú. Dafidi sì fi í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀.
24 Był też Asael, brat Joaba, między trzydziestoma. A ci są: Elkanan, syn Dodana, Betlehemczyk;
Ọ̀kan nínú àwọn ọgbọ̀n náà: Asaheli arákùnrin Joabu sì Jásí Elhanani ọmọ Dodo ti Bẹtilẹhẹmu;
25 Samma Harodczyk; Elika Harodczyk.
Ṣamma ará Haroditi, Elika ará Harodi.
26 Heles Faltyczyk; Hyra, syn Ikkiesa, Tekuitczyk;
Helesi ará Palti, Ira ọmọ Ikẹsi ará Tekoa;
27 Abijezer Anatotczyk; Mobonaj Husatczyk;
Abieseri ará Anatoti, Sibekai ará Huṣati;
28 Selmon Ahohytczyk; Maharaj Netofatczyk;
Salmoni ará Ahohi, Maharai ará Netofa;
29 Heleb, syn Baany, Netofatczyk; Itaj, syn Rybajego, z Gabaad synów Benjaminowych;
Heledi ọmọ Baanah, ará Netofa, Ittai ọmọ Ribai to Gibeah ti àwọn ọmọ Benjamini;
30 Banajas Faratończyk; Haddaj od potoku Gaas;
Benaiah ará Piratoni, Hiddai ti àfonífojì Gaaṣi,
31 Abijalbon Arbatczyk; Asmewet Barchomczyk;
Abi-Alboni ará Arbati, Asmafeti Barhumiti;
32 Elijachba Salabończyk; z synów Jassonowych Jonatana;
Eliaba ará Ṣaalboni, àwọn ọmọ Jaṣeni, Jonatani;
33 Semma Hororczyk; Ahijam, syn Sarara, Ararytczyk;
ọmọ Ṣamma ará Harari, Ahiamu ọmọ Ṣarari ará Harari;
34 Elifelet, syn Achasbaja, syna Machatego; Elijam, syn Achitofela Gilończyka.
Elifeleti ọmọ Ahasbai, ọmọ ará Maakati, Eliamu ọmọ Ahitofeli ará Giloni;
35 Hezraj Karmelczyk; Faraj Arbitczyk.
Hesro ará Karmeli, Paarai ará Arba;
36 Igal, syn Natana z Soby; Bani Gadczyk.
Igali ọmọ Natani ti Soba, Bani ará Gadi;
37 Selek Ammonitczyk; Nacharaj Berotczyk, który nosił broń Joaba, syna Sarwii;
Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beeroti, ẹni tí ń ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah;
38 Hira Jetrytczyk; Gareb Jetrytczyk.
Ira ará Itri, Garebu ará Itri.
39 Uryjasz Hetejczyk. Owa wszystkich trzydzieści i siedm.
Uriah ará Hiti. Gbogbo wọn jẹ́ mẹ́tàdínlógójì.