< II Samuela 14 >

1 A porozumiawszy Joab, syn Sarwii, że się serce królewskie obróciło ku Absalomowi,
Joabu ọmọ Seruiah sì kíyèsi i, pé ọkàn ọba sì fà sí Absalomu.
2 Posłał Joab do Tekuj, i wziął stamtąd niewiastę mądrą, i rzekł do niej: Proszę zmyśl, jakobyś w żałobie była, a oblecz się proszę w szaty żałobne, i nie namazuj się olejkiem, ale bądź jako niewiasta, która przez wiele dni w żałobie chodziła po uma rłym.
Joabu sì ránṣẹ́ sí Tekoa, ó sì mú ọlọ́gbọ́n obìnrin kan láti ibẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, ṣe bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀, kí o sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sára, kí o má sì ṣe fi òróró pa ara, kí o sì dàbí obìnrin ti ó ti ń ṣọ̀fọ̀ fún òkú lọ́jọ́ púpọ̀.
3 I wnijdziesz do króla, a będziesz mówiła do niego w ten sposób; i nauczył jej Joab, jako miała mówić.
Kí o sì tọ ọba wá, kí o sọ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí.” Joabu sì fi ọ̀rọ̀ sí lẹ́nu.
4 Przetoż mówiła ona niewiasta Tekuitska do króla, upadłszy obliczem swem na ziemię, a pokłoniwszy się rzekła: Ratuj królu!
Nígbà tí obìnrin àrá Tekoa sì ń fẹ́ sọ̀rọ̀ fún ọba, ó wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀, o sí bu ọlá fún un, o sì wí pé, “Ọba, gbà mi.”
5 I rzekł jej król: Cóż ci? A ona odpowiedziała: Zaistem ja niewiasta wdowa; bo mi mąż mój umarł:
Ọba sì bi í léèrè pé, “Kín ni o ṣe ọ́?” Òun sì dáhùn wí pé, “Nítòótọ́ opó ni èmi ń ṣe, ọkọ mi sì kú.
6 A służebnica twoja miała dwóch synów, którzy się powadzili z sobą na polu; a gdy nie był, ktoby je rozwadził, a ranił jeden drugiego, i zabił go.
Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì ti ní ọmọkùnrin méjì, àwọn méjèèjì sì jọ jà lóko, kò sì si ẹni tí yóò là wọ́n, èkínní sì lu èkejì, ó sì pa á.
7 A oto, powstawszy wszystka rodzina przeciw służebnicy twojej, mówią: Wydaj tego, który zabił brata swego, że go zabijemy za duszę brata jego, którego zamordował, owszem zgładzimy i dziedzica; a tak zagaszą iskierkę moję, która pozostała, aby nie z ostawili mężowi memu imienia i szczątku na ziemi.
Sì wò ó, gbogbo ìdílé dìde sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Fi ẹni tí ó pa arákùnrin rẹ fún wa, àwa ó sì pa á ní ipò ẹ̀mí arákùnrin rẹ̀ tí ó pa, àwa ó sì pa àrólé náà run pẹ̀lú.’ Wọn ó sì pa iná mi tí ó kù, wọn kì yóò sì fi orúkọ tàbí ẹni tí ó kú sílẹ̀ fún ọkọ mi ní ayé.”
8 Tedy rzekł król do niewiasty: Idź do domu twego, a ja skażę za tobą.
Ọba sì wí fún obìnrin náà pé, “Lọ sí ilé rẹ̀, èmi ó sì kìlọ̀ nítorí rẹ.”
9 I odpowiedziała niewiasta Tekuicka królowi: Królu, panie mój, niech będzie na mnie ta nieprawość, i na dom ojca mego; ale król i stolica jego niech będzie niewinna.
Obìnrin ará Tekoa náà sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi, ọba, jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ náà wà lórí mi, àti lórí ìdílé baba mí; kí ọba àti ìtẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ aláìlẹ́bi.”
10 I rzekł król: Będzieli kto mówił przeciwko tobie, przywiedź go do mnie, a potem nie tknie się ciebie więcej.
Ọba sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ sí ọ, mú ẹni náà tọ̀ mí wá, òun kì yóò sì tọ́ ọ mọ́.”
11 Tedy ona rzekła: Wspomnij proszę, królu, na Pana Boga twego, aby się nie mnożyli mściciele krwi na zgubę, a nie zgładzili syna mego. I odpowiedział: Jako żywy Pan, że nie spadnie i najmniejszy włos syna twego na ziemię.
Ó sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí ọba ó rántí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má ṣe ní ipá láti ṣe ìparun, kí wọn o má bá a pa ọmọ mi!” Òun sì wí pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè ọ̀kan nínú irun orí ọmọ rẹ ki yóò bọ sílẹ̀.”
12 Zatem rzekła niewiasta: Niech przemówi proszę służebnica twoja do króla, pana mego, słowo. A on rzekł: Mów.
Obìnrin náà sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ sọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi ọba.” Òun si wí pé, “Máa wí.”
13 Rzekła tedy niewiasta: I czemużeś umyślił podobną rzecz przeciw ludowi Bożemu? albowiem król mówi to słowo, jakoby był winny, ponieważ nie chcesz przywrócić, królu, wygnańca swego.
Obìnrin náà sì wí pé, “Nítorí kín ni ìwọ sì ṣe ro irú nǹkan yìí sí àwọn ènìyàn Ọlọ́run? Nítorí pé ní sísọ nǹkan yìí ọba ní ẹ̀bi, nítorí pé ọba kò mú ìsáǹsá rẹ̀ bọ̀ wá ilé.
14 Wszyscy umieramy, a jesteśmy jako wody rozlane po ziemi, które nie mogą być zebrane; lecz jemu Bóg nie odjął żywota, ale pewnie umyślił, aby nie wyganiał od siebie wygnańca.
Nítorí pé àwa ó sá à kú, a ó sì dàbí omi tí a tú sílẹ̀ tí a kò sì lè ṣàjọ mọ́; nítorí bí Ọlọ́run kò ti gbà ẹ̀mí rẹ̀, ó sì ti ṣe ọ̀nà kí a má bá a lé ìsáǹsá rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
15 A teraz, żem przyszła mówić do króla, pana mego, te słowa, przyczyną jest, że mię postraszył lud; przetoż rzekła służebnica twoja: Będę teraz mówiła do króla, snać co uczyni król na prośbę służebnicy swojej.
“Ǹjẹ́ nítorí náà ni èmi sì ṣe wá sọ nǹkan yìí fún olúwa mi ọba, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ti dẹ́rùbà mí; ìránṣẹ́bìnrin rẹ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ èmi ó sọ fún ọba; ó lè rí bẹ́ẹ̀ pé ọba yóò ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ fún un.
16 Albowiem usłyszy to król, i wybawi służebnicę swoję z rąk męża, który wygładzić chce mnie, i syna mego społem, z dziedzictwa Bożego.
Nítorí pé ọba ò gbọ́, láti gbà ìránṣẹ́bìnrin rẹ sílẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin náà tí ó ń fẹ́ gé èmi àti ọmọ mi pẹ̀lú kúrò nínú ilẹ̀ ìní Ọlọ́run.’
17 Rzekła też służebnica twoja: Wżdyć mi będzie słowo króla, pana mego, ku pociesze; albowiem jako Anioł Boży, tak jest król, pan mój, słuchając dobrego i złego, a Pan Bóg twój niech będzie z tobą.
“Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ọba olúwa mi yóò sì jásí ìtùnú; nítorí bí angẹli Ọlọ́run bẹ́ẹ̀ ni olúwa mi ọba láti mọ rere àti búburú: Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.’”
18 A odpowiadając król rzekł do niewiasty: Proszę nie taj przedemną tego, o co się spytam. I rzekła niewiasta: Mów proszę, królu, panie mój.
Ọba sì dáhùn, ó sì wí fún obìnrin náà pé, “Má ṣe fi nǹkan tí èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ pamọ́ fún mi, èmi bẹ̀ ọ́.” Obìnrin náà wí pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba máa wí?”
19 Tedy rzekł król: Izali ty tego wszystkiego nie czynisz z naprawy Joabowej? I odpowiedziała niewiasta, i rzekła: Jako żyje dusza twoja, królu, panie mój, że nie można uchylić się ani na prawo, ani na lewo od wszystkiego, co mówił król, pan mój; albowiem sługa twój Joab, on mi to rozkazał, i on nauczył służebnicy twojej tych wszystkich słów.
Ọba sì wí pé, “Ọwọ́ Joabu kò ha wà pẹ̀lú rẹ nínú gbogbo èyí?” Obìnrin náà sì dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹ̀mí rẹ ti ń bẹ láààyè, olúwa mi ọba, kò sí ìyípadà sí ọwọ́ ọ̀tún, tàbí sí ọwọ́ òsì nínú gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti wí, nítorí pé Joabu ìránṣẹ́ rẹ, òun ni ó rán mi, òun ni ó sì fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ lẹ́nu.
20 Żem odmieniła sposób tej mowy, sprawił to sługa twój Joab; lecz pan mój mądry jest, jako jest mądry Anioł Boży, wiedząc wszystko, co się dzieje na ziemi.
Láti mú irú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá ni Joabu ìránṣẹ́ rẹ ṣe ṣe nǹkan yìí: olúwa mi sì gbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n angẹli Ọlọ́run, láti mọ gbogbo nǹkan tí ń bẹ̀ ní ayé.”
21 Przetoż rzekł król do Joaba: Otom teraz to uczynił. Idźże a przywróć dziecię me Absaloma.
Ọba sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, èmi ó ṣe nǹkan yìí, nítorí náà lọ, kí o sì mú ọmọdékùnrin náà Absalomu padà wá.”
22 I upadł Joab obliczem swem na ziemię, a pokłoniwszy się błogosławił królowi, i rzekł Joab: Dziś poznał sługa twój, żem znalazł łaskę w oczach twoich, królu, panie mój, ponieważ uczynił król zadość prośbie sługi swego.
Joabu sì wólẹ̀ ó dojú rẹ̀ bolẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì súre fún ọba. Joabu sì wí pé, “Lónìí ni ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé, èmi rí oore-ọ̀fẹ́ gbà lójú rẹ, olúwa mi, ọba, nítorí pé ọba ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀.”
23 Wstał tedy Joab, a szedł do Giessur, i przywiódł Absaloma do Jeruzalemu.
Joabu sì dìde, ó sì lọ sí Geṣuri, ó sì mú Absalomu wá sí Jerusalẹmu.
24 I rzekł król: Niech się wróci do domu swego, ale oblicza mego niech nie widzi. A tak wrócił się Absalom do domu swego, ale oblicza królewskiego nie widział.
Ọba sì wí pé, “Jẹ́ kí ó yípadà lọ sí ilé rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ó rí ojú mi.” Absalomu sì yípadà sí ilé rẹ̀, kò sì rí ojú ọba.
25 A nie było męża tak krasnego, jako Absalom we wszystkim Izraelu, coby miał tak wielką chwałę; od stopy nogi jego aż do wierzchu głowy jego nie było na nim zmazy.
Kó sì sí arẹwà kan ní gbogbo Israẹli tí à bá yìn bí Absalomu: láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀ kò sí àbùkù kan lára rẹ̀.
26 A gdy strzygł głowę swoję, (a zwykł ją na każdy rok strzydz; bo mu ciążyła, przetoż ją strzygł, ) ważyły włosy głowy jego dwieście syklów wagi królewskiej.
Nígbà tí ó bá sì rẹ́ irun orí rẹ̀ (nítorí pé lọ́dọọdún ni òun máa ń rẹ́ ẹ. Nígbà tí ó bá wúwo fún un, òun a sì máa rẹ́ ẹ) òun sì wọn irun orí rẹ̀, ó sì jásí igba ṣékélì nínú òsùwọ̀n ọba.
27 I urodzili się Absalomowi trzej synowie, i córka jedna, której imię było Tamar, która niewiasta była piękna na wejrzeniu.
A sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún Absalomu àti ọmọbìnrin kan ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tamari: òun sì jẹ́ obìnrin tí ó lẹ́wà lójú.
28 I mieszkał Absalom w Jeruzalemie dwa lata, a twarzy królewskiej nie widział.
Absalomu sì gbé ni ọdún méjì ní Jerusalẹmu kò sì rí ojú ọba.
29 Przetoż posłał Absalom do Joaba, chcąc go posłać do króla, ale on nie chciał przyjść do niego; posłał potem powtóre, i nie chciał przyjść.
Absalomu sì ránṣẹ́ sí Joabu, láti rán an sí ọba, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.
30 Tedy rzekł do sług swoich: Przepatrzcie rolę Joabową podle roli mojej, gdzie ma jęczmień; idźcież, a spalcie go ogniem. I zapalili słudzy Absalomowi rolę onę ogniem.
Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Joabu gbé ti èmi, ó sì ní ọkà barle níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́.” Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tiná bọ oko náà.
31 Zatem wstawszy Joab, przyszedł do Absaloma w dom, i rzekł do niego: Czemóż słudzy twoi spalili rolę moję ogniem?
Joabu sì dìde, ó sì tọ Absalomu wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tiná bọ oko mi?”
32 I odpowiedział Absalom Joabowi: Otom posłał do ciebie, mówiąc: Przyjdź sam, a poślę cię do króla, abyś mówił: Nacóżem przyszedł z Giessur? Lepiej mi było tam jeszcze zostać; przetoż teraz niech oglądam oblicze królewskie; wszak jeźli jest przy mnie nieprawość, niech mię rozkaże zabić.
Absalomu sì dá Joabu lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Geṣuri wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn ún síbẹ̀!”’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”
33 Tedy przyszedł Joab do króla, i oznajmił mu. I przyzwał Absaloma, który przyszedł do króla, i ukłonił się twarzą swą ku ziemi przed królem; i pocałował król Absaloma.
Joabu sì tọ ọba wá, ó sì rò fún un: ó sì ránṣẹ́ pe Absalomu, òun sì wá sọ́dọ̀ ọba, ó tẹríba fún un, ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀ níwájú ọba, ọba sì fi ẹnu ko Absalomu lẹ́nu.

< II Samuela 14 >