< II Samuela 10 >
1 I stało się potem, że umarł król synów Ammonowych, a królował Hanon, syn jego, po nim.
Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
2 Tedy rzekł Dawid: Uczynię miłosierdzie z Hanonem, synem Nahasowym, jako uczynił ojcec jego miłosierdzie ze mną. I posłał Dawid ciesząc go przez sługi swe po ojcu jego, a tak przyszli słudzy Dawidowi do ziemi synów Ammonowych.
Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
3 Ale książęta synów Ammonowych rzekły do Hanona, pana swego: I mniemasz, żeby to uczciwość czynił Dawid ojcu twemu, iż przysłał do ciebie tych, którzyby cię cieszyli? Azaż raczej nie dla tego posłał Dawid sługi swe do ciebie aby przepatrzyli miasto, i wyszpiegowali je, aby je potem zburzył?
Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
4 A tak wziąwszy Hanon sługi Dawidowe, ogolił im po połowie brody ich, i poobrzynał szaty ich aż do połowy, aż do zadków ich, i puścił je.
Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
5 A gdy to opwiedziano Dawidowi, posłał przeciwko nim, (ponieważ oni mężowie byli bardzo obelżeni, ) i rzekł im król: Zostńcie w Jerycho, aż odrosną brody wasze, a potem się wrócicie.
Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
6 Widząc tedy synowie Ammonowi, że się zbrzydzili Dawidowi posłali ciż synowie Ammonowi, i najęli za pieniądze Syryjczyka z domu Rechob, i Syryjczyka w Soba, dwadzieścia tysięcy pieszych, a od króla Maacha tysiąc mężów, a od Istoba dwanaście tysięcy mężów.
Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
7 Co gdy usłyszał Dawid, posłał Joaba ze wszystkiem wojskiem ludzi rycerskich.
Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
8 Tedy synowie Ammonowi wyciągnęli, a uszykowali się do bitwy przed samem wejściem w bramę; Syryjczyk zasię z Soby, i Rechob, i Istob, i Maacha byli osobno w polu.
Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
9 Przetoż widząc Joab uszykowane wojska przeciwko sobie z przodku i z tyłu, wybrał niektóre ze wszystkich przebranych z Izraela, i uszykował wojsko przeciwko Syryjczykom.
Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
10 A ostatek ludu dał pod rękę Abisaja, brata swego, i uszykował je przeciwko synom Ammonowym.
Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
11 I rzekł: Jeźli mi Syryjczycy będą silnymi, będziesz mi na pomoc, a jeźli tobie synowie Ammonowi będą silnymi przyjdęć na pomoc.
Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
12 Zmacniaj się, a bądźmy mężnymi za lud nasz, i za miasto Boga naszego, a Pan niech uczyni, co dobrego jest w oczach jego.
Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
13 Nastąpił tedy Joab, i lud, który był z nim, aby zwiódł bitwę z Syryjczykami; a oni uciekali przed nim.
Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
14 Tedy synowie Ammonowi ujrzawszy, że uciekli Syryjczycy; uciekli i oni przed Abisajem, i weszli do miasta. A Joab wrócił się od synów Ammonowych, i przyszedł do Jeruzalemu.
Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
15 A gdy obaczyli Syryjczycy, iż są porażeni od Izraela, zebrali się wespół.
Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
16 I posłał Hadadezer, a wywiódł Syryjczyki, którzy byli za rzeką, i przyciągnęli do Helam, a Sobach, hetman wojska Hadadezerowego prowadził je.
Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
17 I oznajmiono to Dawidowi; który zebrawszy wszystkiego Izraela, przeprawił się przez Jordan, i przyszedł do Helam, gdzie uszykowawszy wojsko Syryjczycy przeciw Dawidowi, zwiedli z nim bitwę.
Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
18 Tedy uciekli Syryjczycy przed Izraelem, i poraził Dawid Syryjczyków siedm set wozów, i czterdzieści tysięcy jezdnych; do tego Sobacha, hetmana wojska ich, ranił, który tamże umarł.
Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
19 A gdy ujrzeli wszyscy królowie, hołdownicy Hadadezerowi, iż porażeni byli od Izraela, uczynili pokój z Izraelem, i służyli im; i bali się Syryjczycy dawać pomocy na potem synom Ammonowym.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.