< II Królewska 9 >

1 A Elizeusz prorok zawołał jednego z synów prorockich, i rzekł mu: Przepasz biodra twoje, a weźmij tę bańkę olejku w rękę twą, a idź do Ramot Galaadskiego.
Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
2 A gdy tam przyjdziesz, ujrzysz tam Jehu, syna Jozafatowego, syna Namsy, a wszedłszy tam, odwiedziesz go z pośrodku braci jego, i wprowadzisz go do gmachu najskrytszego.
Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
3 A wziąwszy bańkę olejku, wylejesz na głowę jego, i rzeczesz: Tak mówi Pan: Pomazałem cię za króla nad Izraelem. A otworzywszy drzwi ucieczesz, i nie zabawisz się tam.
Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
4 Tedy odszedł on młodzieniec, sługa prorocki, do Ramot Galaadskiego.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
5 A gdy przyszedł, oto hetmani wojsk siedzieli. I rzekł: Hetmanie! mam nieco z tobą mówić. I rzekł Jehu: Z którymże ze wszystkich nas? I odpowiedział: Z tobą, hetmanie!
Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
6 Tedy wstawszy wszedł do gmachu, a on wylał olejek na głowę jego, i rzekł mu: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Pomazałem cię za króla nad ludem Pańskim, nad Izraelem.
Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
7 I wytracisz dom Achaba, pana twego; albowiem pomszczę się krwi sług moich proroków, i krwi wszystkich sług Pańskich, z ręki Jezabeli.
Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
8 A tak zginie wszystek dom Achabowy; i wykorzenię z domu Achabowego aż do najmniejszego szczenięcia, i więźnia, i opuszczonego w Izraelu.
Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
9 I uczynię domowi Achabowemu, jako domowi Jeroboama, syna Nabatowego, i jako domowi Baazy, syna Achyjaszowego.
Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
10 Jezabelę też zjedzą psy na polu Jezreelskim, a nie będzie, ktoby ją pogrzebał. To rzekłszy otworzył drzwi, i uciekł.
Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
11 A gdy Jehu wyszedł do sług pana swego, rzekł mu jeden: A dobrzeż wszystko? Pocóż przychodził ten szalony do ciebie? A on im odpowiedział: Wy znacie tego męża, i mowę jego.
Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
12 Tedy rzekli: Nie prawda to; proszę powiedz nam. A on rzekł: Tak a tak rzekł do mnie, mówiąc: Tak mówi Pan: Pomazałem cię za króla nad Izraelem.
“Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
13 Pospieszyli się tedy, a wziąwszy każdy szatę swą, kładli je podeń na najwyższym stopniu, i zatrąbiwszy w trąbę, mówili: Króluje Jehu!
Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
14 Tedy się sprzysiągł Jehu, syn Jozafata, syna Namsy, przeciw Joramowi. (A na ten czas Joram strzegł Ramot Galaadskiego, on i wszystek Izrael, przed Hazaelem, królem Syryjskim.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
15 Ale się był wrócił król Joram, aby się leczył na rany, które mu byli zadali Syryjczycy, gdy walczył z Hazaelem, królem Syryjskim.) I rzekł Jehu: Jeźli się wam zda, niech nie wychodzi nikt z miasta, żeby szedł co oznajmić w Jezreelu.
ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
16 I wsiadł na wóz Jehu, i jechał do Jezreela, bo tam Joram leżał; Ochozyjasz także, król Judzki, przyjechał był, aby nawiedził Jorama.
Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
17 Wtem stróż, który stał na wieży w Jezreelu, ujrzawszy poczet Jehu przyjeżdżający, rzekł: Poczet jakiś widzę. I rzekł Joram: Weźmij jezdnego, a wyślij przeciwko nim, aby się spytał, jeźli pokój.
Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
18 A tak bieżał jezdny przeciwko niemu, i rzekł: Tak mówi król: A pokój? I odpowiedział Jehu: Co tobie do pokoju? Obróć się, jedź za mną. Przetoż oznajmił stróż mówiąc: Dojechałci poseł do nich, ale się nie wraca.
Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
19 Zatem posłał drugiego jezdnego, który przyjechawszy do nich, rzekł: Tak mówi król: A pokój? Odpowiedział Jehu: Co tobie do pokoju? Obróć się, a jedź za mną.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
20 Znowu oznajmił to stróż, mówiąc: Przyjechałci do nich, ale się nie wraca. A przyjazd jego, jakoby przyjazd Jehu, syna Namsy; bo szalenie jedzie.
Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
21 Tedy rzekł Joram: Zaprzęgaj. I zaprzężono w wóz jego. I wyjechał Joram, król Izraelski, i Ochozyjasz, król Judzki, każdy na wozie swym. A wyjechawszy przeciw Jehu, trafili go na polu Nabota Jezreelskiego.
“Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
22 A gdy ujrzał Joram Jehu, rzekł: Jestże pokój Jehu? I odpowiedział: Co za pokój? ponieważ jeszcze cudzołóstwa Jezabeli, matki twojej, i czary jej wielkie są.
Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
23 Przetoż obróciwszy się Joram uciekł, mówiąc do Ochozyjasza: Zdrada, Ochozyjaszu!
Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
24 Tedy Jehu wziąwszy w ręce swoje łuk, postrzelił Jorama między ramiona jego, aż przeszła strzała przez serce jego, tak, że padł na wozie swoim.
Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
25 Potem rzekł Jehu do Badakiera, hetmana swego: Weźmij go, a porzuć na polu Nabota Jezreelskiego; albowiem pamiętasz, gdyśmy ja i ty jechali społu za Achabem, ojcem jego, że Pan wydał był przeciwko niemu tę pogróżkę.
Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
26 Zaiste krwi Nabota, i krwi synów jego, którąm widział wczoraj, rzekł Pan, pomszczę się nad tobą na tem polu. Pan to rzekł: przetoż teraz weźmij go, a porzuć go na polu według słowa Pańskiego.
‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
27 Co Ochozyjasz, król Judzki, ujrzawszy, uciekał drogą do domu ogrodowego. Ale go gonił Jehu, i rzekł: I tego zabijcie na wozie jego. I zranili go na wstąpie Guru, który jest podle Jeblaam. A uciekł do Magieddy, i tam umarł.
Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
28 I kazali go zawieść słudzy jego do Jeruzalemu, a pogrzebli go w grobie jego z ojcami jego w mieście Dawidowem.
Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
29 A roku jedenastego Jorama, syna Achabowego, królował Ochozyjasz nad Judą.
(Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
30 Zatem przyszedł Jehu do Jezreel. Co gdy Jezabela usłyszała, ufarbowała twarz swoję, i ochędożyła głowę swą a patrzała z okna.
Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
31 A gdy Jehu wjeżdżał w bramę, rzekła: Jestże pokój, o Zymry, morderzu pana swego?
Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
32 A on podniósłszy twarz swoję ku oknu, rzekł: Któż ze mną trzyma, kto? Tedy wejrzeli nań dwaj albo trzej komornicy jej.
Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
33 Którym rzekł: Zrzućcie ją. I zrzucili ją, i popryskała się ściana i konie krwią jej, i podeptał ją.
Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
34 A gdy tam wszedł, jadł i pił, i rzekł: Obaczcie proszę onę przeklętą, a pogrzebcie ją; boć córką królewską jest.
Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
35 Tedy szedłszy, aby ją pogrzebli, nie znaleźli z niej jedno czaszkę z głowy, i nogi, i dłoni rąk.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
36 A wróciwszy się, oznajmili mu to. Który rzekł: Wypełniło się słowo Pańskie, które powiedział przez sługę swego Elijasza Tesbitę, mówiąc: Na polu Jezreel zjedzą psy ciało Jezabeli.
Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
37 Niech będzie trup Jezabeli, jako gnój na roli, na polu Jezreel, tak żeby nie mówiono. Tać jest Jezabela.
Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”

< II Królewska 9 >