< II Królewska 20 >
1 W one dni zachorował Ezechyjasz aż na śmierć, i przyszedł do niego Izajasz prorok, syn Amosowy, i rzekł mu: Tak mówi Pan: Rozpraw dom twój; bo umrzesz, a nie będziesz żył.
Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Hesekiah ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò ní í gbádùn.”
2 Tedy obrócił Ezechyjasz twarz swoję do ściany, i modlił się Panu, mówiąc:
Hesekiah yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
3 Proszę, o Panie! wspomnij teraz, żem chodził przed tobą w prwadzie, i w sercu całem, czyniąc to, co dobrego jest w oczach twoich. I płakał Ezechyjasz płaczem wielkiem.
“Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtítọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Hesekiah sọkún kíkorò.
4 Ale jeszcze Izajasz nie wyszedł był do pół sieni, gdy się słowo Pańskie stało do niego, mówiąc:
Kí ó tó di wí pé Isaiah jáde kúrò ní àárín àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé:
5 Wróć się, a mów do Ezechyjasza, wodza ludu mego: Tak mówi Pan, Bóg Dawida, ojca twego: Wysłuchałem modlitwę twoję, a widziałem łzy twoje; oto Ja uzdrawiam cię, dnia trzeciego wnijdziesz do domu Pańskiego;
“Lọ padà kí o sì sọ fún Hesekiah, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dafidi sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò wò ọ́ sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsin yìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
6 I przydam do dni twoich piętnaście lat, a z ręki króla Assyryjskiego wyrwę ciebie, i to miasto; i bronić będę tego miasta dla siebie, i dla Dawida, sługi mego.
Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ. Èmi yóò sì gbà ọ́ àti ìlú ńlá yìí láti ọwọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí nítorí ti èmi tìkára mi àti nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi.’”
7 Przytem rzekł Izajasz: Przynieście bryłę fig suchych. Którą przyniósłszy włożyli na wrzód, i zgoił się.
Nígbà náà ni Isaiah wí pé, “Mú odidi ọ̀pọ̀tọ́.” Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fi lé oówo náà, ara rẹ̀ sì yá.
8 I rzekł Ezechyjasz do Izajasza: Jaki znak tego, że mię uzdrowi Pan, a iż pójdę dnia trzeciego do domu Pańskiego?
Hesekiah sì béèrè lọ́wọ́ Isaiah pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé Olúwa yóò wò mí sàn àti wí pé èmi yóò lọ sókè sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa láti ọjọ́ kẹta títí di òní?”
9 Odpowiedział Izajasz: Toć będzie znakiem od Pana, iż uczyni Pan tę rzecz, którąć obiecał. Chceszże, żeby cień postąpił na dziesięć stopni, albo żeby się na wstecz nawrócił na dziesięć stopni?
Isaiah dáhùn pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa fún ọ wí pé Olúwa yóò ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí: kí òjìji lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá, tàbí kí ó padà lọ ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá?”
10 I rzekł Ezechyjasz: Snadniej może cień postąpić na dół na dziesięć stopni, tego nie chcę; ale niech się wróci cień na wstecz na dziesięć stopni.
“Ó jẹ́ ohun ìrọ̀rùn fún òjìji láti lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá,” Hesekiah wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí ó lọ padà ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá.”
11 Tedy wołał Izajasz prorok do Pana; i nawrócił cień po onych stponiach, któremi był postąpił na zegarze słonecznym Achazowym, na wstecz na dziesięć stopni.
Nígbà náà wòlíì Isaiah ké pe Olúwa, Olúwa sì ṣe òjìji padà sí ìgbésẹ̀ mẹ́wàá ó ti sọ̀kalẹ̀ ní òpópó ọ̀nà Ahasi.
12 Onegoż czasu posłał Berodach Baladan, syn Baladanowy, król Babiloński, list i dary do Ezechyjasza; bo zasłyszał, że był zaniemógł Ezechyjasz.
Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli ránṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Hesekiah nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Hesekiah.
13 I wysłuchał ich Ezechyjasz i okazał im wszystkie skarbnice klejnotów swoich, srebro, i złoto, i rzeczy wonne, i olejki najwyborniejsze, i dom rynsztunków swoich, i wszystko, co się znajdowało w skarbach jego; nie było nic czego by im nie pokazał Ezechyjasz w domu swym, i we wszystkiem państwie swojem.
Hesekiah gba ìránṣẹ́ náà ó sì fihàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò sì fihàn wọ́n.
14 Przetoż przyszedł prorok Izajasz do króla Ezechyjasza, i rzekł mu: Coć powiedzieli ci mężowie, a skąd przyszli do ciebie? I odpowiedział Ezechyjasz: Z ziemi dalekiej przyszli z Babilonu.
Nígbà náà Isaiah wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?” “Láti ìlú jíjìn réré,” Hesekiah dáhùn. “Wọ́n wá láti Babeli.”
15 I rzekł: Cóż widzieli w domu twoim? Odpowiedział Ezechyjasz: Wszystko, cokolwiek jest w domu moim, widzieli: nie było nic, czegobym im nie pokazał w skarbach moich.
Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?” “Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Hesekiah wí pé. “Kò sí nǹkan kan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fihàn wọ́n.”
16 Ale Izajasz rzekł do Ezechyjasza: Słuchaj słowa Pańskiego.
Nígbà náà Isaiah wí fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
17 Oto przyjdą dni, w które zabiorą wszystko do Babilonu, cokolwiek jest w domu twoim, i cokolwiek schowali ojcowie twoi aż do dnia tego; nie zostanie ci nic, mówi Pan.
àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ òní, wọn yí ó gbe lọ sí Babeli, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.
18 Ale i syny twoje, którzy wynijdą z ciebie, i które spłodzisz, pobiorą, i będą komornikami na dworze króla Babilońskiego.
Àti díẹ̀ nínú àwọn ìran rẹ, ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀, tí wọn yóò bí fún ọ, ni wọn yóò kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà ní ààfin ọba Babeli.”
19 Tedy rzekł Ezechyjasz do Izajasza: Dobre jest słowo Pańskie, któreś mówił. Nadto rzekł: Zaiste dobre, jeźli tylko pokój i prawda będzie za dni moich.
Hesekiah wí fún Isaiah pé. “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò wí pé, “Kò ha dára àlàáfíà àti òtítọ́ ní ọjọ́ ayé mi?”
20 Ale inne sprawy Ezechyjaszowe, i wszystka moc jego, i jako uczynił sadzawkę, i rury, którymi przywiódł wodę do miasta to zapisano w kronikach o królach Judzkich.
Ní ti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tókù nípa ìjọba Hesekiah, gbogbo ohun tí ó ṣe tan àti bí ó ti ṣe adágún omi àti ọ̀nà omi náà nípa èyí tí ó gbé wá omi sínú ìlú ńlá, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìgbésẹ̀ ayé àwọn ọba àwọn Juda?
21 I zasnął Ezechyjasz z ojcami swymi, a królował Manases, syn jego, miasto niego.
Hesekiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀: Manase ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.