< II Królewska 2 >

1 I stało się, gdy miał wziąć Pan Elijasza w wichrze do nieba, że wyszedł Elijasz z Elizeuszem z Galgal.
Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
2 I rzekł Elijasz do Elizeusza: Proszę siedź tu; bo mię Pan posłał aż do Betel. I rzekł Elizeusz: Jako żywy Pan, i jako żywa dusza twoja, że się ciebie nie puszczę. I przyszli do Betel.
Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
3 Tedy wyszli synowie proroccy, którzy byli w Betel, do Elizeusza, i rzekli do niego: Wieszże, iż dziś Pan weźmie od ciebie pana twego? A on rzekł: Wiemci; milczcie tylko.
Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
4 Znowu rzekł mu Elijasz: Elizeuszu, proszę siedź tu; bo mię Pan posłał do Jerycha. A on odpowiedział: Jako żywy Pan, i jako żywa dusza twoja, że się ciebie nie puszczę. A tak przyszli do Jerycha.
Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
5 Tedy przystąpiwszy synowie proroccy, którzy byli w Jerychu, do Elizeusza, rzekli do niego: Wieszże, że dziś Pan weźmie pana twego od ciebie? A on rzekł: Wiemci; milczcie.
Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
6 Jeszcze mu rzekł Elijasz: Proszę siedź tu; bo mię Pan posłał do Jordanu. Który odpowiedział: Jako żywy Pan, jako żywa i dusza twoja, że się ciebie nie puszczę.
Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
7 I szli obadwaj. A pięćdziesiąt mężów synów prorockich szli, i stanęli naprzeciwko z daleko; ale oni obaj stanęli nad Jordanem.
Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
8 A wziąwszy Elijasz płaszcz swój, zwinął go, a uderzył nim wody, i rozdzieliły się tam i sam, tak iż przeszli obaj po suszy.
Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
9 A gdy przeszli, rzekł Elijasz do Elizeusza: Żądaj, czego chcesz, abym ci uczynił pierwej niż będę wzięty od ciebie. Tedy rzekł Elizeusz: Proszę niech będzie dwójnasobny duch twój we mnie;
Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
10 Ale mu on odpowiedział: Trudnejś rzeczy pożądał; wszakże ujrzyszli mię, gdy będę wzięty od ciebie, tak ci się stanie; ale jeźli nie ujrzysz, nie stanieć się.
“Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
11 I stało się, gdy oni przecię szli rozmawiając, oto wóz ognisty, i konie ogniste rozłączyły obydwóch. I wstąpił Elijasz w wichrze do nieba.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
12 Co Elizeusz widząc, wołał: Ojcze mój, ojcze mój! Wozie Izraelski i jazdo jego. I nie widział go więcej. A pochwyciwszy szaty swe rozdarł je na dwie części.
Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
13 I podniósł płaszcz Elijaszowy, który był spadł z niego, a wróciwszy się, stanął nad brzegiem Jordanu. A tak wziąwszy płaszcz Elijaszowy, który był spadł z niego, uderzył nim wody, mówiąc: Gdzież jest Pan, Bóg Elijaszowy?
Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
14 A tak i on uderzył nim wody, a rozdzieliły się tam i sam, i przeszedł Elizeusz.
Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
15 Co widząc synowie proroccy, którzy byli w Jerycho, stojąc na przeciwko, rzekli: Odpoczął duch Elijaszowy nad Elizeuszem; a wyszedłszy przeciwko niemu pokłonili mu się aż do ziemi.
Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
16 I rzekli do niego: Oto teraz jest przy sługach twych pięćdziesiąt mężów mocnych. Proszę niech idą, a niech szukają Pana twego; by go snać nie zaniósł Duch Pański, a nie porzucił go na której górze, albo w której dolinie. Ale im on rzekł: Nie posyłajcie.
“Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
17 A gdy nań nalegali aż do uprzykrzenia, rzekł: Poślijcież. A tak posłali onych pięćdziesiąt mężów, którzy szukając przez trzy dni nie znaleźli go.
Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
18 A gdy się wrócili do niego, (a on mieszkał w Jerycho, ) rzekł do nich: Azażem wam nie mówił: Nie chodźcie?
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
19 Rzekli też mężowie onego miasta do Elizeusza: Wej, oto mieszkanie miasta tego jest dobre, jako panie mój widzisz; ale wody złe i ziemia niepłodna.
Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
20 Tedy rzekł: Przynieście mi bańkę nową, a włóżcie w nię soli. I przynieśli mu.
Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
21 A poszedłszy do źródła wód, wrzucił tam soli, i rzekł: Tak mówi Pan: Uzdrowiłem te wody; nie będzie więcej stamtąd śmierci, ani niepłodności.
Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
22 A tak uzdrowione są one wody aż do dnia tego, według słowa Elizeuszowego, które był powiedział.
Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
23 Potem szedł stamtąd do Betel. A gdy szedł drogą, dzieci małe wyszły z miasta, i naśmiewały się z niego, i mówiły mu: Idźże łysy, idźże łysy!
Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
24 Który obejrzawszy się, ujrzał je, i złorzeczył im w imieniu Pańskiem. Przetoż wyszedłszy dwie niedźwiedzice z lasu, rozdrapały z nich czterdzieści i dwoje dzieci.
Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
25 I szedł stamtąd na górę Karmel, a z onąd zasię wrócił się do Samaryi.
Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.

< II Królewska 2 >