< II Królewska 19 >

1 A gdy to usłyszał król Ezechyjasz, rozdarł szaty swoje, a oblekł się w wór, i wszedł do domu Pańskiego;
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
2 I posłał Elijakima, sprawcę domu swego, i Sobnę pisarza, i starsze z kapłanów, obleczone w wory, do Izajasza proroka, syna Amosowego.
Ó sì rán Eliakimu olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Którzy rzekli do niego: Tak mówi Ezechyjasz: Dzień utrapienia i łajania, i bluźnierstwa jest ten dzień; albowiem synowie przyszli aż do porodzenia, a siły niemasz ku rodzeniu.
Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Hesekiah sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.
4 Oby usłyszał Pan, Bóg twój, wszystkie słowa Rabsacesowe, którego przysłał król Assyryjski, pan jego, urągać Bogu żywemu! aby się pomścił onych słów, które słyszał Pan, Bóg twój. Przetoż uczyń modlitwę za te ostatki, które się znajdują.
Ó lè jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yóò gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ olùdarí pápá, ẹni tí ọ̀gá rẹ̀, ọba Asiria, ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣẹ̀sín, yóò sì bá a wí fún ọ̀rọ̀ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún ìyókù àwọn tí ó wà láààyè.”
5 Przyszli tedy słudzy króla Ezechyjasza do Izajasza.
Nígbà tí ìránṣẹ́ ọba Hesekiah lọ sí ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 Którym odpowiedział Izajasz: Tak powiedzcie panu waszemu: To mówi Pan: Nie bój się tych słów, któreś słyszał, któremi mię lżyli słudzy króla Assyryjskiego.
Isaiah wí fún wọn pé, “Sọ fún ọ̀gá rẹ, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa sọ pé: Ẹ má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ̀yin ti gbọ́—àwọn ọ̀rọ̀ ìhàlẹ̀ pẹ̀lú èyí ti ọba Asiria ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Oto Ja puszczę nań ducha, i usłyszy wieść, a wróci się do ziemi swojej, i położę go mieczem w ziemi jego.
Gbọ́! Èmi yóò rán ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ nígbà tí ó bá sì gbọ́ ariwo, yóò sì padà sí ìlú rẹ̀, níbẹ̀ ni èmi yóò sì gbé gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Ale wróciwszy się Rabsaces znalazł króla Assyryjskiego dobywającego Lebny; albowiem usłyszał, iż odciągnął był od Lachys.
Nígbà tí olùdarí pápá gbọ́ wí pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi ó sì padà ó sì rí ọba níbi ti ó gbé ń bá Libina jà.
9 A usłyszawszy o Tyraku, królu Etyjopskim, że mówino: Oto wyciągnął na wojnę przeciwko tobie, znowu psłał posły do Ezechyjasza, mówiąc:
Nísinsin yìí, Sennakeribu sì gbọ́ ìròyìn wí pé Tirakah, ọba Etiopia ti Ejibiti wá ó sì ń yan jáde lọ láti lọ bá a jagun. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tún rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ yìí pé,
10 To powiedzcie królowi Ezechyjaszowi, królowi Judzkiemu, mówiąc: Niech cię nie zwodzi Bóg twój, któremu ty ufasz, a mówisz: Nie będzie podane Jeruzalem w ręce króla Assyryjskiego.
“Sọ fún Hesekiah ọba Juda pé, má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé kí ó tàn ó jẹ nígbà tí ó wí pé, ‘Jerusalẹmu a kò ní fi lé ọwọ́ ọba Asiria.’
11 Otoś słyszał, co poczynili królowie Assyryjscy wszystkim ziemiom, burząc je; a tybyś miał być wybawiony?
Lóòótọ́ ìwọ ti gbọ́ gbogbo ohun tí ọba Asiria tí ó ṣe sí gbogbo àwọn ìlú, ó pa wọ́n run pátápátá. Ìwọ yóò sì gbàlà?
12 Izali wybawili bogowie narodów te, które wygubili ojcowie moi, Gozan, i Haran, i Resef, i syny Eden, którzy byli w Telassar?
Ṣé àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè tí a ti parun láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá mi gbà wọ́n là: òrìṣà Gosani, Harani Reṣefu àti gbogbo ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Gdzież jest król Emat, i król Arfad, i król miasta Sefarwaim, Ana i Awa?
Níbo ni ọba Hamati wa, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi, ti Hena, tàbí ti Iffa gbé wà?”
14 Przetoż wziąwszy Ezechyjasz list z ręki posłów, przeczytał go, i wszedłszy do domu Pańskiego rozciągnął go Ezechyjasz przed Panem.
Hesekiah gba lẹ́tà láti ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ ó sì kà á. Nígbà náà ó sì lọ sí òkè ilé tí a kọ́ fún Olúwa ó sì tẹ́ ẹ síwájú Olúwa.
15 I modlił się Ezechyjasz przed Panem, mówiąc: Panie, Boże Izraelski, siedzący na Cherubinach! ty, tyś sam jest Bóg wszystkich królestw ziemi, tyś stworzył niebo i ziemię.
Hesekiah gbàdúrà sí Olúwa: “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ń gbé ní àárín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí gbogbo ìjọba tí ó wà láyé, ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
16 Nakłońże, Panie! ucha twojego, a usłysz; otwórz, Panie! oczy twoje, a obacz; usłysz słowa Sennacheryba, który przysłał hańbić ciebie, Boga żywego.
Dẹtí sílẹ̀, Olúwa kí o sì gbọ́; la ojú rẹ, Olúwa, kí o sì rí i, gbọ́ ọ̀rọ̀ Sennakeribu tí ó rán láti fi bú Ọlọ́run alààyè.
17 Prawdać jest, Panie! że spustoszyli królowie Assyryjscy narody one, i ziemię ich.
“Òtítọ́ ni, Olúwa, wí pé ọba Asiria ti pa orílẹ̀-èdè wọ̀nyí run àti ilẹ̀ wọn.
18 I powrzucali bogi ich w ogień; albowiem nie byli bogowie, ale robota rąk ludzkich, drewno, i kamień; przetoż je wygubili.
Wọ́n ti ju òrìṣà wọn sínú iná wọn sì ti bà wọ́n jẹ́, nítorí pé wọn kì í ṣe ọlọ́run. Ṣùgbọ́n, wọ́n jẹ́ igi àti òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ ènìyàn.
19 A teraz, Panie Boże nasz! wybaw nas proszę z ręki jego, aby poznały wszystkie królestwa ziemi, żeś ty, Panie! sam Bogiem.
Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run wa, gbà wá kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ìjọba lórí ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé ìwọ nìkan ṣoṣo ni, Olúwa Ọlọ́run wa.”
20 Tedy posłał Izajasz, syn Amosowy, do Ezechyjasza, mówiąc: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: O coś mię prosił z strony Sennacheryba, króla Assyryjskiego, wysłuchałem cię.
Nígbà náà Isaiah ọmọ Amosi rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Sennakeribu ọba Asiria.
21 A teć są słowa, które mówił Pan o nim: Panna, córka Syońska, wzgardziła cię, śmiała się z ciebie, kiwała głową za tobą córka Jeruzalemska.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, “‘Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni kẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu mi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.
22 Kogożeś hańbił, i kogo bluźnił? przeciwko komużeś podniósł głos, a wyniosłeś ku górze oczy swoje? przeciw Świętemu Izraelskiemu.
Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀? Lórí ta ni ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga? Lórí ẹni mímọ́ ti Israẹli!
23 Przez posły twoje hańbiłeś Pana mego, i rzekłeś: W mnóstwie wozów moich wstąpiłem na wysokie góry, i na strony Libańskie, i podrąbię wysokie cedry jego, i wyborne jodły jego, i przyjdę aż do ostatnich przybytków jego, do lasów, i wybornych ról jego.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, “Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi a sì lọ sí orí òkè ìbùwọ̀ rẹ̀ sínú ibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ̀.
24 Jam wykopał źródła, i piłem wody cudze, a wysuszyłem stopami nóg moich wszystkie potoki oblężonych.
Mo ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì, mo sì mu omi níbẹ̀. Pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi, èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Ejibiti.”
25 Izażeś nie słyszał, żem ja zdawna uczynił a od dni starodawnych stworzyłem je? a teraz miałżebym na nie przywieść spustoszenie, i obrócić w gromady gruzu; jako insze miasta obronne?
“‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́? Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án. Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀; nísinsin yìí mo ti mú wá sí ìkọjá pé ìwọ ti yí ìlú olódi padà dí òkìtì àlàpà òkúta.
26 Których obywatele stali się jako bez rąk, przestraszeni są i zawstydzeni, bywszy jako trawa polna, i jako zioła zielone, i trawy po dachach, które pierwej schną, niż się dostają,
Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa, wọ́n ti dà á láàmú wọ́n sì ti ṣọ́ di ìtìjú. Wọ́n dàbí koríko igbó lórí pápá, gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbàsókè, gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.
27 Mieszkanie twoje i wyjście twoje, i wejście twoje znam, także popędliwość twoję przeciwko mnie.
“‘Ṣùgbọ́n èmi mọ ibi tí ìwọ dúró àti ìgbà tí ìwọ bá dé tàbí lọ àti bí ìwọ ṣe ìkáàánú rẹ: sí mi.
28 Ponieważeś się przeciwko mnie zajuszył, a zapędy twoje przyszły do uszów moich, przetoż założę kolce moje za nozdrza twoje, a wędzidło moje wprawię w gębę twoję, i wrócę cię tą drogą, którąś przyszedł,
Ṣùgbọ́n ìkáàánú rẹ sí mi àti ìrora rẹ dé etí mi, Èmi yóò gbé ìwọ̀ mi sí imú rẹ àti ìjánu mi sí ẹnu rẹ, èmi yóò mú ọ padà nípa wíwá rẹ.’
29 A to będziesz miał, Ezechyjaszu! za znak: Tego roku będziesz jadł samorodne zboże, i roku także drugiego samorodne zboże; ale roku trzeciego będziecie siać i żąć, i sadzić winnice i jeść owoc ich.
“Èyí yóò jẹ́ àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ọdún yìí ìwọ yóò jẹ ohun tí ó bá hù fún rara rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó bá hù jáde láti inú ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, gbìn kí o sì kórè, gbin ọgbà àjàrà kí o sì jẹ èso rẹ̀.
30 Ostatek bowiem domu Judy, który pozostał, wkorzeni się głęboko, i wyda owoc ku górze.
Lẹ́ẹ̀kan sí i ìyókù ti ilé Juda yóò sì tún hu gbòǹgbò lábẹ́, yóò sì so èso lókè.
31 Albowiem z Jeruzalemu wynijdą ostatki, i ci, którzy są zachowani z góry Syońskiej. Gorliwość Pana zastępów to uczyni.
Láti inú Jerusalẹmu ní àwọn ìyókù yóò ti wá àti láti orí òkè Sioni ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó sá àsálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ṣe èyí.
32 A przetoż tak mówi Pan o królu Assyryjskim: Nie wnijdzie do miasta tego, ani tam dojdzie strzała jego, ani go ubieży tarcza, ani usypie szańców około niego;
“Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa ti ọba Asiria: “Kò ní wọ ìlú yìí tàbí ta ọfà síbí. Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lú àpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
33 Drogą, którą przyszedł, wróci się, a do miasta tego nie wnijdzie, mówi Pan.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá ni yóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí, ni Olúwa wí.
34 Bo będę bronił miasta tego, i zachowam je sam dla siebie, i dla Dawida, sługi mego.
Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí, èmi yóò sì pa á mọ́ fún èmi tìkára mi àti fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.”
35 I stało się onej nocy, że wyszedł Anioł Pański, a pobił w obozie Assyryjskim sto ośmdziesiąt i pięć tysięcy. A gdy wstali rano, oto wszędy pełno trupów.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà, angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Asiria. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
36 Przetoż ruszywszy się odjechał i wrócił się Seneacheryb, król Assyryjski, a mieszkał w Niniwe.
Bẹ́ẹ̀ ni Sennakeribu ọba Asiria wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Ninefe ó sì dúró níbẹ̀.
37 A gdy chwalił boga swego Nesrocha w domu, tedy Adramelech i Sarassar, synowie jego, zabili go mieczem, a sami uciekli do ziemi Ararat. I królował Assarhaddon, syn jego, miasto niego.
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nisroki, ọmọkùnrin rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati Esarhadoni ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< II Królewska 19 >