< II Królewska 15 >

1 Roku dwudziestego i siódmego Jeroboama, króla Izraelskiego, królował Azaryjasz, syn Amazyjasza, króla Judzkiego.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n tí Jeroboamu ọba Israẹli, Asariah ọmọ Amasiah ọba Juda sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
2 Szesnaście mu lat było, gdy począł królować, a pięćdziesiąt i dwa lata królował w Jeruzalemie. Imię matki jego było Jechelija z Jeruzalemu.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jekoliah; ó wá láti Jerusalẹmu.
3 Ten czynił, co dobrego jest w oczach Pańskich, według wszystkiego, jako czynił Amazyjasz, ojciec jego.
Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
4 Wszakże wyżyny nie były zniesione: jeszcze lud ofiarował i kadził po wyżynach.
Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò, àwọn ènìyàn náà tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sun tùràrí níbẹ̀.
5 I zaraził Pan króla, a był trędowaty aż do śmierci swej, i mieszkał w domu osobnym; przetoż Joatam, syn królewski, rządził domem, sądząc lud ziemi.
Olúwa sì kọlu ọba náà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀, títí di ọjọ́ tí ó kú, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀tọ̀. Jotamu, ọmọ ọba sì tọ́jú ààfin, ó sì ń darí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
6 A inne sprawy Azaryjaszowe, i wszystko co czynił, azaż tego nie zapisano w kronikach o królach Judzkich?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Asariah, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda.
7 I zasnął Azaryjasz z ojcami swymi, a pochowano go z ojcami jego w mieście Dawidowem; a królował Joatam, syn jego, miasto niego.
Asariah sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. A sì sin ín sí ẹ̀bá wọn ní ìlú ńlá ti Dafidi. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
8 Roku trzydziestego i ósmego Azaryjasza, króla Judzkiego, królował Zacharyjasz, syn Jeroboamowy, nad Izraelem w Samaryi sześć miesięcy.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asariah ọba Juda. Sekariah ọmọ Jeroboamu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún oṣù mẹ́fà.
9 I czynił złe przed oczyma Pańskimi, jako czynili ojcowie jego, nie odstępując od grzechów Jeroboama, syna Nabatowego, który przywiódł do grzechu Izraela.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba rẹ̀ tí ṣe. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
10 I sprzysiągł się przeciw niemu Sellum, syn Jabesowy, i ranił go przed ludem, i zabił go, a królował miasto niego.
Ṣallumu ọmọ Jabesi dìtẹ̀ sí Sekariah. Ó dojúkọ ọ́ níwájú àwọn ènìyàn, ó sì pa á, ó sì jẹ ọba dípò rẹ̀.
11 A inne sprawy Zacharyjaszowe, oto są napisane w kronikach o królach Izraelskich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Sekariah. Wọ́n kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
12 Toć jest ono słowo Pańskie, które powiedział do Jehu, mówiąc: Synowie twoi do czwartego pokolenia będą siedzieli na stolicy Izraelskiej. I tak się stało.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ fún Jehu jẹ́ ìmúṣẹ: “Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
13 Tedy Sellum, syn Jabesowy, królował roku trzydziestego i dziewiątego roku Uzyjasza, króla Judzkiego, a królował przez jeden miesiąc w Samaryi.
Ṣallumu ọmọ Jabesi di ọba ní ọdún kọkàndínlógójì Ussiah ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún oṣù kan.
14 Bo przyciągnąwszy Manachem, syn Gady, z Tersy, a przyszedłszy do Samaryi, poraził Selluma, syna Jabesowego w Samaryi, a zabiwszy go, królował miasto niego.
Nígbà náà Menahemu ọmọ Gadi lọ láti Tirsa sí Samaria. Ó dojúkọ Ṣallumu ọmọ Jabesi ní Samaria, ó pa á ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
15 A inne sprawy Sellumowe, i sprzysiężenie jego, którem się był sprzysiągł, oto zapisane w kronikach o królach Izraelskich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ṣallumu, àti ìdìtẹ̀ tí ó dì, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
16 Tedy dobył Manachem miasta Tafsy, i pobił wszystkie, którzy w niem byli, i wszystki granice jego od Tersy; przeto, że mu nie otworzyli, pomordował je, i wszystkie brzemienne w niem porozcinał.
Ní ìgbà tí Menahemu ń jáde bọ̀ láti Tirsa, ó dojúkọ Tifisa àti gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ìlú ńlá àti agbègbè rẹ̀, nítorí wọn kọ̀ láti sí ẹnu ibodè. Ó yọ Tifisa kúrò lẹ́nu iṣẹ́, ó sì la inú gbogbo àwọn obìnrin aboyún.
17 Roku trzydziestego i dziewiątego Azaryjasza, króla Judzkiego, królował Manachem, syn Gady, nad Izraelem dziesięć lat w Samaryi.
Ní ọdún kọkàndínlógójì ti Asariah ọba Juda, Menahemu ọmọ Gadi di ọba Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún ọdún mẹ́wàá.
18 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, nie odstępując od grzechów Jeroboama, syna Nabatowego, który do grzechu przywodził Izraela po wszystkie dni swoje.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa, ní gbogbo ìjọba rẹ̀. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
19 A gdy wyciągnął Ful, król Assyryjski, przeciw ziemi Izraelskiej, dał Manachem Fulowi tysiąc talentów srebra, aby mu był na pomocy ku umocnieniu królestwa w rękach jego.
Nígbà náà, Pulu ọba Asiria, gbógun ti ilẹ̀ náà, Menahemu sì fún un ní ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì fàdákà láti fi gba àtìlẹ́yìn rẹ̀ àti láti fún ìdúró tirẹ̀ lágbára lórí ìjọba.
20 I ułożył Manachem podatek na Izraela, na wszystkie najbogatsze, aby dawali królowi Asyryjskiemu, po pięćdziesiąt syklów srebra, każdy z osobna; i wrócił się król Assyryjski, a nie bawił się tam w onej ziemi.
Menahemu fi agbára gba owó náà lọ́wọ́ Israẹli. Gbogbo ọkùnrin ọlọ́lá ní láti dá àádọ́ta ṣékélì fàdákà láti fún ọba Asiria. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Asiria padà sẹ́yìn, kò sì dúró ní ilẹ̀ náà mọ́.
21 A inne sprawy Manachemowe, i cokolwiek czynił, napisane są w kronikach o królach Izraelskich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Menahemu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé ọba Israẹli?
22 I zasnął Manachem z ojcami swymi, a królował Facejasz, syn jego, miasto niego.
Menahemu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Pekahiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
23 Roku pięćdziesiątego Azaryjasza, króla Judzkiego, królował Facejasz, syn Manachemowy, nad Izraelem w Samaryi dwa lata.
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún Asariah ọba Juda, Pekahiah ọmọ Menahemu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì.
24 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, nie odstępując od grzechu Jeroboama, syna Nabatowego, który przywiódł do grzechu Izraela.
Pekahiah ṣe búburú lójú Olúwa. Kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
25 Tedy się zbuntował przeciwko niemu Facejasz, syn Romelijasza, hetman jego, i zabił go w Samaryi w pałacu domu królewskiego, z Argobem i z Aryjaszem, mając z sobą pięćdziesiąt mężów Galaadczyków, a zabiwszy go królował miasto niego.
Ọ̀kan lára àwọn olórí ìjòyè rẹ̀ Peka ọmọ Remaliah, dìtẹ̀ sí i. Ó mú àádọ́ta àwọn ọkùnrin ti àwọn ará Gileadi pẹ̀lú u rẹ̀. Ó pa Pekahiah pẹ̀lú Argobu àti Arie ní odi ààfin ọba ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni Peka pa Pekahiah, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
26 A inne sprawy Facejaszowe i wszystko co czynił, oto napisano w kronikach o królach Izeraelskich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Pekahiah, gbogbo ohun tí ó ṣe, ni a kọ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
27 Roku pięćdziesiątego i wtórego Azaryjasza, króla Judzkiego, królował Facejasz syn Romelijasza, nad Izraelem w Samaryi dwadzieścia lat.
Ní ọdún kejìléláàádọ́ta Asariah ọba Juda, Peka ọmọ Remaliah di ọba Israẹli ní Samaria. Ó sì jẹ ọba fún ogún ọdún.
28 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, nie odstępując od grzechu Jeroboama, syna Nabatowego, który przywiódł do grzechu Izraela.
Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
29 Za dni Facejasza, króla Izraelskiego, przyciągnął Teglet Falaser, król Assyryjski, i wziął Ajon i Abelbetmaacha, i Jonoe, i Kiedes, i Azor, i Galaad, i Galileę, wszystkę ziemię Neftali, a przeniósł obywatele jej do Assyryi.
Ní ìgbà Peka ọba Israẹli, Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá, ó sì mú Ijoni, Abeli-Beti-Maaka, Janoa, Kedeṣi àti Hasori. Ó gba Gileadi àti Galili pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali. Ó sì kó àwọn ènìyàn ní ìgbèkùn lọ sí Asiria.
30 Tedy się zbuntował Ozeasz, syn Eli, przeciw Facejaszowi, synowi Romelijaszowemu, a raniwszy go, zabił go, i królował miasto niego roku dwudziestego Joatama, syna Uzyjaszowego.
Nígbà náà, Hosea ọmọ Ela, dìtẹ̀ sí Peka ọmọ Remaliah. Ó dojúkọ ọ́, ó sì pa á, ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba ní ogún ọdún Jotamu ọmọ Ussiah.
31 A inne sprawy Facejaszowe, i wszystko co czynił, oto zapisano w kronikach o królach Izraelskich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Peka, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
32 Roku wtórego Facejasza, syna Romelijaszowego, króla Izraelskiego królował Joatam, syn Uzyjasza, króla Judzkiego.
Ní ọdún keje Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli, Jotamu ọmọ Ussiah ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
33 Dwadzieścia i pięć lat miał, gdy królować począł, i szesnaście lat królował w Jeruzalemie. Imię matki jego Jerusa, córka Sadokowa.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jeruṣa ọmọbìnrin Sadoku.
34 I czynił, co dobrego jest przed oczyma Pańskiemi; według wszystkiego, co czynił Uzyjasz, ojciec jego, postępował.
Ó ṣe ohun tí ó tọ́ lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ Ussiah ti ṣe.
35 Wszakże wyżyny nie były zniesione; jeszcze lud ofiarował i kadził na wyżynach. Tenże zbudował bramę najwyższą domu Pańskiego.
Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò àwọn ènìyàn tẹ̀síwájú láti rú ẹbọ àti láti sun tùràrí níbẹ̀: Jotamu tún ìlẹ̀kùn gíga tó ń kọ́ ní ti ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
36 A inne sprawy Joatamowe, i wszystko co czynił, zapisane w kronikach o królach Judzkich.
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jotamu, àti ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
37 Za onych dni począł Pan posyłać na Judę Rasyna, króla Syryjskiego, i Facejasza, syna Romelijaszowego.
(Ní ayé ìgbàanì, Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní rán Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah láti dojúkọ Juda).
38 I zasnął Joatam z ojcami swymi, i pogrzebiony jest z ojcami swymi w mieście Dawida, ojca swego. A królował Achaz, syn jego, miasto niego.
Jotamu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi, ìlú ńlá ti baba rẹ̀. Ahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< II Królewska 15 >