< II Królewska 14 >

1 Roku wtórego Joaza, syna Joachaza, króla Izraelskiego, począł królować Amazyjasz, syn Joaza, króla Judzkiego.
Ní ọdún kejì tí Jehoaṣi ọmọ Joahasi ọba Israẹli, Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
2 Dwadzieścia i pięć lat miał, gdy królować począł, a dwadzieścia i dziewięć lat królował w Jeruzalemie. Imię matki jego było Joadana z Jeruzalemu.
Ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani; ó wá láti Jerusalẹmu.
3 Ten czynił, co dobrego jest przed oczyma Pańskiemi, aczkolwiek nie tak jako Dawid, ojciec jego; według wszystkiego, co czynił Joaz, ojciec jego, postępował.
Ó ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i Dafidi baba a rẹ̀ tí ṣe. Nínú ohun gbogbo, ó tẹ̀lé àpẹẹrẹ baba a rẹ̀ Joaṣi.
4 Wszakże wyżyny nie były zniesione; jeszcze lud ofiarował i kadził po wyżynach.
Àwọn ibi gíga bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí i kúrò, àwọn ènìyàn sì tẹ̀síwájú láti rú ẹbọ àti sun tùràrí níbẹ̀.
5 A gdy zmocnione było królestwo w ręku jego, pobił sługi swe, którzy byli zabili króla, ojca jego.
Lẹ́yìn tí ó ti fi ọwọ́ gbá ìjọba rẹ̀ mú gbọingbọin, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n ti pa baba a rẹ̀ ọba.
6 Lecz synów onych morderców nie pobił, jako napisano w księgach zakonu Mojżeszowego, gdzie rozkazał Pan, mówiąc: Nie pomrą ojcowie za synów, ani synowie pomrą za ojców, ale każdy za grzech swój umrze.
Síbẹ̀ kò pa ọmọ àwọn apànìyàn náà. Ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ sínú ìwé òfin Mose níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kì yóò pa baba nítorí àwọn ọmọ, tàbí àwọn ọmọ nítorí àwọn baba; olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
7 Ten też poraził Edomczyków dziesięć tysięcy w dolinie solnej, i wziął mocą Selę, a nazwał imię jej Jokteel, aż do tego czasu.
Òun ni ẹni tí ó ṣẹ́gun ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ará Edomu ní àfonífojì iyọ̀, ó sì fi agbára mú Sela nínú ogun, tí ó ń pè é ní Jokteeli, orúkọ tí ó ní títí di òní.
8 Tedy posłał Amazyjasz posły do Joaza, syna Joachaza, syna Jehu, króla Izraelskiego, mówiąc: Pójdź, wejrzymy sobie w oczy.
Nígbà náà, Amasiah rán àwọn ìránṣẹ́ sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu ọba Israẹli pẹ̀lú ìpèníjà: “Wá, jẹ́ kí á wo ara wa ní ojú.”
9 Posłał zasię Joaz, król Izraelski, do Amazyjasza, króla Judzkiego, mówiąc: Oset, który jest na Libanie, posłał do cedru Libańskiego, mówiąc: Daj córkę twoję synowi memu za żonę. Wtem przyszedł zwierz polny, który jest na Libanie, i podeptał on oset.
Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì sí Amasiah ọba Juda: “Òṣùṣú kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí kedari ní Lebanoni, ‘Fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó.’ Nígbà náà ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin tinú igbó ní Lebanoni wá pẹ̀lú ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ òṣùṣú náà mọ́lẹ̀.
10 Żeś ty bardzo poraził Edomczyki, dlatego się podniosło serce twoje. Chlubże się, a siedź w domu twoim; i przeczże się masz wdawać w to złe, abyś upadł ty, i Juda z tobą?
Ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu pẹ̀lú, ṣùgbọ́n, nísinsin yìí ìwọ ṣe ìgbéraga. Ògo nínú ìṣẹ́gun rẹ, ṣùgbọ́n dúró nílé! Kí ni ó dé tí o fi ń wá wàhálà tí o sì fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
11 Ale nie usłuchał Amazyjasz. Przetoż wyciągnął Joaz, król Izraelski, a wejrzeli sobie w oczy, on i Amazyjasz, król Judzki, w Betsemes, które jest w Judztwie.
Bí ó ti wù kí ó rí Amasiah kò ní tẹ́tí, bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi ọba Israẹli sì dojúkọ ọ́. Òun àti Amasiah ọba Juda kọjú sí ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
12 I porażony jest Juda od ludu Izraelskiego, a uciekł każdy do przybytku swego.
A kó ipa ọ̀nà Juda nípasẹ̀ Israẹli, gbogbo àwọn ọkùnrin sì sálọ sí ilé e rẹ̀.
13 Lecz Amazyjasza, króla Judzkiego, syna Joaza, syna Ochozyjaszowego, pojmał Joaz, król Izraelski, w Betsemes, a przyciągnąwszy do Jeruzalemu, zburzył mur Jeruzalemski od bramy Efraim aż do bramy narożnej, na cztery sta łokci.
Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Jehoaṣi, ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà, Jehoaṣi lọ sí Jerusalẹmu, ó sì lọ wó odi Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ìlẹ̀kùn Efraimu sí ibi igun ìlẹ̀kùn. Ìpín kan tí ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ irinwó ìgbọ̀nwọ́.
14 I zabrał wszystko złoto i srebro i wszystkie naczynia, które się znalazły w domu Pańskim, i w skarbach domu królewskiego, i ludzie zastawne, i wrócił się do Samaryi.
Ó mú gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun tí ó rí nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa àti níbi ìfowópamọ́ sí nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn ògo, ó sì dá wọn padà sí Samaria.
15 A inne sprawy Joazowe, które czynił, i moc jego, i jako walczył z Amazyjaszem, królem Judzkim, azaż tego nie zapisano w kronikach o królach Izraelskich?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jehoaṣi, gbogbo ohun tí ó ṣe pẹ̀lú àṣeyọrí rẹ̀, pẹ̀lú ogun rẹ̀ sí Amasiah ọba Juda, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
16 I zasnął Joaz z ojcami swymi, a pogrzebiony jest w Samaryi z królmi Izraelskimi, a królował Jeroboam, syn jego, miasto niego.
Jehoaṣi sì sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria pẹ̀lú àwọn ọba Israẹli. Jeroboamu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
17 I żył Amazyjasz, syn Joazowy, król Judzki, po śmierci Joaza, syn Joachaza, króla Izraelskiego, piętnaście lat.
Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
18 A inne sprawy Amazyjaszowe, azaż nie są opisane w kronikach o królach Judzkich?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ rẹ̀ nígbà ìjọba Amasiah, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
19 Potem sprzysięgli się przeciwko niemu niektórzy w Jeruzalemie; ale uciekł do Lachys. Przetoż posławszy za nim do Lachys, zabili go tam.
Wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi, ṣùgbọ́n wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
20 Skąd przynieśli go na koniach, i pogrzebiony jest w Jeruzalemie z ojcami swymi, w mieście Dawidowem.
Wọ́n gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin, a sì sin ín sí Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, ní ìlú ńlá ti Dafidi.
21 A tak wziąwszy wszystek lud Judzki Azaryjasza, któremu było szesnaście lat, postanowili go królem na miejscu ojca jego Amazyjasza.
Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn Juda mú Asariah tí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìndínlógún. Wọ́n sì ṣe é ní ọba ní ìrọ́pò baba rẹ̀ Amasiah.
22 Ten pobudował Elat, i przywrócił je do Judy, gdy zasnął król z ojcami swymi.
Òun ni ẹni tí ó tún Elati kọ́, ó sì dá a padà sí Juda lẹ́yìn tí Amasiah ti sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
23 Roku piętnastego Amazyjasza, syna Joaza, króla Judzkiego, królował Jeroboam, syn Joaza, króla Izraelskiego, w Samaryi czterdzieści lat i rok.
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún tí Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda, Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ọba Israẹli di ọba ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún ọ̀kànlélógójì ọdún.
24 A czynił złe przed oczyma Pańskiemi, nie uchylając się od wszystkich grzechów Jeroboama, syn Nabatowego, który przywiódł do grzechu Izraela.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati. Èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
25 Ten zasię przywrócił granice Izraelskie od wejścia do Emat aż do morza pustego, według słowa Pana, Boga Izraelskiego, które był wyrzekł przez sługę swego Jonasza, syna Amaty, proroka; który był z Gatefer.
Òun ni ẹni tí ó ti dá àwọn ààlà Israẹli padà láti Lebo-Hamati sí òkú aginjù. Ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ Jona ọmọ Amittai, wòlíì láti Gati-Heferi.
26 Albowiem widział Pan utrapienie Izraelskie, im dalej tem większe, tak, że i więzień, i opuszczony zniszczeni byli, a nie był, ktoby ratował Izraela.
Olúwa ti rí ìpọ́njú Israẹli pé, ó korò gidigidi, nítorí kò sí ẹrú tàbí òmìnira tàbí olùrànlọ́wọ́ kan fún Israẹli.
27 A nie rzekł był Pan, aby miał wygładzić imię Izraela, żeby nie zostało pod niebem: przetoż je wybawił przez rękę Jeroboama, syna Joazaowego.
Láti ìgbà tí Olúwa kò ti wí pé òhun yóò bu àbùkù lu orúkọ Israẹli láti abẹ́ ọ̀run. Ó gbà wọ́n là, lọ́wọ́ Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi.
28 A inne sprawy Jeroboamowe, i wszystko co czynił, i moc jego, którą walczył, i którą przywrócił Damaszek i Emat Judzkie Izraelowi, azaż tego nie zapisano w kronikach o królach Izraelskich?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jeroboamu, gbogbo ohun tí ó ṣe àti gbogbo àwọn agbára rẹ, bí ó ti jagun sí, àti bí ó ti gba Damasku àti Hamati, tí í ṣe ti Juda, padà fún Israẹli, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
29 I zasnął Jeroboam z ojcami swymi, z królmi Izraelskimi, a królował Zacharyjasz, syn jego, miasto niego.
Jeroboamu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àwọn ọba Israẹli Sekariah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< II Królewska 14 >