< II Kronik 9 >

1 Tedy królowa z Saby słysząc sławę Salomonową, przyjechała do Jeruzalemu, aby doświadczała Salomona w zagadkach, z wielkim bardzo pocztem, i z wielbłądami niosącemi rzeczy wonne, i złota bardzo wiele, i kamienia drogiego, a przyszedłszy do Salomo na, mówiła z nim o wszystkiem, co miała w sercu swojem.
Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ nípa òkìkí Solomoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè tí ó le. Ó dé pẹ̀lú ẹgbẹ́ ńlá kan pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye wúrà, àti òkúta iyebíye, ó wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni ó sì sọ̀rọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ nípa gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn rẹ̀.
2 Ale jej odpowiedział Salomon na wszystkie jej słowa, a nie było nic skrytego przed Salomonem, na coby jej nie odpowiedział.
Solomoni sì dá a lóhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyíkéyìí tí kò lè ṣe àlàyé fún.
3 Przetoż widząc królowa z Saby mądrość Salomonową, i dom, który zbudował;
Nígbà tí ayaba Ṣeba rí ọgbọ́n Solomoni àti pẹ̀lú ilé tí ó ti kọ́,
4 Także potrawy stołu jego, i siadania sług jego, i stawania służących mu, i szaty ich, i podczaszy jego, i szaty ich, i schody, po których wstępował do domu Pańskiego, zdumiewała się bardzo.
oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì rẹ̀, àti ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti dídúró àwọn ìránṣẹ́ nínú aṣọ wọn, àti àwọn agbọ́tí nínú aṣọ wọn àti ẹbọ sísun tí ó ṣe ní ilé Olúwa, ó sì dá a lágara fún ìyàlẹ́nu.
5 I rzekła do króla: Prawdziwać to mowa, którąm słyszała w ziemi mojej o sprawach twoich, i o mądrości twojej.
Ó sì wí fún ọba pé, “Ìròyìn tí mo gbọ́ ní ìlú mi nípa iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ, òtítọ́ ni.
6 Alem nie wierzyła słowom ich, ażem przyjechawszy oglądała oczyma swemi; ale oto nie powiedziano mi i połowy o wielkiej mądrości twojej; przeszedłeś sławę, o którejm słyszała.
Ṣùgbọ́n èmi kò gba ohun tí wọ́n sọ gbọ́ àyàfi ìgbà tí mó dé ibí tí mo sì ri pẹ̀lú ojú mi. Nítòótọ́, kì í tilẹ̀ ṣe ìdájọ́ ìdajì títóbi ọgbọ́n rẹ ní a sọ fún mi: ìwọ ti tàn kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
7 Błogosławieni mężowie twoi i błogosławieni ci słudzy twoi, którzy stoją przed tobą zawsze, a słuchają mądrości twojej.
Báwo ni inú àwọn ọkùnrin rẹ ìbá ṣe dùn tó! Báwo ní dídùn inú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn tí n dúró nígbà gbogbo níwájú rẹ láti gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
8 Niechże będzie Pan, Bóg twój, błogosławiony, który cię sobie upodobał, aby cię posadził na stolicy swojej za króla przed Panem, Bogiem twoim. Dla tego, iż umiłował Bóg twój Izraela, aby go umocnił na wieki, przetoż postanowił cię nad nimi za króla, abyś czynił sąd i sprawiedliwość.
Ìyìn ló yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ní inú dídùn nínú rẹ tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀ láti jẹ ọba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run rẹ fún Israẹli láti fi ìdí wọn kalẹ̀ láéláé, ó sì ti fi ọ́ ṣe ọba lórí wọn, láti ṣe ìdájọ́ àti òtítọ́.”
9 I dała królowi sto i dwadzieścia talentów złota, i rzeczy wonnych bardzo wiele, i kamienia drogiego; a nieprzyszło nigdy więcej takich rzeczy wonnych, jakie dała królowa z Saby królowi Salomonowi.
Nígbà náà ni ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iye tùràrí, àti òkúta iyebíye. Kò sì tí ì sí irú tùràrí yí gẹ́gẹ́ bí èyí tí ayaba Ṣeba fi fún ọba Solomoni.
10 Nadto i słudzy Hiramowi, i słudzy Salomonowi, którzy byli przywieźli złota z Ofir, przywieźli i drzewa almugimowego, i kamienia drogiego.
Àwọn ènìyàn Hiramu àti àwọn ọkùnrin Solomoni gbé wúrà wá láti Ofiri, wọ́n sì tún gbé igi algumu pẹ̀lú àti òkúta iyebíye wá.
11 I poczynił król z onego drzewa almugimowego schody do domu Pańskiego, i do domu królewskiego, i harfy, i lutnie śpiewakom; a nie widziano przedtem nigdy takich rzeczy w ziemi Judzkiej.
Ọba sì lo igi algumu náà láti fi ṣe àtẹ̀gùn fún ilé Olúwa àti fún ilé ọba àti láti fi ṣe dùùrù àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Kò sì ṣí irú rẹ̀ tí a ti rí rí ní ilẹ̀ Juda.
12 Król także Salomon dał królowej z Saby wszystko, czego chciała, i czego żądała, oprócz nagrody za to, co była przyniosła do króla. Potem się wróciła, i odjechała do ziemi swej, ona i słudzy jej.
Ọba Solomoni fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ohun tí ó béèrè fún àti ohun tí ó wù ú; ó sì fi fún un ju èyí tí ó mú wá fún un lọ. Nígbà náà ni ó lọ ó sì padà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìlú rẹ̀.
13 A była waga tego złota, które przychodziło Salomonowi na każdy rok, sześć set i sześćdziesiąt i sześć talentów złota.
Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì,
14 Oprócz tego, co kupcy, i którzy handlują przynosili; także wszyscy królowie Arabscy, i książęta onej ziemi przywozili złoto i srebro Salomonowi.
láì tí ì ka àkójọpọ̀ owó ìlú tí ó wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn oníṣòwò àti àwọn ọlọ́jà. Àti pẹ̀lú gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀ náà mu wúrà àti fàdákà wá fún Solomoni.
15 Przetoż uczynił król Salomon dwieście tarczy ze złota ciągnionego; sześć set syklów złota ciągnionego wychodziło na każdą tarczą.
Ọba Solomoni sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì tí a fi òlùlù wúrà sí ọ̀kánkán asà.
16 Przytem trzysta puklerzy ze złota ciągnionego, trzysta syklów złotych wychodziło na każdy puklerz, które schował król w dom lasu Libanowego.
Ó sì ti ṣe ọ̀ọ́dúnrún kékeré ṣékélì tí a fi òlùlù wúrà, pẹ̀lú ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì wúrà nínú àpáta kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sínú ààfin ti ó wà ní igbó Lebanoni.
17 Uczynił także król stolicę wielką z kości słoniowej, i powlókł ją szczerem złotem.
Nígbà náà ọba sì ṣe ìtẹ́ pẹ̀lú eyín erin ńlá kan ó sì fi wúrà tó mọ́ bò ó.
18 A sześć stopni było u onej stolicy, a podnóżek był ze złota, trzymający się stolicy; poręcze też były z obudwu stron, kędy siadano, a dwa lwy stały u poręczy.
Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, àti pẹ̀lú àpótí ìtìsẹ̀ wúrà kan ni a dè mọ́ ọn. Ní ìhà méjèèjì ibi ìjókòó ní ó ní ìgbọ́wọ́lé, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́bàá olúkúlùkù wọn.
19 Dwanaście też lwów stało na sześciu stopniach z obu stron; nie było nic takowego urobiono w żadnem królestwie.
Kìnnìún méjìlá dúró lórí àtẹ̀gùn mẹ́ta, ọ̀kan àti ní ìhà olúkúlùkù àtẹ̀gùn kò sì sí irú rẹ̀ tí a ti ṣe rí fún ìjọba mìíràn.
20 Nadto wszystkie naczynia, z których pijał król Salomon, były złote, i wszystek sprzęt w domu lasu Libanowego ze złota szczerego; nic nie było ze srebra, bo go nie miano w żadnej cenie za dni Salomonowych.
Gbogbo ohun èlò mímú ìjọba Solomoni ọba ni ó jẹ́ kìkì wúrà, àti gbogbo ohun èlò ààfin ní igbó Lebanoni ni ó jẹ́ wúrà mímọ́. Kò sì ṣí èyí tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
21 Albowiem okręty królewskie chodziły na morze z sługami Hiramowymi; raz we trzy lata wracały się też okręty z morza, przynosząc złoto, i srebro, kości słoniowe, i koczkodany, i pawie.
Ọba ní ọkọ̀ tí a fi ń tajà tí àwọn ọkùnrin Hiramu ń bojútó. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ó máa ń padà, ó ń gbé wúrà àti fàdákà àti eyín erin àti ìnàkí.
22 A tak uwielbiony jest król Salomon nad wszystkich królów ziemskich, bogactwy i mądrością.
Ọba Solomoni sì tóbi nínú ọláńlá àti ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba tí ó kù lórí ilẹ̀ ayé lọ.
23 Przetoż wszyscy królowie ziemscy pragnęli widzieć Salomona, aby słuchali mądrości jego, którą był dał Bóg w serce jego.
Gbogbo àwọn ọba ayé ń wá ojúrere lọ́dọ̀ Solomoni láti gbọ́n ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sínú ọkàn rẹ̀.
24 I przynosili mu każdy upominek swój, naczynia srebrne, i naczynia złote, szaty, zbroje, i rzeczy wonne, konie i muły, a to na każdy rok.
Ní ọdọọdún, olúkúlùkù ẹni tí o wá mú ẹ̀bùn ohun èlò wúrà àti fàdákà àti aṣọ ìbora, ìhámọ́ra, àti tùràrí, àti ẹṣin àti ìbáaka wá.
25 I miał Salomon cztery tysiące stajen koni i wozów, a dwanaście tysięcy jezdnych, których rozsadził po miastach wozów, i przy sobie w Jeruzalemie.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé fún àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, àti ẹgbàá mẹ́fà àwọn ẹṣin, tí ó fi pamọ́ nínú ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ nínú Jerusalẹmu.
26 I panował nad wszystkimi królmi od rzeki aż do ziemi Filistyńskiej, i aż do granicy Egipskiej.
Ó sì jẹ ọba lórí gbogbo àwọn ọba láti odò Eufurate títí dé ilé àwọn ará Filistini àti títí ó fi dé agbègbè ti Ejibiti.
27 A złożył król srebra w Jeruzalemie jako kamienia, a ceder złożył jako płonnych fig, których rośnie na polu bardzo wiele.
Ọba sì sọ fàdákà dàbí òkúta ní Jerusalẹmu, àti igi kedari ni ó sì ṣe bí igi sikamore, tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
28 Przywodzono też konie Salomonowi z Egiptu i ze wszystkich innych ziem.
A sì mú àwọn ẹṣin Solomoni wa láti ilẹ̀ òkèrè láti Ejibiti àti láti gbogbo ìlú.
29 A ostatek spraw Salomonowych pierwszych i ostatnich zapisano w księdze Natana proroka, i w proroctwie Achyjasza Sylonitczyka, i w widzeniach Jaddy widzącego, który prorokował przeciw Jeroboamowi, synowi Nabatowemu.
Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ìjọba Solomoni, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn Natani wòlíì, àti nínú ìsọtẹ́lẹ̀ Ahijah ará Ṣilo àti nínú ìran Iddo, wòlíì tí o so nípa Jeroboamu ọmọ Nebati?
30 I królował Salomon w Jeruzalemie nad wszystkim Izraelem czterdzieści lat.
Solomoni jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo àwọn Israẹli fún ogójì ọdún
31 Zasnął potem Salomon z ojcami swymi, a pochowano go w mieście Dawida, ojca jego, a Roboam syn jego, królował miasto niego.
Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀, Rehoboamu, ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< II Kronik 9 >