< II Kronik 33 >

1 We dwunastym roku był Manases, gdy królować począł; a pięćdziesiąt i pięć lat królował w Jeruzalemie.
Manase jẹ́ ọmọ ọdún méjìlá nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta.
2 Ten czynił złe przed oczyma Pańskiemi według obrzydłości onych narodów, które wygnał Pan przed obliczem synów Izraelskich.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. Nípa títẹ̀lé ọ̀nà iṣẹ́ ìríra ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli rìn.
3 Albowiem znowu pobudował wyżyny, które był poburzył Ezechyjasz, ojciec jego; wystawił też i ołtarze Baalom, a nasadził gajów, i kłaniał się wszystkiemu wojsku niebieskiemu, a służył mu,
Ó tún kọ́ àwọn ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah ti fọ́ túútúú. Ó sì gbé àwọn pẹpẹ dìde fún àwọn Baali ó sì ṣe àwọn ère Aṣerah. Ó foríbalẹ̀ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run ó sì sìn wọ́n.
4 Pobudował też ołtarze w domu Pańskim, o którym powiedział był Pan: W Jeruzalemie będzie imię moje na wieki.
Ó kọ́ àwọn pẹpẹ sínú ilé Olúwa ní èyí tí Olúwa ti wí pé, “Orúkọ mi yóò wà ní Jerusalẹmu títí láé.”
5 Nadto nabudował ołtarze wszystkiemu wojsku niebieskiemu we dwóch sieniach domu Pańskiego.
Nínú ààfin méjèèje ti ilé Olúwa, ó kọ́ àwọn pẹpẹ fún gbogbo àwọn ogun ọ̀run
6 I przewodził synów swych przez ogień w dolinie synów Hennomowych; nadto czasów przestrzegał, i bawił się wieszczbą i czarnoksięstwem, a ustawił czarnoksiężników i guślarzy, i bardzo wiele złego czynił przed oczyma Pańskiemi, draźniąc go.
Ó sì mú kí àwọn ọmọ ara rẹ̀ kí ó kọjá láàrín iná ní àfonífojì Beni-Hinnomu, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
7 Postawił także bałwana rytego, którego był uczynił w domu Bożym, o którym był rzekł Bóg do Dawida i do Salomona, syna jego: W domu tym i w Jeruzalemie, którem obrał ze wszystkich pokoleń Izraelskich, położę imię moje na wieki;
Ó mú ère gbígbẹ́ tí ó ti gbẹ́ ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, ní èyí tí Ọlọ́run ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí mo ti yàn kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò fi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé.
8 A nie dopuszczę się więcej ruszyć nodze Izraela z ziemi, którąm naznaczył ojcom waszym, by jedno strzegli i sprawowali się według wszystkiego, com i rozkazał, według wszystkiego zakonu, i ustaw, i sądów wydanych przez Mojżesza.
Èmi kì yóò ṣí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli kúrò mọ́ ní ilẹ̀ náà tí èmi ti yàn fún àwọn baba ńlá yín, níwọ̀n bí wọ́n bá ṣe pẹ̀lẹ́ láti ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ fún wọn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo òfin, àṣẹ àti àwọn ìlànà tí a fún yín láti ọwọ́ Mose wá.”
9 Ale Manases zwiódł Judę i obywateli Jeruzalemskich, tak iż się gorzej sprawowali niż narody, które Pan wygładził przed obliczem synów Izraelskich.
Ṣùgbọ́n Manase mú kí Juda àti àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu yapa, àti láti ṣe búburú ju àwọn orílẹ̀-èdè lọ, àwọn tí Olúwa ti parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
10 Bo choć mówił Pan do Manasesa, i do ludu jego, przecież oni nie słuchali.
Olúwa bá Manase sọ̀rọ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò kọbi ara sí i.
11 Przetoż Pan nawiódł na nich hetmanów wojska króla Assyryjskiego, którzy pojmawszy Manasesa w cierniu, i związawszy go dwoma łańcuchami, zawiedli go do Babilonu.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa mú àwọn alákòóso ọmọ-ogun ọba Asiria láti dojúkọ wọ́n, tí ó mú Manase nígbèkùn, ó fi ìwọ̀ mú un ní imú rẹ̀, ó dè é pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ ó sì mú un lọ sí Babeli.
12 Który będąc uciśniony, modlił się Panu, Bogu swemu, i upokorzył się bardzo przed obliczem Boga ojców swoich,
Nínú ìpọ́njú rẹ̀, ó wá ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. Ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gidigidi níwájú Ọlọ́run àwọn baba rẹ̀.
13 I prosił go; a dał mu się uprosić, i wysłuchał modlitwę jego, a przywrócił go do Jeruzalemu na królestwo jego. Tedy poznał Manases, iż sam Pan jest Bogiem.
Nígbà tí ó sì gbàdúrà sí i, inú Olúwa dùn sí àdúrà rẹ̀, ó sì tẹ́tí sí ẹ̀bẹ̀ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni ó mú un padà wá sí Jerusalẹmu àti sí ìjọba rẹ̀. Nígbà náà Manase mọ̀ wí pé Olúwa ni Ọlọ́run.
14 Potem budował mur około miasta Dawidowego ku zachodniej stronie Gichonu potoku aż do wejścia do bramy rybnej, i otoczył murem Ofel, i wywiódł go bardzo wysoko; postanowił też hetmanów po wszystkich miastach obronnych w Judzie.
Ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí, ó mọ odi kan lẹ́yìn ìlú Dafidi, ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Gihoni, ní àfonífojì, àní ní àtiwọ ẹnu ibodè ẹja, ó sì yí orí òkè Ofeli ká; ó sì mọ ọ́n ga sókè gidigidi, ó sì fi balógun sínú gbogbo ìlú olódi Juda wọ̀n-ọn-nì.
15 Zniósł też bogów cudzych, i bałwana z domu Pańskiego, i wszystkie ołtarze, które był pobudował na górze domu Pańskiego, i w Jeruzalemie, i wyrzucił za miasto.
Ó pa gbogbo àwọn Ọlọ́run àjèjì run. Ó sì hú gbogbo àwọn ère kúrò nínú ilé Olúwa, pẹ̀lú gbogbo àwọn pẹpẹ tí ó ti kọ́ ní òkè ilé Olúwa àti ní Jerusalẹmu; ó sì kó wọn jáde kúrò nínú ìlú.
16 Zatem naprawił ołtarz Pański, i sprawował na nim ofiary spokojne, i dziękczynienia, a przykazał Judzie, aby służyli Panu, Bogu Izraelskiemu.
Nígbà náà ni ó mú àwọn pẹpẹ padà bọ̀ sípò. Ó sì rú ọrẹ ìdàpọ̀ àti ọrẹ-ọpẹ́ lórí rẹ̀. Ó sì sọ fún Juda láti sin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
17 Wszakże jeszcze lud ofiarował na wyżynach, lecz tylko Panu, Bogu swemu.
Àwọn ènìyàn, ko tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ ní àwọn ibi gíga. Ṣùgbọ́n sí Olúwa Ọlọ́run wọn nìkan.
18 Ale inne sprawy Manasesowe, i modlitwa jego do Boga jego, i słowa widzących, którzy mawiali do niego w imię Pana, Boga Izraelskiego, są w księgach spraw królów Izraelskich.
Àwọn iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Manase pẹ̀lú àdúrà rẹ̀ sí Ọlọ́run rẹ̀ àti àwọn ọ̀rọ̀ tí àwọn aríran sọ sí i ní orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wà nínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
19 Modlitwa zaś jego, i jako jest wysłuchany, i każdy grzech jego, i przestępstwo jego, i miejsca, na których był pobudował wyżyny, i wystawił gaje święcone, i bałwany, przedtem niż się był upokorzył, zapisane w księgach Chozaja.
Àdúrà rẹ̀ àti bí inú Ọlọ́run ṣe dùn sí àdúrà rẹ̀ àti gbogbo àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àti àìṣòótọ́, àti àwọn òpó níbi tí ó kọ́ àwọn ibi gíga sí, ó sì gbé àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà kí ó tó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, gbogbo rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìrántí àwọn aríran.
20 Potem zasnął Manases z ojcami swymi, i pochowali go w domu jego; a Amon, syn jego, królował miasto niego.
Manase sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sínú ààfin rẹ̀. Amoni ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
21 We dwudziestu i dwóch latach był Amon, gdy królować począł, a dwa lata królował w Jeruzalemie.
Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
22 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, jako czynił Manases, ojciec jego; albowiem wszystkim bałwanom, których był naczynił Manases, ojciec jego, ofiarował Amon, i służył im.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe. Amoni rú ẹbọ sí gbogbo àwọn òrìṣà tí Manase baba rẹ̀ ti ṣe, ó sì sìn wọ́n.
23 A nie upokorzył się przed obliczem Pańskiem, jako się upokorzył Manases, ojciec jego; owszem ten Amon daleko więcej grzeszył.
Ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i baba rẹ̀ Manase. Kò rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Olúwa: ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ Amoni sì ń pọ̀ sì í.
24 I sprzysięgli się przeciw niemu słudzy jego, i zabili go w domu jego.
Àwọn oníṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ sí i. Wọ́n sì pa á ní ààfin rẹ̀.
25 Ale lud onej ziemi pobił wszystkich, co się byli sprzysięgli przeciw królowi Amonowi; a postanowił lud ziemi królem Jozjasza, syna jego, miasto niego.
Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì mú Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< II Kronik 33 >