< II Kronik 25 >

1 Dwadzieścia i pięć lat miał Amazyjasz, gdy królować począł, a dwadzieścia i dziewięć lat królował w Jeruzalemie. Imię matki jego Joadana, z Jeruzalemu.
Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
2 I czynił co było dobrego przed oczyma Pańskiemi, wszakże nie doskonałem sercem.
Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
3 I stało się, gdy było utwierdzone królestwo jego, że pomordował sługi swe, którzy zabili króla, ojca jego.
Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
4 Wszakże synów ich niepobił: ale uczynił, jako napisano w zakonie, w księgach Mojżeszowych, gdzie przykazał Pan, mówiąc: Nie umrą ojcowie za synów, ani synowie umrą za ojców, ale każdy za grzech swój umrze.
Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
5 Tedy zgromadził Amazyjasz lud Judzki, i postanowił ich według domów ojcowskich za półkowników i za rotmistrzów po wszystkiem pokoleniu Judowem, i Benjaminowem, a policzywszy ich od dwudziestu lat i wyżej, znalazł ich trzy kroć sto tysięcy na wybór, gotowych do boju, noszących drzewce i tarczę.
Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
6 Najął także za pieniądze z Izraela sto tysięcy mężów dużych za sto talentów srebra.
Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
7 Lecz mąż Boży przyszedł do niego mówiąc: Królu! niech nie wychodzi z tobą wojsko Izraelskie; bo nie masz Pana z Izraelem i ze wszystkimi synami Efraimowymi.
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
8 Ale jeźli mi nie wierzysz, idź, i zmocnij się ku bitwie, a porazi cię Bóg przed nieprzyjacielem; bo w mocy Bożej jest ratować, i do upadku przywieść.
Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
9 Tedy rzekł Amazyjasz mężowi Bożemu: A cóż mam czynić z tem stem talentów, którem dał wojsku Izraelskiemu? Odpowiedział mąż Boży: Ma Pan skąd ci może dać daleko więcej nadto.
Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
10 Przetoż oddzielił Amazyjasz to wojsko, które było przyszło do niego z Efraima, aby szło na miejsce swe; i rozgniewali się bardzo na Judę, i wrócili się do miejsca swego z wielkim gniewem.
Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
11 Lecz Amazyjasz zmocniwszy się, wywiódł lud swój, i ciągnął na dolinę Soli, i poraził synów Seir dziesięć tysięcy.
Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
12 Dziesięć także tysięcy żywo pojmali synowie Judzcy, i przywiedli ich na wierzch skały, i zrzucili ich z wierzchu skały, aż się wszyscy porozpukali.
Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
13 Ono zasię wojsko, które rozpuścił Amazyjasz, aby nie szło z nim na wojnę, wtargnęło do miast Judzkich, od Samaryi aż do Betoronu, a poraziwszy w nich trzy tysiące ludu, zebrali korzyść wielką.
Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
14 A gdy się Amazyjasz wrócił od porażki Idumejczyków, przyniósł z sobą bogów synów Seir, i wystawił ich sobie za bogów, a kłaniał się przed nimi, i kadził im.
Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
15 Przetoż rozgniewał się Pan bardzo na Amazyjasza, i posłał do niego proroka, który mu rzekł: Przeczże szukasz bogów ludu tego, którzy nie wyrwali ludu swego z ręki twej?
Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
16 A gdy on do niego mówił, rzekł mu król: Izali cię za radcę królewskiego obrano? Przestań tego, aby cię nie zabito. A tak przestał prorok; wszakże rzekł: Wiem, że cię umyślił Bóg zatracić, gdyżeś to uczynił, a nie usłuchałeś rady mojej.
Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
17 Tedy naradziwszy się Amazyjasz, król Judzki, posłał do Joaza, syna Joachaza, syna Jehu, króla Izraelskiego, mówiąc: Pójdź, a wejrzymy sobie w oczy.
Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
18 I posłał Joaz, król Izraelski, do Amazyjasza, króla Judzkiego, mówiąc: Oset, który jest na Libanie, posłał do cedru Libańskiego, mówiąc: Daj córkę twoję synowi memu za żonę. Wtem idąc tedy zwierz polny, który był na Libanie, podeptał on oset.
Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
19 Myśliłeś: Otom poraził Edomczyków; przetoż wyniosło cię serce twoje, abyś się tem chlubił. Siedźże tedy w domu twym; przecz się masz wdawać w to złe, abyś upadł, ty i Juda z tobą?
Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
20 Ale nie usłuchał Amazyjasz; bo to było od Boga, aby ich podał w ręce nieprzyjacielskie, przeto, że szukali bogów Idumejskich:
Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
21 Wyciągnął tedy Joaz, król Izraelski, i wejrzeli sobie w oczy, on i Amazyjasz, król Judzki, w Betsemes, które jest w Judzie.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
22 I porażony jest Juda przed Izraelem, a pouciekali każdy do namiotów swoich.
Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
23 Lecz Amazyjasza, króla Judzkiego, syna Joazowego, syna Joachaza, pojmał król Izraelski w Betsemes, i przywiódł go do Jeruzalemu, a obalił mury Jeruzalemskie od bramy Efraimskiej aż do bramy narożnej, na czterysta łokci.
Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
24 I zabrał wszystko złoto i srebro, i wszystkie naczynia, które się znalazły w domu Bożym u Obededoma i w skarbach domu królewskiego, i ludzi, zastawnych, a wrócił się do Samaryi.
Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
25 I żył Amazyjasz, syn Joazowy, król Judzki, po śmierci Joaza, syna Joachaza, króla Izraelskiego, piętnaście lat.
Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
26 A inne sprawy Amazyjaszowe, pierwsze i poślednie, izali nie są zapisane w księgi królów Judzkich i Izraelskich?
Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
27 A od onego czasu, jako odpadł Amazyjasz od Pana, uczyniono przeciwko niemu sprzysiężenie w Jeruzalemie. Lecz on uciekł do Lachis; ale posłano za nim do Lachis, i zabito go tam.
Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
28 A przyniósłszy go na koniach, pochowali go z ojcami jego w mieście Judzkiem.
A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.

< II Kronik 25 >