< II Kronik 17 >
1 Tedy królował Jozafat, syn jego miasto niego, a zmocnił się przeciw Izraelowi.
Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
2 I osadził żołnierzem wszystkie miasta Judzkie obronne; osadził też i ziemię Judzką, także miasta Efraimskie, które był pobrał Aza, ojciec jego.
Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
3 A był Pan z Jozafatem, przeto, iż chodził drogami pierwszemi Dawida, ojca swego, a nie szukał Baalów;
Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
4 Ale Boga ojca swego szukał, i w przykazaniach jego chodził, a nie według spraw ludu Izraelskiego.
Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
5 I utwierdził Pan królestwo w ręce jego; a dawał wszystek lud Judzki dary Jozafatowi, tak iż miał bogactwa, i sławę bardzo wielką.
Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
6 A nabywszy wielkiego serca na drogach Pańskich, tem więcej znosił wyżyny i gaje bałwochwalcze z ziemi Judzkiej.
Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
7 Potem roku trzeciego królowania swego posłał książąt swoich, Benchaila, i Obadyjasza, i Zacharyjasza, i Natanaela, i Micheasza, aby uczyli w miastach Judzkich.
Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
8 A przy nich Lewitów, Semejasza, i Natanijasza, i Zabadyjasza, i Asaela i Semiramota, i Jonatana, i Adonijasza, i Tobijasza, i Tobadonijasza, Lewitów; a z nimi Elisama, i Jorama, kapłanów;
Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
9 Którzy uczyli w Judzie, mając z sobą księgi zakonu Pańskiego, i obchodzili wszystkie miasta Judzkie, i nauczali lud.
Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
10 Przetoż przyszedł strach Pański na wszystkie królestwa ziemi, które były około Judy, i nie śmieli walczyć przeciw Jozafatowi.
Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
11 Nawet i Filistynowie przynosili Jozafatowi dary i dań pieniężną. Arabczycy też przygnali mu drobnego bydła, baranów siedm tysięcy i siedm set, kozłów także siedm tysięcy i siedm set.
Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
12 Wzmagał się tedy Jozafat, i rosł nader bardzo, i pobudował w Judzie zamki, i miasta dla składów.
Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
13 A pracy wiele podjął około miast Judzkich; mężów też walecznych i potężnych miał w Jeruzalemie.
Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
14 A tać jest liczba ich według domów ojców ich: z Judy książęta nad tysiącami: książę Adna, a z nim bardzo dużych mężów trzy kroć sto tysięcy.
Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
15 A po nim książę Johanan, a z nim dwa kroć sto tysięcy, i ośmdziesiąt tysięcy.
Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
16 A po nim Amazyjasz, syn Zychry, który się był dobrowolnie oddał Panu, a z nim dwa kroć sto tysięcy mężów dużych.
àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
17 Przytem z synów Benjaminowych, mąż duży Elijada, a z nim ludu zbrojnego z łukami i z tarczami dwa kroć sto tysięcy.
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
18 A po nim Jozabad, a z nim sto i ośmdziesięt tysięcy gotowych do boju.
àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
19 Ci służyli królowi, oprócz tych, którymi był król osadził miasta obronne po wszystkiej ziemi Judzkiej.
Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.