< II Kronik 15 >

1 Tedy na Azaryjasza, syna Obedowego, przypadł Duch Boży.
Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
2 Który wyszedłszy przeciw Azie rzekł mu: Słuchajcie mię, Aza i wszystko pokolenie Judowe i Benjaminowe! Pan był z wami, pókiście byli z nim, a jeźli go szukać będziecie, znajdziecie go: ale jeźli go opuścicie, opuści was.
Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
3 Przez wiele dni był Izrael bez Boga prawdziwego, i bez kapłana, nauczyciela, i bez zakonu:
Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
4 Wszakże gdyby się byli nawrócili w utrapieniu swem do Pana, Boga Izraelskiego, a szukali go, dałby się im był znaleść.
Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
5 Ale teraźniejszych czasów niebezpieczno wychodzić i wchodzić; bo zamięszanie wielkie między wszystkimi obywatelami ziemi.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
6 I depcze naród po narodzie, a miasto po mieście, przeto, że ich Bóg strwożył wszelakiem uciśnieniem.
Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
7 Przetoż wy zmacniajcie się, a niech nie słabieją ręce wasze; bo czeka zapłata pracy waszej.
Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
8 A gdy usłyszał Aza te słowa, i proroctwo Obeda proroka, zmocnił się, i zniósł obrzydliwości ze wszystkiej ziemi Judzkiej i Benjamińskiej, i z miast, które był pobrał na górze Efraim, i odnowił ołtarz Pański, który był przed przysionkiem Pańskim.
Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
9 Potem zebrał wszystek lud z Judy i z Benjamina, i przychodniów, którzy u nich byli z Efraima, i z Manasesa i z Symeona; bo ich było bardzo wiele zbiegło z Izraela do niego, widząc, iż Pan, Bóg jego, z nim był.
Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 I zgromadzili się do Jeruzalemu miesiąca trzeciego, roku piętnastego królestwa Azy.
Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
11 I sprawowali ofiary Panu dnia onego z łupów, które byli przygnali, wołów siedm set, a owiec siedm tysięcy.
Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
12 I uczynili umowę, aby szukali Pana, Boga ojców swoich, ze wszystkiego serca swego, i ze wszystkiej duszy swojej.
Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
13 A ktobykolwiek nie szukał Pana, Boga Izraelskiego, aby był zabity, od najmniejszego aż do największego, od męża aż do niewiast.
Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
14 I przysięgli Panu głosem wielkim, i z krzykiem, i z trąbami, i z kornetami.
Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
15 A weselił się wszystek lud Judzki z onej przysięgi: albowiem ze wszystkiego serca swego przysięgali, i ze wszystkiej ochoty szukali go, i dał się im znaleść, i dał im Pan odpocznienie zewsząd.
Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
16 Nadto i Maachę, matkę swą, król Aza z państwa złożył, przeto, że była uczyniła w gaju bałwana brzydkiego; i podciął Aza bałwana jej, i pokruszył go, a spalił u potoku Cedron.
Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
17 A choć wyżyny nie były zniesione z Izraela, przecież serce Azy było doskonałe po wszystkie dni jego.
Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
18 Wniósł też, co był poświęcił ojciec jego, i co sam poświęcił, do domu Bożego, srebro i złoto i naczynia.
Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
19 A nie było wojny aż do roku trzydziestego i piątego królowania Azy.
Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.

< II Kronik 15 >