< II Kronik 14 >

1 A gdy zasnął Abijasz z ojcami swymi, a pochowano go w mieście Dawidowem, tedy królował Aza, syn jego, miasto niego. Za dni jego była w pokoju ziemia, przez dziesięć lat.
Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Ní àwọn ọjọ́ rẹ̀, orílẹ̀-èdè wà ní àlàáfíà fún ọdún mẹ́wàá.
2 I czynił Aza co było dobrego, i przyjemnego w oczach Pana, Boga swego.
Asa ṣe ohun tí ó dára, tí ó sì tọ́ ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
3 Bo poburzył ołtarze obce, i wyżyny, i podruzgotał bałwany ich, i wyrąbał gaje ich;
Ó gbé àwọn pẹpẹ àjèjì kúrò àti àwọn ibi gíga. Ó fọ́ àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀, ó sì gé àwọn ère Aṣerah bolẹ̀.
4 A przykazał Judzie, aby szukali Pana, Boga ojców swych, i przestrzegali zakonu i przykazań jego.
Ó pa á láṣẹ fún Juda láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wọn àti láti tẹ̀lé àwọn òfin rẹ̀ àti àṣẹ.
5 Zniósł też ze wszystkich miast Judzkich wyżyny, i słoneczne bałwany, a było w pokoju królestwo za czasu jego.
Ó gbé àwọn ibi gíga kúrò àti àwọn pẹpẹ tùràrí ní gbogbo ìlú ní Juda. Ìjọba sì wà ní àlàáfíà ní abẹ́ rẹ̀.
6 Nadto pobudował miasta obronne w Judzie, przeto, iż była w pokoju ziemia i nie powstała wojna przeciwko niemu za onych lat; bo mu dał Pan odpocznienie.
Ó mọ àwọn ìlú ààbò ti Juda, níwọ̀n ìgbà tí ìlú ti wà ní àlàáfíà. Kò sí ẹnikẹ́ni ti o jagun pẹ̀lú rẹ̀ nígbà náà, nítorí Olúwa fún un ní ìsinmi.
7 I rzekł do Judy: Pobudujmy te miasta, i otoczmy je murem i wieżami, bramami, i zaworami, póki ziemia jest w mocy naszej; bośmy szukali Pana, Boga naszego; szukaliśmy go, i sprawił nam odpocznienie zewsząd. Przetoż budowali, a szczęściło się im.
“Ẹ jẹ́ kí a kọ́ àwọn ìlú wọ̀nyí,” ó wí fún Juda, “kí ẹ sì mọ odi yí wọn ká pẹ̀lú àwọn ilé ìṣọ́ gíga, àwọn ẹnu-ọ̀nà òde, àti àwọn ìpẹ́ẹ̀rẹ̀. Ilé náà ti wà, nítorí a ti béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run wa; a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì ti fún wa ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kọ́ ọ, wọn sì ṣe rere.
8 I miał Aza wojsko noszących tarcz i drzewce: z Judy trzykroć sto tysięcy, a z Benjamina noszących puklerz i ciągnących łuk dwa kroć sto tysięcy i ośmdziesiąt tysięcy. Ci wszyscy byli bardzo mężni.
Asa ní àwọn ọmọ-ogun ti ó jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin láti Juda. Pẹ̀lú àwọn ohun èlò àwọn àpáta ńlá àti ọ̀kọ̀ àti ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá láti Benjamini wọ́n dira pẹ̀lú àwọn àpáta kéékèèké àti àwọn ọrun. Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ ògbójú jagunjagun ọkùnrin.
9 Tedy wyciągnął przeciw nim Zara Etyjopczyk, mając wojska dziesięć kroć sto tysięcy, a wozów trzy sta, i przyciągnął aż do Maresy.
Sera ará Etiopia yàn láti dojúkọ wọ́n, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú ọ̀ọ́dúnrún kẹ̀kẹ́, wọ́n sì wá láti jìnnà réré bí Meraṣa.
10 Wyciągnął też i Aza przeciw niemu, i uszykowali wojska w dolinie Sefata u Maresy.
Asa jáde lọ láti lọ bá a. Wọ́n sì mú ibi ogun ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Sefata lẹ́bàá Meraṣa.
11 Tedy zawołał Aza do Pana, Boga swego, i rzekł: O Panie! ty nie potrzebujesz wielu, abyś ratował tego, który nie ma potęgi. Ratujże nas, o Panie, Boże nasz! gdyż na tobie spolegamy, a w imię twoje idziemy przeciwko temu mnóstwu. Tyś Pan, Bóg nasz; niech nie ma góry nad tobą człowiek śmiertelny.
Nígbà náà, Asa ké pe Olúwa Ọlọ́run baba a rẹ̀, ó sì wí pé “Olúwa kò sí ẹnìkan bí rẹ láti rán aláìlágbára lọ́wọ́ láti dójú kọ alágbára. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run wa, nítorí tí àwa gbẹ́kẹ̀lé ọ àti ní orúkọ rẹ ni àwa fi wá láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun yìí. Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run wa; má ṣe jẹ́ kí ènìyàn kó ṣẹ́gun rẹ.”
12 A tak poraził Pan Etyjopczyków przed Azą i przed Judą, tak iż uciekli Etyjopczycy.
Olúwa lu àwọn ará Kuṣi bolẹ̀ níwájú Asa àti Juda. Àwọn ará Kuṣi sálọ.
13 A gonił ich Aza i lud, który był z nim, aż do Gierary. I polegli Etyjopczycy, tak, że nie mogli wskórać: bo starci są przed obliczem Pańskiem i przed wojskiem jego. I nabrali łupów bardzo wiele.
Asa àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sá tẹ̀lé wọn ní jìnnà réré sí Gerari. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, àwọn ará Kuṣi ṣubú, wọn kò sì le sán padà mọ́. Wọn rún wọn mọ́lẹ̀ níwájú Olúwa àti ọmọ-ogun rẹ̀. Àwọn ọkùnrin Juda kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun.
14 Nadto poburzyli wszystkie miasta około Gierary; albowiem przypadł strach Pański na nich, i splundrowali one wszystkie miasta; bo w nich była wielka korzyść.
Wọ́n pa gbogbo àwọn ìletò tí ó wà ní ẹ̀bá Gerari, nítorí tí ìpayà Olúwa ti sọ̀kalẹ̀ sórí wọn. Wọ́n kó gbogbo ìkógun àwọn ìletò yìí lọ, níwọ̀n ìgbà tí ọ̀pọ̀ ìkógun ti wà níbẹ̀.
15 Także i obory trzód poburzyli; a zająwszy owiec i wielbłądów bardzo wiele, wrócili się do Jeruzalemu.
Wọ́n kọlu àwọn ibùdó àwọn darandaran, wọ́n sì gbé àwọn ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ àti àwọn ìbákasẹ. Nígbà náà wọ́n padà sí Jerusalẹmu.

< II Kronik 14 >