< I Samuela 8 >
1 I stało się, gdy się zstarzał Samuel, że postanowił syny swe sędziami nad Izraelem.
Nígbà tí Samuẹli di arúgbó, ó yan àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí adájọ́ fún Israẹli.
2 A było imię syna jego pierworodnego Joel, a imię drugiego syna jego Abija; ci byli sędziami w Beerseba.
Orúkọ àkọ́bí rẹ̀ a máa jẹ́ Joẹli àti orúkọ èkejì a máa jẹ́ Abijah, wọ́n ṣe ìdájọ́ ní Beerṣeba.
3 Ale nie chodzili synowie jego drogami jego; lecz udali się za łakomstwem, i brali dary, a wywracali sąd.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀, kò rìn ní ọ̀nà rẹ̀. Wọ́n yípadà sí èrè àìṣòótọ́, wọ́n gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì ń yí ìdájọ́ po.
4 Przetoż zebrali się wszyscy starsi Izraelscy, i przyszli do Samuela do Ramaty,
Bẹ́ẹ̀ ni, gbogbo àwọn àgbàgbà ti Israẹli péjọpọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama.
5 I rzekli mu: Otoś się ty zstarzał, a synowie twoi nie chodzą drogami twojemi; przetoż postanów nam króla, aby nas sądził, jako je wszystkie narody mają.
Wọ́n wí fún un pé, “Ìwọ ti di arúgbó, àwọn ọmọ rẹ kò sì rìn ní ọ̀nà rẹ, nísinsin yìí, yan ọba fún wa kí ó lè máa darí wa gẹ́gẹ́ bí i tí gbogbo orílẹ̀-èdè.”
6 Ale się nie podobała ta rzecz Samuelowi, że mówili: Daj nam króla, aby nas sądził; przetoż modlił się Samuel Panu.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n wí pé, “Fún wa ní ọba tí yóò darí wa,” èyí kò tẹ́ Samuẹli lọ́rùn, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
7 Tedy rzekł Pan do Samuela: Usłuchaj głosu ludu tego we wszystkiem, coć powiedzą; albowiem nie tobą wzgardzili, ale mną wzgardzili, iżbym nie królował nad nimi.
Olúwa sì sọ fún Samuẹli pé, “Gbọ́ ohùn àwọn ènìyàn náà, ní gbogbo èyí tí wọ́n sọ fún ọ; nítorí kì í ṣe ìwọ ni wọ́n kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ni wọ́n kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba lórí wọn.
8 A według wszystkich spraw, które czynili od onego dnia, któregom je wywiódł z Egiptu, aż do dnia tego, gdy mię opuścili i służyli bogom obcym, tak też czynią i tobie.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ọjọ́ tí mo mú wọn jáde wá láti Ejibiti títí di ọjọ́ òní, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ń sin ọlọ́run mìíràn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí ọ.
9 Przetoż teraz usłuchaj głosu ich, a wszakże oświadcz się jako najpilniej przed nimi, i oznajmij im prawo króla, który nad nimi ma królować.
Nísinsin yìí, gbọ́ tiwọn; ṣùgbọ́n kìlọ̀ fún wọn dáradára, kí o sì jẹ́ kí wọ́n mọ irú ohun tí ọba tí yóò jẹ́ lórí wọn yóò ṣe.”
10 A tak Samuel odniósł wszystkie słowa Pańskie do ludu, który go prosił o króla,
Samuẹli sọ gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa sí àwọn ọmọ ènìyàn tí ó ń béèrè fún ọba lọ́wọ́ rẹ̀.
11 I mówił: Toć będzie prawo króla, który królować ma nad wami: Syny wasze brać będzie a osadzi nimi wozy swoje, i poczyni je jezdnymi, a będą biegać przed wozem jego;
Ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba tí yóò jẹ lórí yín yóò ṣe. Yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín, yóò sì mú wọn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti fún ẹlẹ́ṣin rẹ, wọn yóò sì máa sáré níwájú kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
12 Poczyni też sobie z nich pułkowniki nad tysiącami, i rotmistrze nad pięćdziesięcioma; poczyni z nich oracze ról swoich, i żeńce żniwa swego, i te, którzyby robili rynsztunki wojenne, i potrzeby do wozów jego.
Yóò yan díẹ̀ láti jẹ́ olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí àádọ́ta àti àwọn mìíràn. Yóò yan wọ́n láti máa tulẹ̀ oko rẹ̀ àti láti máa kórè rẹ̀ àti àwọn mìíràn láti máa ṣe ohun èlò ogun àti ohun èlò kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀.
13 Córki też wasze pobierze, by gotowały rzeczy wonne, i były kucharkami i piekarkami.
Yóò mú àwọn ọmọbìnrin yín láti máa ṣe olùṣe ìkunra olóòórùn dídùn àti láti máa ṣe àsè àti láti máa ṣe àkàrà.
14 Pola też wasze, i winnice wasze, i oliwnice wasze co najlepsze pobierze, a rozda sługom swoim.
Yóò mú èyí tí ó dára jù nínú oko yín, àti nínú ọgbà àjàrà yín àti nínú igi olifi yín, yóò sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
15 Przytem z zasiewków waszych, i z winnic waszych będzie brał dziesięciny, i rozda je komornikom swoim, i sługom swoim.
Yóò mú ìdásímẹ́wàá hóró ọkà yín àti àká èso àjàrà yín, yóò sì fi fún àwọn oníṣẹ́ àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
16 Także sługi wasze, i dziewki wasze, i młodzieńce wasze co najgrzeczniejsze będzie brał, i osły wasze pobierze, i obróci do roboty swojej.
Àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín àti èyí tí ó dára jù nínú ẹran ọ̀sìn àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yín ni yóò mú fún ìlò ti ara rẹ̀.
17 Z bydła waszego dziesięcinę będzie brał, a wy będziecie niewolnikami jego.
Yóò sì mú ìdámẹ́wàá nínú àwọn agbo ẹran yín, yóò sì máa ṣe ẹrú u rẹ̀.
18 I będziecie wołać dnia onego dla króla waszego, którego sobie obierzecie, a nie wysłucha was Pan dnia onego.
Tí ọjọ́ náà bá dé, ẹ̀yin yóò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ ọba tí ẹ̀yin ti yàn. Olúwa kò sì ní dá a yín lóhùn ní ọjọ́ náà.”
19 Ale nie chciał lud usłuchać głosu Samuelowego; owszem mówili: Nic z tego; ale król niech będzie nad nami,
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kọ̀ láti tẹ́tí sí Samuẹli wọ́n wí pé, “Rárá! A bí ìwọ fẹ́ jẹ́ ọba lórí i wa?
20 Abyśmy byli i my, jako i wszystkie narody; będzie nas sądził król nasz, a wychodząc przed nami, będzie odprawował wojny nasze.
Nígbà náà àwa yóò dàbí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, pẹ̀lú ọba láti darí i wa àti láti jáde lọ níwájú wa láti ja ogun wa.”
21 A wysłuchwaszy Samuel wszystkich słów ludu, odniósł je do uszu Pańskich.
Nígbà tí Samuẹli gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn sọ, ó tún tún un sọ níwájú Olúwa.
22 I rzekł Pan do Samuela: Usłuchaj głosu ich, a postanów nad nimi króla. Przetoż rzekł Samuel do mężów Izraelskich: Idźcie każdy do miasta swego.
Olúwa dáhùn pé, “Tẹ́tí sí wọn, kí o sì yan ọba fún wọn.” Nígbà náà, Samuẹli sọ fún àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Kí olúkúlùkù padà sí ìlú u rẹ̀.”