< I Samuela 6 >

1 I była skrzynia Pańska w ziemi Filistyńskiej przez siedm miesięcy.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
2 Tedy przyzwawszy Filistynowie kapłanów i wieszczków, rzekli: Cóż uczynimy z skrzynią Pańską? powiedzcie nam, jako ją odesłać mamy na miejsce jej?
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
3 Którzy odpowiedzieli: Jeźli odeślecie skrzynię Boga Izraelskiego, nie odsyłajcież jej próżnej, ale przy niej koniecznie oddajcie ofiarę za przewinienie; tedyć będziecie uzdrowieni, i dowiecie się, czemu nie odstąpiła ręka jego od was.
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
4 I rzekli: Jakaż będzie ofiara za przewinienie, którą jej oddać mamy? Odpowiedzieli: Według liczby książąt Filistyńskich pięć złotych zadnic i pięć złotych myszy; albowiem jednaka jest plaga na was wszystkich, i na książęta wasze.
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
5 A poczynicie podobieństwa zadnic waszych, i podobieństwa myszy waszych, które psowały ziemię, i oddacie Bogu Izraelskiemu chwałę; owa snać ulży ręki swej nad wami, i nad Bogami waszymi, i nad ziemią waszą.
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
6 A czemuż obciążacie serce wasze, jako obciążali Egipczanie i Farao serce swoje? izaż nie dopiero, gdy dziwne rzeczy nad nimi czynił wypuścili je i wyszli?
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
7 Przetoż teraz sprawcie wóz nowy jeden, a weźmijcie dwie krowy od cieląt, na których nie postało jarzmo, i zaprzężcie te krowy w wóz, a cielęta ich od nich odwiedźcie do domu.
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
8 Weźmijcie też skrzynię Pańską, i wstawcie ją na wóz; a sztuki złote, któreście ofiarowali za przewinienie, włóżcie w skrzynkę po bok jej, a puśćcie ją, że pójdzie.
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
9 A patrzajcie, jeźli drogą granic swych pójdzie do Betsemes, tedyć on na nas dopuścił to wielkie złe; a jeźliż nie, tedy poznamy, że nie ręka jego dotknęła się nas, ale to z trafunku przyszło na nas.
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
10 I uczynili tak oni mężowie, a wziąwszy dwie krowy od cieląt, zaprzęgli je w wóz, a cielęta ich zamknęli w domu.
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
11 Potem wstawili skrzynię Pańską na wóz, i skrzynkę, i myszy złote, i podobieństwa zadnic swoich.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
12 I udały się one krowy drogą, prosto ku Betsemes, a gościńcem jednym idąc szły, a ryczały; i nie zstępowały ani w prawo ani w lewo a książęta Filistyńskie szły za nimi aż do granic Betsemes.
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
13 A na ten czas Betsemczycy żęli pszenicę w dolinie, a podniósłszy oczów swych ujrzeli skrzynię, i uradowali się ujrzawszy ją.
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
14 A gdy wóz przyszedł na pole Jozuego Betsemity, tamże stanął. Tam też był kamień wielki; tedy porąbawszy drwa od onego wozu, ofiarowali one krowy na całopalenie Panu.
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
15 Ale Lewitowie zstawili skrzynię Pańską, i skrzynkę, która była z nią, w której były sztuki złote, i postawili na onym kamieniu wielkim; a mężowie z Betsemes sprawowali całopalenia, i ofiarowali ofiary Panu onego dnia.
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Co widząc pięcioro książąt Filistyńskich, wrócili się do Akkaronu onegoż dnia.
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
17 A teć były zadnice złote, które oddali Filistynowie za przewinienie Panu: Od Azotu jednę, od Gazy jednę, od Aszkalonu jednę, od Gat jednę, i od Akkaronu jednę.
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
18 Myszy także złote według liczby wszytskich miast Filistyńskich, od pięciu księstw, począwszy od miasta murowanego aż do wsi bez muru, i aż do kamienia onego wielkiego, na którym postawili skrzynię Pańską, który jest aż do dnia tego na polu Jozuego Betsemity.
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
19 Ale pobił Pan niektóre z mężów Betsemitskich, przeto iż zaglądali w skrzynię Pańską, i pobił z ludu pięćdziesiąt tysięcy i siedmdziesiąt mężów; i płakał lud, przeto że Pan lud wielką porażką poraził.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
20 I rzekli mężowie z Betsemes: Któż się będzie mógł ostać przed obliczem Pana, Boga tego świętego? i do kogoż pójdzie od nas?
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
21 A tak wyprawili posły do obywateli Karyjatyjarym mówiąc: Przywrócili Filistynowie skrzynię Pańską; pójdźcie, przeprowadźcie ją do siebie.
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”

< I Samuela 6 >