< I Samuela 28 >

1 I stało się w one dni, że zebrali Filistynowie wojska swe na wojnę, aby walczyli z Izraelem. Tedy Achis rzekł do Dawida: Wiedz wiedząc, iż ze mną pociągniesz na wojnę, ty i mężowie twoi.
Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, àwọn Filistini sì kó àwọn ogun wọn jọ, láti bá Israẹli jà. Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Mọ̀ dájúdájú pé, ìwọ yóò bá mi jáde lọ sí ibi ìjà, ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ.”
2 I odpowiedział Dawid Achisowi: Dopiero się ty dowiesz, co uczyni sługa twój. I rzekł Achis do Dawida: Zaiste stróżem głowy mojej postanowię cię po wszystkie dni.
Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Nítòótọ́ ìwọ ó sì mọ ohun tí ìránṣẹ́ rẹ lè ṣe.” Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Nítorí náà ni èmi ó ṣe fi ìwọ ṣe olùṣọ́ orí mi ni gbogbo ọjọ́.”
3 A Samuel już był umarł, i płakał go wszystek Izrael, i pogrzebli go w Ramacie, mieście jego; a Saul wygnał był wieszczki i czarowniki z ziemi.
Samuẹli sì ti kú, gbogbo Israẹli sì sọkún rẹ̀, wọ́n sì sin ín ní Rama ní ìlú rẹ̀. Saulu sì ti mú àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin kúrò ní ilẹ̀ náà.
4 Zebrawszy się tedy Filistynowie, przyciągnęli, a położyli się obozem u Sunam; zebrał też Saul wszystkiego Izraela, a położył się obozem w Gielboe.
Àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ, wọ́n wá, wọ́n sì dó sí Ṣunemu: Saulu sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì tẹ̀dó ní Gilboa.
5 A widząc Saul obóz Filistyński, bał się, a ulękło się serce jego bardzo.
Nígbà tí Saulu sì rí ogun àwọn Filistini náà òun sì bẹ̀rù, àyà rẹ̀ sì wárìrì gidigidi.
6 I radził się Saul Pana; ale mu nie odpowiedział Pan ani przez sny, ani przez urym, ani przez proroki;
Nígbà tí Saulu sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa kò dá a lóhùn nípa àlá, nípa Urimu tàbí nípa àwọn wòlíì.
7 Przetoż rzekł Saul do sług swoich: Szukajcie mi niewiasty, któraby miała ducha wieszczego, a pójdę do niej, i wywiem się przez nię. I rzekli słudzy jego do niego: Oto, niewiasta w Endor, mająca ducha wieszczego.
Saulu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ èmi yóò sì tọ̀ ọ́ lọ, èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, obìnrin kan wà ní Endori tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀.”
8 Tedy odmienił odzienie swoje Saul, a oblókłszy się w insze szaty, szedł sam i dwaj mężowie z nim, a przyszli do niewiasty w nocy, i rzekł: Wróż mi, proszę, przez ducha wieszczego, a wywiedź tego, kogoć powiem.
Saulu sì pa ara dà, ó sì mú aṣọ mìíràn wọ̀, ó sì lọ, àwọn ọmọkùnrin méjì sì pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ obìnrin náà lóru: òun sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ wo nǹkan fún mi, kí o sì mú ẹni tí èmí ó dárúkọ rẹ̀ fún ọ wá sókè fún mi.”
9 I rzekła do niego niewiasta: Oto ty wiesz, co uczynił Saul, iż wygładził wieszczki i czarowniki z ziemi; przeczże ty sidło kładziesz na duszę moję, abyś mię na śmierć podał?
Obìnrin náà sì dá a lóhùn pé, “Wò ó, ìwọ sá à mọ ohun tí Saulu ṣe, bí òun ti gé àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin kúrò ní ilẹ̀ náà; ǹjẹ́ èéha ṣe tí ìwọ dẹkùn fún ẹ̀mí mi, láti mú kí wọ́n pa mí.”
10 I przysiągł jej Saul przez Pana, mówiąc: Jako żywy Pan, że nie przyjdzie na cię karanie dla tego.
Saulu sì búra fún un nípa Olúwa pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìyà kan kì yóò jẹ́ ọ́ nítorí nǹkan yìí.”
11 Tedy rzekła niewiasta: Kogoż ci mam wywieść? A on rzekł: Wywiedź mi Samuela.
Obìnrin náà sì bi í pé, “Ta ni ẹ̀mí ó mú wá sókè fún ọ?” Òun sì wí pé, “Mú Samuẹli gòkè wá fún mi.”
12 A widząc niewiasta Samuela, zawołała głosem wielkim, i rzekła niewiasta do Saula, mówiąc: Przeczżeś mię zdradził, gdyżeś ty jest Saul?
Nígbà tí obìnrin náà sì rí Samuẹli, ó kígbe lóhùn rara: obìnrin náà sì bá Saulu sọ̀rọ̀ pè, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí jẹ? Nítorí pé Saulu ni ìwọ jẹ́.”
13 I rzekł jej król: Nie bój się; cóżeś widziała? I rzekła niewiasta do Saula: Widziałam bogi występujące z ziemi.
Ọba sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù; kín ni ìwọ rí?” Obìnrin náà sì wí fún Saulu pé, “Èmi rí ọlọ́run kan tí ń ti ilẹ̀ wá.”
14 Tedy rzekł do niej: Co za osoba jego? I rzekła: Mąż stary wyszedł, a ten odziany płaszczem. I poznał Saul, że to był Samuel, i schyliwszy się twarzą ku ziemi, pokłonił mu się.
Ó sì bi í pé, “Báwo ni ó ti rí i sí.” Ó sì wí pé, “Ọkùnrin arúgbó kan ni ó ń bọ; ó sì fi agbádá bora.” Saulu sì mọ̀ pé, Samuẹli ni; ó sì tẹríba, ó sì wólẹ̀.
15 Zatem rzekł Samuel do Saula: Przecz mi nie dasz pokoju, wzbudzając mię? Odpowiedział mu Saul: Jestem uciśniony bardzo, gdyż Filistynowie walczą przeciwko mnie, a Bóg odstąpił odemnie, i nie odpowiada mi więcej, ani przez proroki, ani przez sny; przetoż przyzwałem cię, abyś mi oznajmił, co mam czynić.
Samuẹli sì i wí fún Saulu pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń yọ mí lẹ́nu láti mú mi wá sókè?” Saulu sì dáhùn ó sì wí pé, “Ìpọ́njú ńlá bá mi; nítorí tí àwọn Filistini ń bá mi jagun, Ọlọ́run sì kọ̀ mí sílẹ̀, kò sì dá mi lóhùn mọ́, nípa ọwọ́ àwọn wòlíì, tàbí nípa àlá; nítorí náà ni èmi ṣe pè ọ́, kí ìwọ lè fi ohun tí èmi yóò ṣe hàn mi.”
16 I rzekł Samuel: Czemuż mię tedy pytasz, gdyż Pan odstąpił od ciebie, a przestawa z nieprzyjacielem twoim?
Samuẹli sì wí pé, “Ó ti ṣe ń bi mí léèrè nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, o sì di ọ̀tá rẹ̀.
17 I uczynił mu Pan, jakoć powiedział przez mię, i wyrwał Pan królestwo z rąk twoich, a dał je bliźniemu twemu Dawidowi.
Olúwa sì ṣe fún ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ti ipa ọwọ́ mi sọ: Olúwa sì yá ìjọba náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi fún aládùúgbò rẹ́, àní Dafidi.
18 Bo żeś ty nie był posłusznym głosowi Pańskiemu, aniś wykonał gniewu zapalczywości jego nad Amalekiem, przetożci to uczynił Pan dzisiaj.
Nítorí pé ìwọ kò gbọ́ ohùn Olúwa ìwọ kò sì ṣe iṣẹ́ ìbínú rẹ̀ sí Amaleki nítorí náà ni Olúwa sì ṣe nǹkan yìí sí ọ lónìí yìí.
19 Nadto poda Pan i Izraela z tobą w rękę Filistynów, a jutro ty i synowie twoi ze mną będziecie; obóz też Izraelski poda Pan w ręce Filistynów.
Olúwa yóò sì fi Israẹli pẹ̀lú ìwọ lé àwọn Filistini lọ́wọ́, ní ọ̀la ni ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò pẹ̀lú mi: Olúwa yóò sì fi ogun Israẹli lé àwọn Filistini lọ́wọ́.”
20 A natychmiast Saul upadł jako długi na ziemię, bo się zląkł bardzo słów Samuelowych, i siły nie było w nim, przeto że nic nie jadł przez cały dzień i przez całą noc.
Lójúkan náà ni Saulu ṣubú lulẹ̀ gbalaja níbí ó ṣe gùn tó, ẹ̀rù sì bà á gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ Samuẹli; agbára kò sí fún un; nítorí pé kò jẹun ní ọjọ́ náà tọ̀sán tòru.
21 Potem weszła niewiasta do Saula, a widząc, iż się bardzo przeląkł, rzekła mu: Oto, usłuchała służebnica twoja głosu twego, i odważyłam zdrowie swoje, i usłuchałam słów twoich, któreś mówił do mnie.
Obìnrin náà sì tọ Saulu wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mí mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.
22 Przetoż teraz usłuchaj proszę i ty głosu służebnicy twojej; a położę przed cię sztuczkę chleba, abyś jadł, i posilił się, abyś mógł iść w drogę.
Ǹjẹ́, nísinsin yìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ síwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”
23 Ale nie chciał, i mówił: Nie będę jadł. I przymusili go słudzy jego, także i niewiasta; i usłuchał głosu ich, a wstawszy z ziemi, usiadł na łóżku.
Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dìde kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lórí àkéte.
24 A ona niewiasta miała karmne cielę w domu, a pospieszywszy się, zabiła je; potem wziąwszy mąki zaczyniła, i napiekła z niej przaśników.
Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sanra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.
25 I przyniosła przed Saula, i przed sługi jego, którzy najadłszy się, wstali, i poszli onej nocy.
Ó sì mú un wá síwájú Saulu, àti síwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.

< I Samuela 28 >