< I Samuela 17 >

1 Tedy zebrali Filistynowie wojska swe, aby walczyli, a zeszli się u Sochot, które jest w Judzie, i położyli się obozem między Sochotem i między Asekiem na granicach Domim.
Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
2 A Saul i mężowie Izraelscy zebrali się, i położyli się obozem w dolinie Ela, i uszykowali wojsko przeciw Filistynom.
Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
3 A Filistynowie stali na górze z jednej strony, ale Izraelczycy stali na górze z drugiej strony; a dolina była między nimi.
Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
4 I wyszedł mąż między nie z obozu Filistyńskiego imieniem Golijat z Get, wzwyż na sześciu łokci i na piędzi.
Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
5 A przyłbica miedziana była na głowie jego, a w karacenę łuszczastą ubierał się, a waga karaceny pięć tysięcy syklów miedzi ważyła.
Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
6 Nadto nakolanki miedziane miał na nogach swoich, i tarcz miedzianą między ramionami swemi.
Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
7 A oszczepisko oszczepu jego jako nawój tkacki, a grot oszczepu jego miał sześć set syklów żelaza, a niosący tarcz jego szedł przed nim.
Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
8 I stanąwszy wołał do hufów Izraelskich, i mówił im: Nacoście wyciągnęli z wojskiem ku potykaniu? izażem ja nie jest Filistyńczyk, a wy słudzy Saulowi? Obieżcież między sobą męża, a niech mi się stawi.
Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
9 Będzieli się mógł potkać ze mną, a zabije mię, będziemy waszymi niewolnikami; lecz jeźli go ja przemogę, i zabiję go, wy będziecie naszymi niewolnikami, i służyć nam będziecie. Nadto rzekł Filistyńczyk:
Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
10 Jam dziś urągał hufom Izraelskim; dajcie mi męża, a niech czyni ze mną pojedynkiem.
Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
11 A usłyszawszy Saul i wszystek Izrael te słowa Filistyńczyka, ulękli się, i strwożyli się bardzo.
Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
12 (A Dawid był synem męża Efratejczyka z Betlehem Juda, którego imię Isaj, który miał ośm synów, a ten był za dni Saulowych stary i podeszły w leciech.
Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
13 I poszli trzej synowie Isajego starsi za Saulem na wojnę; a imiona trzech synów jego, którzy poszli na wojnę, są te: Elijab pierworodny, a wtóry po nim Abinadab, a trzeci Samma;
Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
14 Lecz Dawid był najmłodszy; a tak trzej najstarsi poszli byli za Saulem.)
Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
15 Dawid tedy odchodził i wracał się od Saula, aby pasł trzody ojca swego w Betlehem.
ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
16 Ale Filistyńczyk wychadzał wstawając rano i wieczór, i stawał przez czterdzieści dni.
Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
17 I rzekł Isaj do Dawida, syna swego: Weźmij teraz braciom swym to efa prażma, i dziesięcioro chleba tego, a bież do obozu do braci swych.
Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
18 A tych dziesięć młodych serów doniesiesz rotmistrzowi; a bracią swą nawiedziwszy dowiesz się, jako się mają, i zastawę ich wydźwigniesz.
Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
19 A Saul, i oni, i wszyscy synowie Izraelscy leżeli w dolinie Ela, walcząc przeciwko Filistynom.
Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
20 Wstawszy tedy Dawid rano na świtaniu, a poruczywszy trzodę stróżowi, wziął to na się, i szedł, jako mu był rozkazał Isaj, i przyszedł do obozu; a wojsko wyszło było do szyku, i okrzyk uczyniło ku potykaniu.
Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
21 A już byli uszykowali Izraelczycy i Filistynowie wojsko przeciwko wojsku.
Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
22 Przetoż zostawiwszy Dawid to, co przyniósł, i złożywszy to z siebie pod rękę stróża sprzętu żołnierskiego, bieżał do wojska, a przyszedłszy przywitał się z bracią swoją w pokoju.
Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
23 A gdy rozmawiał z nimi, oto mąż imieniem Golijat, Filistyńczyk z Get, występował między nie z wojska Filistyńskiego, i mówił oneż słowa, co słyszał i Dawid.
Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
24 A wszyscy synowie Izraelscy ujrzawszy onego męża, uciekali od oblicza jego, i bali się bardzo.
Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
25 I mówili mężowie Izraelscy: A widzieliżeście tego męża, który wyszedł? Bo wyszedł, aby urągał Izraelowi, ale ktoby go zabił, ubogaci go król bogactwy wielkiemi, i córkę mu swoję da, a dom ojca jego uczyni wolnym w Izraelu.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
26 Tedy Dawid rzekł do mężów, którzy z nim stali, mówiąc: Co dadzą mężowi, któryby zabił tego Filistyńczyka, a odjął pohańbienie od Izraela? Bo cóż to za Filistyńczyk nieobrzezany, że urąga wojskom Boga żyjącego?
Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
27 I powiedział mu lud oneż słowa, mówiąc: To dadzą mężowi, który go zabije.
Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
28 A gdy usłyszał Elijab, brat jego starszy, co mówił z onymi mężami, zapalił się gniewem Elijab na Dawida, i rzekł: Po coś tu przyszedł, a komuś poruczył onę trochę owiec na puszczy? znam ci ja pychę twoję, i złość serca twego, żeś przyszedł, abyś się przypatrywał bitwie.
Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
29 Tedy rzekł Dawid: Cóżem teraz uczynił? Wszakiem tu na rozkazanie przyszedł.
Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
30 I odwrócił się od niego ku drugiemu, i pytał się jako i przedtem; a odpowiedział mu lud tak jako i pierwej.
Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
31 I usłyszano słowa, które mówił Dawid, i opowiedziano je Saulowi, którego Saul wziął do siebie.
Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
32 I mówił Dawid do Saula: Niech niczyje serce nie upada dla tego; sługa twój pójdzie, a będzie się bił z tym Filistynem.
Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
33 Ale Saul rzekł do Dawida: Nie możesz ty iść przeciwko temu Filistynowi, abyś się z nim potykał, boś jest dzieciną, a on jest mężem walecznym od młodości swojej.
Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
34 I odpowiedział Dawid Saulowi: Pasał sługa twój trzodę ojca swego, a gdy przychodził lew, i niedźwiedź, a porywał barana z stada,
Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
35 Tedym go gonił, i biłem go, i wydzierałem z paszczęki jego; a gdy się rzucał na mię, ułapiwszy go za gardło jego, tłukłem go, i zabijałem go.
Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
36 I lwa i niedźwiedzia zabił sługa twój; tedyć też będzie i ten Filistyńczyk nieobrzezany, jako jeden z tych, gdyż urągał wojskom Boga żyjącego.
Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
37 Nadto rzekł Dawid: Pan, który mię wyrwał z mocy lwa, i z mocy niedźwiedzia, tenże mię wyrwie z rąk Filistyna tego. Tedy rzekł Saul do Dawida: Idź, a Pan niech będzie z tobą.
Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
38 I ubrał Saul Dawida w szaty swe, i włożył przyłbicę miedzianą na głowę jego, a oblukł go w pancerz.
Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
39 Przypasał też Dawid miecz jego na szaty swoje, i kosztował, jeźliby mógł chodzić (bo przedtem tego nie doświadczał). Tedy rzekł Dawid do Saula: Nie mogę w tem chodzić, bom temu nie przywykł. I złożył to Dawid z siebie.
Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
40 Ale wziął kij swój w rękę swoję, i obrał sobie pięć gładkich kamieni z potoku, i włożył je do naczynia pasterskiego, które miał, to jest do torby, a procę swoję niósł w rękach swoich, i przybliżył się ku Filistynowi.
Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
41 Szedł też Filistyńczyk, postępując i przybliżając się ku Dawidowi, i wyrostek, który niósł tarcz, przed nim.
Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
42 A gdy spojrzał Filistyńczyk i obaczył Dawida, lekce go sobie poważył, przeto, że był dzieciną, a lisowatym i pięknym na wejrzeniu.
Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
43 Rzekł tedy Filistyńczyk do Dawida: Izalim ja pies, iż ty idziesz na mię z kijem? I przeklinał Filistyńczyk Dawida przez bogi swoje.
Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
44 Nadto rzekł Filistyńczyk do Dawida: Pójdź do mnie, a dam ciało twoje ptastwu powietrznemu i bestyjom polnym.
Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
45 Tedy rzekł Dawid do Filistyna: Ty idziesz do mnie z mieczem i z oszczepem, i z tarczą, a ja idę do ciebie w imieniu Pana zastępów, Boga wojsk Izraelskich, któremuś urągał.
Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
46 Dziś cię poda Pan w ręce moje, a zabiję cię, i odejmę głowę twoję od ciebie, a dam trupy wojska Filistyńskiego ptastwu powietrznemu, i bestyjom ziemskim; a pozna wszystka ziemia, że jest Bóg w Izraelu;
Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
47 I dozna wszystko to zgromadzenie, że nie mieczem, ani oszczepem wybawia Pan, gdyż Pańska jest walka, a poda was w ręce nasze.
Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
48 I stało się, gdy powstał Filistyńczyk, i szedł, a przybliżał się przeciwko Dawidowi, że pospieszył i Dawid, a bieżał na spotkanie przeciwko Filistynowi:
Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
49 A ściągnąwszy Dawid rękę swą do torby, wyjął z niej kamień, i cisnął z procy, a ugodził Filistyńczyka w czoło jego, tak iż utknął kamień w czole jego, i padł twarzą swą na ziemię.
Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
50 A tak przemógł Dawid Filistyńczyka procą i kamieniem, a uderzywszy Filistyńczyka, zabił go, choć miecza nie miał Dawid w ręku.
Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
51 A przybieżawszy Dawid, stanął nad Filistyńczykiem, i wziął miecz jego, i dobył go z pochwy jego, i zabił go, i uciął nim głowę jego. A gdy ujrzeli Filistynowie, iż umarł mocarz ich, uciekli.
Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
52 Powstawszy tedy mężowie Izraelscy i Judzcy, okrzyk uczynili i gonili Filistyny, aż kędy chodzą do doliny, i aż do bram Akkaronu, i padali ranni Filistynowie po drodze Saraim aż do Get i aż do Akkaronu.
Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
53 A wróciwszy się synowie Izraelscy z pogoni Filistynów, rozchwycili obóz ich.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
54 Potem wziąwszy Dawid głowę onego Filistyńczyka, przyniósł ją do Jeruzalemu, a zbroję jego włożył do namiotu swego.
Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
55 A gdy widział Saul Dawida, wychodzącego przeciw Filistynowi, mówił do Abnera, hetmana wojska swego: Czyim jest synem ten młodzieniec? Abnerze! I odpowiedział Abner: Jako żywa dusza twoja, królu, żeć niewiem.
Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
56 Tedy rzekł król: Pytaj, czyim jest synem ten młodzieniec.
Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
57 A gdy się wracał Dawid, zabiwszy Filistyńczyka, tedy go wziął Abner, i przywiódł go przed Saula, a Dawid miał głowę Filistynowę w rękach swych.
Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
58 I rzekł do niego Saul: Czyjeś ty syn, młodzieńcze? I odpowiedział Dawid: Jestem syn sługi twego Isajego Betlehemczyka.
Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”

< I Samuela 17 >