< I Samuela 1 >
1 Był niektóry mąż z Ramataim Sofim, z góry Efraim, któremu było imię Elkana, syn Jerohama, syna Elihu, syna Tuhu, syna Suf, Efratejczyka.
Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
2 A ten miał dwie żony, imię jednaj Anna, a imię drugiej Fenenna; i miała Fenenna dziatki, ale Anna nie miała dziatek.
Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
3 I chadzał on mąż z miasta swego na każdy rok, aby chwałę dawał i ofiarował Panu zastępów w Sylo, gdzie byli dwaj synowie Heli, Ofni i Finees, kapłani Pańscy.
Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 A gdy przyszedł dzień, którego sprawował ofiary Elkana, dał Fenennie, żonie swej, i wszystkim synom jej, i córkom jej, cząstki;
Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 Ale Annie dał jednę część wyborną; bo Annę miłował, chociaż był Pan żywot jej zamknął.
Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 I draźniła ją bardzo przeciwnica jej, aby ją tylko rozgniewała, dla tego, iż zamknął był Pan żywot jej.
Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 To gdy czynił Elkana na każdy rok, a Anna też chodziła do domu Pańskiego, tak ją draźniła przeciwnica, że płakiwała i nie jadała.
Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 Rzekł jej tedy Elkana, mąż jej: Anno, czemu płaczesz i czemu nie jesz? a przecz się tak trapi serce twe? izalim ja tobie nie jest lepszy niż dziesięć synów?
Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
9 Wstała tedy Anna, gdy się najedli i napili w Sylo; a Heli kapłan siedział na stołku u podwoja kościoła Pańskiego.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
10 A ona będąc w gorzkości serca, modliła się Panu, i wielce płakała.
Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
11 I uczyniła ślub, mówiąc: Panie zastępów, jeźliż wejrzawszy wejrzysz na utrapienie służebnicy twojej, i wspomnisz na mię, a nie zabaczysz służebnicy twojej, i dasz służebnicy twojej potomstwo męskiej płci, tedy je dam Panu po wszystkie dni żywota jego, a brzytwa nie postoi na głowie jego.
Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
12 I stało się, gdy przedłużała modlitwy przed Panem, że Heli przypatrował się ustom jej.
Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
13 Ale Anna mówiła w sercu swem, tylko wargi jej ruchały się, ale głosu jej słychać nie było; i miał ją Heli za pijaną.
Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
14 Przetoż rzekł do niej Heli: Długoż będziesz pijaną? wytrzeźwij się z wina twego.
Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
15 Ale odpowiedziała Anna i rzekła: Nie tak, panie mój, niewiasta utrapionego ducha jestem, anim wina ani napoju mocnego nie piła, alem wylała duszę moję przed obliczem Pańskiem.
Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
16 Nie rozumiejże o służebnicy twojej, jako o niewieście niepobożnej, gdyż z wielkiego myślenia i frasunku mego mówiłam aż dotąd.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
17 Tedy odpowiedział Heli, i rzekł: Idźże w pokoju, a Bóg Izraelski niech ci da prośbę twoję, którejś żądała od niego.
Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
18 I rzekła: Niech znajdzie służebnica twoja łaskę przed oczyma twemi; i odeszła niewiasta w drogę swą, i jadła, a twarz jej nie była więcej smętna.
Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
19 I wstali bardzo rano, a pokłoniwszy się przed Panem, wrócili się, i przyszli do domu swego do Ramata. Tedy poznał Elkana Annę, żonę swą, a wspomniał na nię Pan.
Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
20 I stało się po wypełnieniu dni, jako poczęła Anna, że porodziła syna, i nazwała imię jego Samuel; bo rzekła: U Panam go uprosiła.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
21 Potem szedł on mąż Elkana, i wszystek dom jego, aby oddał Panu ofiarę uroczystą, i ślub swój.
Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
22 Ale Anna nie szła; bo mówiła mężowi swemu: Nie pójdę, aż zostawię dzieciątko, potem odwiodę je, że się ukaże przed Panem, i zostanie tam zawsze,
Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
23 I rzekł jej Elkana, mąż jej: Uczyń co jest dobrego w oczach twoich, zostań, aż go zostawisz; tylko niech utwierdzi Pan słowo swoje. Została tedy niewiasta, i karmiła piersiami syna swego, aż go zostawiła.
Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
24 A gdy go zostawiła, przywiodła go z sobą ze trzema cielcami, i z jednem efa mąki, i z łagwią wina, i przywiodła go do domu Pańskiego w Sylo; a dziecię było małe.
Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
25 I zabiwszy cielca, przywiedli dziecię do Heli.
Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
26 A ona rzekła: Słuchaj, panie mój! żywie dusza twoja, panie mój: Jam jest ona niewiasta, któram tu stała przy tobie, modląc się Panu.
Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
27 Prosiłam o to dzieciątko, i dał mi Pan prośbę moję, którejm żądała od niego.
Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
28 Przetoż je też ja oddawam Panu; na wszystkie dni, których będzie żyło, jest oddane Panu. I pokłonili się tam Panu.
Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.