< I Królewska 5 >

1 I posłał Hiram, król Tyrski, sługi swe do Salomona, bo usłyszał, że go pomazano za króla miasto ojca jego; albowiem miłował Hiram Dawida po wszystkie dni.
Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
2 Salomon też zaś posłał do Hirama, mówiąc:
Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
3 Ty wiesz, że Dawid, ojciec mój, nie mógł budować domu imieniowi Pana, Boga swego, dla wojen, które go były ogarnęły, aż nieprzyjacioły podał Pan pod stopy nóg jego;
“Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
4 Ale teraz Pan, Bóg mój, dał mi odpoczynienie zewsząd, i niemam żadnego przeciwnika, ani zabiegu złego.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
5 A otom umyślił budować dom imieniowi Pana, Boga mego, jako powiedział Pan do Dawida, ojca mego, mówiąc: Syn twój, któremu dam miasto ciebie osiąść stolicę twoję, ten zbuduje dom ten imieniowi memu.
Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
6 Przetoż teraz rozkaż, aby mi narąbano ceder na Libanie, a słudzy moi będą z sługami twoimi, a zapłatę sług twoich dam tobie tak, jako rzeczesz; albowiem ty wiesz, że niemasz między nami męża, któryby umiał tak rąbać drzewo, jako Sydończycy.
“Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
7 A gdy usłyszał Hiram słowa Salomonowe, uradował się bardzo i rzekł: Błogosławiony Pan dzisiaj, który dał Dawidowi syna mądrego nad tym ludem wielkim.
Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
8 I posłał Hiram do Salomona, mówiąc: Słyszałem z czemeś posłał do mnie. Uczynię wszystkę wolą twoję około drzewa cedrowego, i około drzewa jodłowego.
Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
9 Słudzy moi zwiozą je z Libanu do morza, a ja je każę złożyć w tratwy, i spuścić morzem aż do miejsca, o którem mi dasz znać, i tam je rozwiążę, a ty je pobierzesz. Ty też uczynisz wolą moję, a dasz obrok czeladzi mojej.
Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
10 A tak Hiram dodawał Salomonowi drzewa cedrowego, i drzewa jodłowego, jako wiele chciał.
Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
11 Salomon także dawał Hiramowi dwadzieścia tysięcy miar pszenicy na żywność czeladzi jego, i dwadzieścia tysięcy miar oliwy wybijanej; to dawał Salomon Hiramowi na każdy rok.
Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
12 A Pan dał mądrość Salomonowi, jako mu był obiecał, i był pokój między Hiramem i między Salomonem, a uczynili przymierze między sobą.
Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
13 Tedy kazał wybierać król Salomon robotniki ze wszystkiego Izraela, a było wybranych trzydzieści tysięcy mężów.
Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
14 Które słał do Libanu po dziesięć tysięcy na każdy miesiąc, na przemiany; po miesiącu mieszkali na Libanie, a po dwa miesiące w domu swym; a Adoniram był przełożony nad tymi wybranymi.
Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
15 Miał też Salomon siedmdziesiąt tysięcy tych, którzy nosili ciężary, a ośmdziesiąt tysięcy tych, którzy rąbali na górze;
Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
16 Oprócz przedniejszych urzędników Salomonowych, których było nad robotą trzy tysiące i trzy sta, którzy byli przełożeni nad ludem odprawującym robotę.
àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
17 Rozkazał też król, aby wożono kamienie wielkie, kamienie drogie, i kamienie ciosane, na założenie gruntów domu.
Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
18 Ciosali tedy rzemieślnicy Salomonowi, i rzemieślnicy Hiramowi, i Gimblimczycy. A tak gotowali drzewo i kamienie na budowanie domu.
Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.

< I Królewska 5 >