< I Królewska 4 >

1 A tak król Salomon był królem nad wszystkim Izraelem.
Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
2 A teć są książęta, które miał: Azaryjasz, syn Sadoka kapłana.
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
3 Elichoref i Achija, synowie Sysy, byli pisarzami; Jozafat, syn Ahiluda, kanclerzem;
Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
4 A Banajas, syn Jojady, był hetmanem; Sadok zaś i Abijatar kapłanami.
Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
5 A Azaryjasz, syn Natana, nad urzędnikami, a Zabud, syn Natana, był książęciem, przyjacielem królewskim.
Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
6 Ahisar zaś był przełożony nad domem, a Adoniram, syn Abdy, nad wybranym ludem.
Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
7 Miał też Salomon dwanaście przełożonych nad wszystkim Izraelem, którzy dodawali żywności królowi i domowi jego. Każdy z nich przez jeden miesiąc w roku królowi żywności dodawał.
Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
8 A teć są imiona ich: Syn Hura na górze Efraim;
Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
9 Syn Dekara w Makas, i w Salbim, i w Betsames, i w Elon i Bethanan;
Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
10 Syn Heseda w Arubot, który trzymał Socho i wszystkę ziemię Chefer;
Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
11 Syn Abinadaba, który trzymał wszystkie granice Dor, a Tafet, córkę Salomonową, miał za żonę.
Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
12 Baana, syn Ahiluda, który trzymał Tanach i Magieddo, i wszystko Betsan, które jest podle Sartany pod Jezreelem, od Betsan aż do Abelmehola, aż za Jekmaam.
Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
13 Syn Gaber w Ramot Galaadskiem, który trzymał wsi Jaira, syna Manasesowego, które leżą w Galaad. Jemu też należała kraina Argob, która jest w Basan, sześćdziesiąt miast wielkich murowanych z zaworami miedzianemi.
Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
14 Achinadab, syn Iddona, w Mahanaim.
Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
15 Achimaas w Neftalim, który też pojął Basematę, córkę Salomonową, za żonę.
Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
16 Baana, syn Husai, w Aser i w Alot.
Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
17 Jozafat, syn Paruacha, w Isaschar.
Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
18 Semej, syn Eli, w Benjamin.
Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
19 Gaber, syn Ury, w ziemi Galaad i w ziemi Sehona króla Amorejskiego, i Oga króla Basańskiego; a ten sam był rządcą onej ziemi.
Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
20 Tedy Juda i Izrael będąc niezliczeni jako piasek, który jest nad morzem w mnóstwie, jedli, i pili, i weselili się.
Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
21 A Salomon panował nad wszystkiemi królestwy od rzeki aż do ziemi Filistyńskiej, i aż do granicy Egipskiej. I przynosili dary, a służyli Salomonowi po wszystkie dni żywota jego.
Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
22 A tenci był rozchód Salomona na każdy dzień, trzydzieści korcy mąki białej, i sześćdziesiąt korcy innej mąki.
Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
23 Dziesięć wołów karmnych, i dwadzieścia wołów pastewnych, i sto owiec, oprócz jeleni i sarn, i bawołów, i ptastwa karmnego.
Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
24 Albowiem on panował wszędy z tej strony rzeki od Tasfa aż do Gazy nad wszystkimi królmi, którzy byli przed rzeką, a miał pokój ze wszystkich stron w około.
Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
25 I mieszkał Juda i Izrael bezpiecznie, każdy pod winną macicą swoją, i pod figą swoją, od Dan aż do Beerseba, po wszystkie dni Salomonowe.
Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
26 Miał też Salomon czterdzieści tysięcy koni na staniu do wozów swoich, a dwanaście tysięcy jezdnych.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
27 A tak podejmowali oni przełożeni króla Salomona, i wszystkie, którzy przychodzili do stołu króla Salomona, każdy miesiąca swego, nie dopuszczając, aby na czem schodzić miało.
Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
28 Jęczmień także, i plewy dla koni i mułów, zwozili na to miejsce, gdzie był król, każdy według tego, jako mu postanowiono.
Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
29 Nadto dał Bóg Salomonowi mądrość i roztropność bardzo wielką, a przestronność serca, jako piasek, który jest na brzegu morskim.
Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
30 Albowiem większa była mądrość Salomonowa, niżli mądrość wszystkich narodów wschodnich, i niżli wszelka mądrość Egipczanów.
Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
31 Owszem mędrszym był nad wszystkie ludzie, aż i nad Etana Ezrahytę, i nad Hemana, i Chalkola, i Darda, syny Maholowe; a był sławny u wszystkich narodów okolicznych.
Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
32 Nadto złożył trzy tysiące przypowieści, a pieśni jego było tysiąc i pięć.
Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
33 Rozprawiał też o drzewach, począwszy od cedru, który jest na Libanie, aż do hizopu, który wyrasta z ściany. Mówił też o zwierzętach i o ptakach, i o gadzinach, i o rybach.
Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
34 Przetoż przychodzili ze wszystkich narodów słuchać mądrości Salomonowej, i od wszystkich królów ziemi, którzy słyszeli o mądrości jego.
Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.

< I Królewska 4 >