< I Królewska 18 >

1 Potem po wielu dniach, mianowicie po onym roku trzecim, stało się słowo Pańskie do Elijasza, mówiąc: Idź, ukaż się Achabowi; bo spuszczę deszcz na ziemię.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
2 Szedł tedy Elijasz, aby się ukazał Achabowi; a był głód gwałtowny w Samaryi.
Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
3 I zawołał Achab Abdyjasza, który był sprawcą domu jego. (A Abdyjasz się bardzo Pana bał;
Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
4 Bo gdy mordowała Jezabel proroki Pańskie, tedy wziął Abdyjasz sto proroków, i skrył ich po pięćdziesiąt do jaskini, i żywił je chlebem i wodą.)
Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
5 I rzekł Achab do Abdyjasza: Idź przez ziemię do wszystkich źródeł wód, i do wszystkich potoków, aza gdzie znajdziemy trawę, żebyśmy żywo zachowali konie i muły, i żebyśmy nie zgubili bydła.
Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
6 I rozdzielili sobie ziemię, którą przejść mieli. Achab sam szedł jedną drogą, Abdyjasz też szedł drugą drogą osobno.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
7 A gdy Abdyjasz był w drodze, oto się z nim Elijasz spotkał, który gdy go poznał, upadł na oblicze swoje, i rzekł: A tyżeś jest pan mój Elijasz?
Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
8 I odpowiedział mu: Jam jest. Idź, powiedz panu twemu: Oto Elijasz tu jest.
Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
9 Do którego on rzekł: Cóżem zgrzeszył, iż wydawasz sługę twego w ręce Achabowe, aby mię zabił?
Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
10 Jako żywy Pan, Bóg twój, że niemasz narodu, i królestwa, gdzieby nie posłał Pan mój, aby cię szukano; a gdy powiedziano, iż cię niemasz, tedy obowiązał przysięgą królestwa i narody, jako cię znaleść nie mogą.
Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
11 A ty mi teraz mówisz: Idź, a powiedz panu twemu: Oto Elijasz.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
12 I stałoby się, gdybym ja odszedł od ciebie, żeby cię Duch Pański zaniósł, gdziebym nie wiedział; a ja szedłszy opowiedziałbym Achabowi, a gdyby cię nie znalazł, zabiłby mię; a sługa twój boi się Pana od dzieciństwa swego.
Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
13 Azaż nie powiedziano panu memu, com uczynił, gdy mordowała Jezabel proroki Pańskie? żem skrył z proroków Pańskich sto mężów, po pięćdziesiąt mężów w jaskini, i żywiłem je chlebem i wodą?
Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
14 A ty teraz mówisz: Idź, powiedz panu twemu: Oto Elijasz; i zabije mię.
Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
15 I odpowiedział Elijasz: Jako żywy Pan zastępów, przed którego oblicznością stoję, że mu się dziś ukażę.
Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
16 A tak szedł Abdyjasz przeciw Achabowi, i oznajmił mu to. Przetoż szedł Achab przeciw Elijaszowi.
Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
17 A ujrzawszy Achab Elijasza, rzekł Achab do niego: Azaż nie ty jesteś, który czynisz zamięszanie w Izraelu?
Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
18 Na co mu odpowiedział: Nie jać czynię zamięszanie w Izraelu, ale ty i dom ojca twego, gdyż opuściwszy rozkazania Pańskie naśladujecie Baalów.
Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
19 Przetoż teraz poślij, a zbierz do mnie wszystkiego Izraela na górę Karmel, i proroków Baalowych cztery sta i pięćdziesiąt, przytem proroków gajowych cztery sta, którzy jadają z stołu Jezabeli.
Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
20 Posłał tedy Achab do wszystkich synów Izraelskich, i zebrał te proroki na górę Karmel.
Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
21 A przystąpiwszy Elijasz do wszystkiego ludu, rzekł: I długoż będziecie chramać na obie strony? Jeźli Pan jest Bogiem, idźcież za nim; a jeźli Baal, idźcież za nim. I nie odpowiedział mu lud i słowa.
Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
22 Tedy rzekł Elijasz do ludu: Jam tylko sam został prorok Pański; a proroków Baalowych cztery sta i pięćdziesiąt mężów.
Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
23 Niech nam dadzą dwóch cielców, a niech sobie obiorą cielca jednego, a porąbią go na sztuki, i włożą na drwa; ale ognia niech nie podkładają: ja też przygotuję drugiego cielca, którego włożę na drwa, a ognia nie podłożę.
Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
24 Potem wzywajcie imienia bogów waszych, a ja będę wzywał imienia Pańskiego, a Bóg, który się ozwie przez ogień, ten niech będzie Bogiem. Na co odpowiadając wszystek lud rzekł: Dobrześ powiedział.
Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
25 I rzekł Elijasz do proroków Baalowych: Obierzcie sobie cielca jednego, a zgotujcie go pierwej, bo was jest więcej; wzywajcież imienia bogów waszych, ale ognia nie podkładajcie.
Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
26 A tak wzięli cielca, którego im dał, a zgotowawszy wzywali imienia Baalowego od poranku aż do południa, mówiąc: O Baalu, wysłuchaj nas! Ale nie było głosu, ani ktoby odpowiedział. I skakali koło ołtarza, który byli uczynili.
Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
27 A gdy było południe, naśmiewał się z nich Elijasz, mówiąc: Wołajcie większym głosem, ponieważ jest bóg; tylko że się albo zamyślił, albo jest zabawny, albo też jest w drodze; albo też śpi, aza ocuci.
Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
28 A tak wołali głosem wielkim, i rzezali się według zwyczaju swego nożami i włóczenkami, aż się krwią oblewali.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
29 I stało się, gdy minęło południe, że prorokowali aż do czasu ofiarowania ofiary śniednej; ale nie było głosu, ani ktoby odpowiedział, ani ktoby wysłuchał.
Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
30 Zatem rzekł Elijasz do wszystkiego ludu: Przystąpcie do mnie. I przystąpił wszystek lud do niego. Tedy naprawił ołtarz Pański, który był rozwalony.
Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
31 Albowiem wziął Elijasz dwanaście kamieni; (według liczby pokolenia synów Jakóbowych, do którego się stało słowo Pańskie, mówiąc: Izrael będzie imię twoje.)
Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
32 I zbudował z tego kamienia ołtarz w imię Pańskie, a uczynił około ołtarza szeroki rów, coby mógł dwie miary zboża wysiać.
Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
33 Potem ułożył drwa, i na sztuki porąbał cielca, i kładł go na drwa.
Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
34 I rzekł: Napełnijcie cztery wiadra wodą, a wylijcie na całopalenie i na drwa. Rzekł nadto: Powtórzcie, i powtórzyli; rzekł jeszcze: Uczyńcie po trzecie, i uczynili po trzecie,
Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
35 Tak że płynęły wody około ołtarza, aż i rów był napełniony wodą.
Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
36 I stało się, gdy był czas sprawowania ofiary śniednej, przystąpił Elijasz prorok, i rzekł: Panie, Boże Abrahama, Izaaka, i Izraela! dziś niech poznają, żeś ty jest Bogiem w Izraelu, a jam sługa twój, a żem według słowa twego uczynił to wszystko.
Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
37 Wysłuchaj mię Panie, wysłuchaj mię, aby poznał ten lud, żeś ty Panie jest Bogiem, gdybyś zaś nawrócił serca ich.
Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
38 Tedy spadł ogień Pański, i pożarł całopalenie, i drwa, i kamienie, i proch; a wodę, która była w rowie, wysuszył.
Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
39 Co gdy ujrzał wszystek lud, upadli na oblicze swe, i rzekli: Pan jest Bogiem, Panci jest Bogiem.
Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
40 Tedy rzekł Elijasz do nich: Pojmajcie proroki Baalowe, a żaden niech z nich nie uchodzi. I pojmano je. A tak odwiódł je Elijasz do potoku Cyson, i tamże je pobił.
Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
41 Potem rzekł Elijasz do Achaba: Idź, jedz, a pij; albowiem oto szum dżdżu wielkiego.
Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
42 Tedy szedł Achab, aby jadł i pił; a Elijasz wstąpił na wierzch Karmelu, i położył się na ziemię, a włożył twarz swoję między kolana swoje.
Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
43 Potem rzekł do sługi swego: Idź teraz, a spojrzyj ku morzu. Który poszedł, a spojrzawszy rzekł: Niemasz nic. Zasię rzekł: Idź, a wracaj się po siedm kroć.
Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
44 A za siódmym razem rzekł: Oto obłok mały jako dłoń człowiecza występuje z morza. Tedy on rzekł: Idź, a powiedz Achabowi: Zaprzęgaj, a ujeżdżaj, aby cię deszcz nie zastał.
Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
45 I stało się między tem, że się niebiosa obłokami i wiatrem zaćmiły, skąd był deszcz wielki. A tak wsiadłszy Achab, jechał do Jezreela.
Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
46 A ręka Pańska była nad Elijaszem; i przepasał biodra swe, i bieżał przed Achabem, aż przyszedł do Jezreela.
Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.

< I Królewska 18 >