< I Królewska 17 >

1 Tedy rzekł Elijasz Tesbita, jeden z obywateli Galaadu, do Achaba: Jako żywy Pan, Bóg Izraelski, przed którego oblicznością stoję, że nie będzie tych lat rosy, ani deszczu, jedno według słów ust moich.
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 I stało się słowo Pańskie do niego, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 Odejdź stąd, a obróć się na wschód słońca, i skryj się u potoku Charyt, który jest przeciwko Jordanowi.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 I będziesz pił z potoku: a rozkazałem krukom, aby cię tam żywili.
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 I poszedł, a uczynił według słowa Pańskiego, i przyszedłszy usiadł u potoku Charyt, który był przeciwko Jordanowi.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 A kruki przynosiły mu chleb i mięso rano, także chleb i mięso w wieczór; a pił z potoku.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Lecz po wyjściu niektórych dni wysechł on potok; bo nie padał deszcz na ziemię.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 I stało się słowo Pańskie do niego, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 Wstań, idź do Sarepty Sydońskiej, i mieszkaj tam; otom tam rozkazał niewieście wdowie, aby cię żywiła.
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Tedy on wstawszy szedł do Sarepty, i przyszedł do bramy miasta, a oto tam niewiasta wdowa zbierała drwa; który zawoławszy jej, rzekł: Przynieś mi proszę trochę wody w naczyniu, abym się napił.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 A gdy ona szła, aby przyniosła, tedy na nię zawołał, i rzekł: Przynieś mi też proszę sztuczkę chleba w ręce twojej.
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 I odpowiedziała: Jako żywy Pan, Bóg twój, żeć niemam pieczonego chleba, oprócz z garść pełną mąki w garncu, a trochę oliwy w bańce; a oto zbieram trochę drewek, abym szła, i zgotowała to sobie i synowi swemu, a zjadłszy to, abyśmy pomarli.
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Tedy rzekł do niej Elijasz: Nie bój się. Idź, uczyń jakoś rzekła: wszakże uczyń mi z tego pierwej podpłomyk mały, i przynieś mi; potem też sobie i synowi swemu uczynisz.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Albowiem tak powiedział Pan, Bóg Izraelski: Mąka z garnca tego nie będzie strawiona, ani oliwy z tej bańki ubędzie, aż do dnia, gdy Pan spuści deszcz na ziemię.
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 I poszła, a uczyniła podług słowa Elijaszowego, i jadła ona i on, i wszystka czeladź jej, aż się wypełniły te dni.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Nie była strawiona mąka z onego garnca, ani oliwy z bańki ubyło, według słowa Pańskiego, które powiedział przez Elijasza.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 I stało się potem, że się rozniemógł syn onej niewiasty, pani domu onego, a była niemoc jego bardzo ciężka, tak, że w nim tchu nie zostało.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Przetoż rzekła do Elijasza: Cóż mnie i tobie, mężu Boży? przyszedłeś do mnie, abyś przywiódłszy na pamięć nieprawość moję, umorzył syna mego?
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 I rzekł do niej: Daj mi syna twego; i wziąwszy go z łona jej, wniósł go na salę, na której mieszkał, i położył go na łożu swojem.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 I wołał do Pana, a rzekł: Panie, Boże mój, izali też utrapisz wdowę, u której mieszkam, iżeś zabił syna jej?
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 A rozciągnąwszy się nad dziecięciem po trzy kroć, wołał do Pana, mówiąc: Panie, Boże mój, niechaj się proszę wróci dusza dzieciątka tego w ciało jego.
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 I wysłuchał Pan głos Elijaszowy: i wróciła się dusza dziecięcia w ciało jego, i ożyło.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Tedy wziął Elijasz dziecię, i zniósł je z sali do domu, a oddał go matce jego, i rzekł Elijasz: Wej, syn twój żyje.
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 I rzekła niewiasta do Elijasza: Terazem poznała, iżeś jest mąż Boży, a słowo Pańskie w uściech twoich jest prawda.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”

< I Królewska 17 >