< I Królewska 16 >
1 I stało się słowo Pańskie do Jehu, syna Hananijego, przeciw Baazie, mówiące:
Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
2 Dla tego żem cię wydźwignął z prochu, a postanowiłem cię wodzem nad ludem moim Izraelskim, a tyś chodził drogami Jeroboamowemi, i przywiodłeś do grzechu lud mój Izraelski, pobudzając mię ku gniewu grzechami ich:
“Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
3 Otoż ja wygładzę potomki Baazy, i potomki domu jego, a uczynię dom twój, jako dom Jeroboama, syna Nabatowego.
Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
4 Tego, który z rodu Baazy umrze w mieście, zjedzą psy, a tego, który umrze na polu, zjedzą ptaki powietrzne.
Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
5 A inne sprawy Baazy, i co czynił, i moc jego, azaż to nie jest napisano w kronikach królów Izraelskich?
Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
6 A gdy zasnął Baaza z ojcy swymi, pochowany jest w Tersie, i królował Ela, syn jego, miasto niego.
Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
7 A tak przez proroka Jehu, syna Hananijego, stało się słowo Pańskie przeciw Baazie i przeciw domowi jego, i przeciw wszystkiemu złemu, które czynił przed obliczem Pańskiem, wzruszając go ku gniewu sprawami rąk swoich, że ma być podobnym domowi Jeroboamowemu, i dla tego, że go zabił.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
8 Roku dwudziestego i szóstego Azy, króla Judzkiego, królował Ela, syn Baazy, nad Izraelem w Tersie dwa lata.
Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
9 I sprzysiągł się przeciw niemu sługa jego Zymry, hetman nad połową wozów, gdy Ela w Tersie pijąc pijany był w domu Arsy, który był sprawcą domu królewskiego w Tersie.
Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
10 Wtem przypadł Zymry i ranił go, i zabił go roku dwudziestego i siódmego Azy, króla Judzkiego, a królował miasto niego.
Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
11 A gdy już królował i siedział na stolicy jego, wymordował wszystek dom Baazy, i powinne jego, i przyjacioły jego; nie zostawił z niego i szczeniątka.
Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
12 A tak wygładził Zymry wszystek dom Baazy według słowa Pańskiego, które powiedział o Baazie przez proroka Jehu.
Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
13 Dla wszystkich grzechów Baazy, i grzechów Eli, syna jego, którzy grzeszyli, i którzy przywiedli do grzechu Izraela, wzruszając ku gniewu Pana, Boga Izraelskiego, próżnościami swemi.
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
14 Ale inne sprawy Eli, i wszystko co czynił, izali nie napisane w kronikach o królach Izraelskich?
Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
15 Roku dwudziestego i siódmego Azy, króla Judzkiego, królował Zymry siedm dni w Tersie, gdy lud obozem leżał u Giebbeton, które jest Filistyńskie.
Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
16 A gdy usłyszał lud leżący w obozie takową rzecz, iż Zymry sprzysiągłszy się zabił króla: tedy wszystek Izrael postanowili królem Amrego, który był hetmanem na wojskiem Izraelskiem onegoż dnia w obozie.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
17 Przetoż odciągnął Amry i wszystek Izrael z nim od Giebbeton, a oblegli Tersę.
Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
18 A gdy obaczył Zymry, iż wzięto miasto, wszedł na pałac domu królewskiego, i spalił się ogniem z domem królewskim, i umarł.
Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
19 A to się stało dla grzechów jego, których się dopuścił, czyniąc złe przed obliczem Pańskiem, a chodząc drogą Jeroboama, i w grzechach jego, których się dopuszczał, do grzechu przywodząc Izraela.
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
20 A inne sprawy Zymry i sprzysiężenie jego, które uczynił, azaż nie jest napisane w kronikach o królach Izraelskich?
Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
21 Tedy się rozerwał lud Izraelski na dwie części; połowa ludu szła za Tebni, synem Ginetowym, aby go uczynili królem, a połowa szła za Amrym.
Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
22 Ale przemógł lud, który przestawał z Amrym, on lud, który zostawał przy Tebni, synem Ginetowym; i umarł Tebni, a królował Amry.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
23 Roku trzydziestego i pierwszego Azy, króla Judzkiego, królował Amry nad Izraelem dwanaście lat; w Tersie królował sześć lat.
Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
24 I kupił górę Samaryi od Semera za dwa talenty srebra, i pobudował na onej górze, a nazwał imię miasta, które zbudował imieniem Semera, pana góry onej, Samaryi.
Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
25 Ale czynił Amry złe przed oczyma Pańskiemi, a dopuszczał się rzeczy gorszych, niżeli wszyscy, którzy przed nim byli.
Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
26 Albowiem chodził wszystkiemi drogami Jeroboama, syna Nabatowego, i w grzechu jego, którym przywiódł w grzechy Izraela, wzruszając ku gniewu Pana Boga Izraelskiego, próżnościami swemi.
Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
27 A inne sprawy Amrego, i wszystko, co czynił, i moc jego, którą pokazywał, azaż to nie jest napisane w kronikach o królach Izraelskich?
Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
28 I zasnął Amry z ojcy swymi, a pochowany jest w Samaryi; i królował Achab, syn jego, miasto niego.
Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 Achab tedy, syn Amrego, królować począł nad Izraelem roku trzydziestego i ósmego Azy, króla Judzkiego, a królował Achab, syn Amrego, nad Izraelem w Samaryi dwadzieścia i dwa lat.
Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
30 I czynił Achab, syn Amrego, złe przed oczyma Pańskiemi nad wszystkie, którzy byli przed nim.
Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
31 I stało się, nie mając na tem dosyć, iż chodził w grzechach Jeroboama, syna Nabatowego, że sobie wziął za żonę Jezabelę, córkę Etbaala, króla Sydońskiego, a szedłszy służył Baalowi, i kłaniał mu się.
Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
32 I wystawił ołtarz Baalowi w domu Baalowym, który był zbudował w Samaryi.
Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
33 Do tego nasadził Achab gaj, a tem więcej wzruszył ku gniewu Pana, Boga Izraelskiego, nad wszystkie króle Izraelskie, którzy byli przed nim.
Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
34 Za dni jego zbudował Hijel, Betelczyk, miasto Jerycho. Na Abiramie, pierworodnym swoim, założył je, a na Segubie najmłodszym synu swym, wystawił bramy jego, według słowa Pańskiego, które powiedział przez Jozuego, syna Nunowego.
Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.