< I Królewska 15 >

1 Roku tedy ośmnastego królowania Jeroboama, syna Nabatowego, królował Abijam nad Judą.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
2 Trzy lata królował w Jeruzalemie; a imię matki jego było Maacha, córka Abisalomowa.
ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
3 Ten chodził we wszystkich grzechach ojca swego, które czynił przed nim; a nie było serce jego doskonałe przy Panu, Bogu swoim, jako serce Dawida, ojca jego.
Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
4 Wszakże dla Dawida dał mu Pan, Bóg jego, pochodnią w Jeruzalemie, wzbudziwszy syna jego po nim, a utwierdziwszy Jeruzalem,
Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
5 Przeto, że czynił Dawid, co było dobrego w oczach Pańskich, a nie uchylał się od wszystkiego, co mu rozkazał, po wszystkie dni żywota swego, oprócz sprawy z Uryjaszem Hetejczykiem.
Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
6 I była wojna między Roboamem, i między Jeroboamem po wszystkie dni żywota jego.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
7 A insze sprawy Abijamowe, i wszystko, co czynił, azaż nie jest napisane w kronikach o królach Judzkich, jako i wojna między Abijamem i między Jeroboamem?
Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
8 A gdy zasnął Abijam z ojcy swymi, pochowano go w mieście Dawidowem. I królował Aza, syn jego, miasto niego.
Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
9 A tak roku dwudziestego Jeroboama, króla Izraelskiego, królował Aza nad Judą.
Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
10 Czterdzieści lat i jeden królował w Jeruzalemie, a imię matki jego było Maacha, córka Abisalomowa.
Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
11 I czynił Aza, co dobrego było w oczach Pańskich, jako Dawid ojciec jego.
Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
12 Albowiem wytracił Sodomczyki z ziemi, i wyrzucił wszystkie bałwany, których byli naczynili ojcowie jego.
Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
13 Nadto i Maachę, matkę swoję, zrzucił z panowania, bo była sprawiła strasznego bałwana w gaju; przetoż porąbał Aza tego strasznego bałwana jej, i spalił u potoku Cedron.
Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
14 A chociaż wyżyny nie były skażone, jednak serce Azy było doskonałe przy Panu po wszystkie dni jego.
Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
15 I wniósł rzeczy poświęcone ojca swego, i rzeczy, które sam poświęcił, do domu Pańskiego, srebro, i złoto, i naczynia.
Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
16 I była wojna między Azą i między Baazą, królem Izraelskim, po wszystkie dni ich.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
17 Albowiem Baaza, król Izraelski, wyciągnął przeciw Judzie, a zbudował Ramę, aby nie dopuścił wychodzić i wchodzić nikomu do Azy, króla Judzkiego.
Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
18 Ale wziąwszy Aza wszystko srebro i złoto, które było pozostało w skarbiech domu Pańskiego, i w skarbiech domu królewskiego, dał je w ręce sługom swoim; i posłał je król Aza do Benadada, syna Tabremonowego, syna Hezyjonowego, króla Syryjskiego, który mieszkał w Damaszku, mówiąc:
Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
19 Przymierze jest między mną i między tobą, między ojcem moim i między ojcem twoim; otoć posyłam dary, srebro i złoto; idźże, wzrusz przymierze twoje z Baazą, królem Izraelskim, aby odciągnął odemnie.
Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
20 I usłuchał Benadad króla Azy; a posławszy hetmany z wojski, które miał przeciw miastom Izraelskim, zburzył Hijon i Dan i Abelbetmaachę, i wszystko Cynnerot, i wszystkę ziemię Neftalim.
Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
21 Co gdy usłyszał Baaza, przestał budować Ramy, i mieszkał w Tersie.
Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
22 Tedy król Aza zebrał wszystek lud Judzki, nikogo nie wyjmując; a pobrali kamienie z Ramy i drzewo jego, z którego budował Baaza: a zbudował z niego król Aza Gabaa Benjaminowe, i Masfa.
Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
23 A inne wszystkie sprawy Azy, i wszystka moc jego, i cokolwiek czynił, i miasta, które zbudował, azaż to nie jest napisane w kronikach o królach Judzkich? Ale czasu starości swej chorował na nogi swoje.
Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
24 I zasnął Aza z ojcy swymi, a pochowany jest z nimi w mieście Dawida, ojca swego. A Jozafat, syn jego, królował miasto niego.
Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
25 Ale Nadab, syn Jeroboama, nastąpił na królestwo Izraelskie roku wtórego Azy, króla Judzkiego, i królował nad Izraelem dwa lata;
Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
26 I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, chodząc drogami ojca swego, i w grzechach jego, któremi do grzechu przywodził Izraela.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
27 I zbuntował się przeciw niemu Baaza, syn Ahyjasza, z domu Isaschar; a poraził go Baaza u Giebbeton, które było Filistyńskie; bo Nadab ze wszystkim Izraelem obległ był Giebbeton.
Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
28 I zabił go Baaza roku trzeciego Azy, króla Judzkiego, a sam królował miasto niego.
Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
29 I stało się, gdy począł królować, że wymordował wszystek dom Jeroboamowy; a nie zostawił żadnej duszy z narodu Jeroboamowego, aż je wytracił według słowa Pańskiego, które był opowiedział przez sługę swego Achyjasza Sylonitczyka;
Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
30 A to dla grzechów Jeroboamowych, który grzeszył, i który do grzechu przywiódł Izraelczyki, i dla przestępstwa, którem wzruszył ku gniewu Pana, Boga Izraelskiego.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
31 A inne sprawy Nadabowe, i wszystko co czynił, azaż to nie jest napisane w kronikach królów Izraelskich?
Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
32 I była wojna między Azą, i między Baazą, królem Izraelskim, po wszystkie dni ich.
Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
33 Roku trzeciego Azy, króla Judzkiego, królował Baaza, syn Achyjasza, nad wszystkim Izraelem w Tersie przez dwadzieścia i cztery lat.
Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
34 I czynił złe przed Panem, chodząc drogami Jeroboamowemi, i w grzechu jego, którym do grzechu przywiódł Izraelity.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.

< I Królewska 15 >