< I Królewska 13 >
1 A oto mąż Boży przyszedł z Judztwa z słowem Pańskiem do Betel, gdy Jeroboam stał u ołtarza, aby kadził.
Sì kíyèsi i, ènìyàn Ọlọ́run kan wá láti Juda sí Beteli nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, bì Jeroboamu sì ti dúró lẹ́bàá a pẹpẹ láti fi tùràrí jóná.
2 I zawołał przeciw ołtarzowi słowem Pańskiem, i rzekł: Ołtarzu, ołtarzu, tak mówi Pan: Oto syn narodzi się domowi Dawidowemu imieniem Jozyjasz, który będzie ofiarował na tobie kapłany wyżyn, kadzące na tobie, i kości ludzkie popalą na tobie.
Ó sì kígbe sí pẹpẹ náà nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, “Pẹpẹ! Pẹpẹ! Báyìí ni Olúwa wí: ‘A ó bí ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Josiah ní ilé Dafidi. Lórí rẹ ni yóò sì fi àwọn àlùfáà ibi gíga wọ̀n-ọn-nì tí ń fi tùràrí lórí rẹ̀ rú ẹbọ, a ó sì sun egungun ènìyàn lórí rẹ.’”
3 I dał mu znak dnia onegoż, mówiąc: Tenci jest znak, że to mówił Pan: Oto się ołtarz rozpadnie, a wysypie się popiół, który jest na nim.
Ní ọjọ́ kan náà ènìyàn Ọlọ́run sì fún wọn ní àmì kan wí pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa ti kéde: kíyèsi i, pẹpẹ náà yóò ya, eérú tí ń bẹ lórí rẹ̀ yóò sì dànù.”
4 A gdy usłyszał król Jeroboam słowo męża Bożego, które obwoływał przeciw ołtarzowi w Betel, ściągnął rękę swą od ołtarza, mówiąc: Pojmajcie go. I uschła ręka jego, którą był wyciągnął przeciw niemu, a niemógł jej przyciągnąć do siebie.
Nígbà tí Jeroboamu ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run, tí ó kígbe sí pẹpẹ náà ní Beteli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde nínú pẹpẹ, ó sì wí pé, “Ẹ mú un!” ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ tí ó nà sí i sì kákò, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le fà á padà mọ́.
5 Ołtarz się też rozpadł, a wysypał się popiół z ołtarza według znaku, który był dał mąż Boży słowem Pańskiem.
Lẹ́sẹ̀kan náà, pẹpẹ ya, eérú náà sì dànù kúrò lórí pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bí àmì tí ènìyàn Ọlọ́run ti fi fún un nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
6 Przetoż odpowiadając król, rzekł do męża Bożego: Proszę cię, proś oblicza Pana Boga twego, a módl się za mną, aby się wróciła ręka moja do mnie. I modlił się mąż Boży obliczu Pańskiemu, i wróciła się ręka królewska do niego, i była jako pierwej.
Nígbà náà ní ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì gbàdúrà fún mi kí ọwọ́ mi lè padà bọ̀ sípò.” Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa, ọwọ́ ọba sì padà bọ̀ sípò, ó sì padà sí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀.
7 Tedy rzekł król do męża Bożego: Pójdź ze mną do domu, abyś się posilił, a dam ci upominek.
Ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Wá bá mi lọ ilé, kí o sì wá nǹkan jẹ, èmi yóò sì fi ẹ̀bùn fún ọ.”
8 Ale rzekł mąż Boży do króla: Byśmi dał połowę domu twego, nie pojadę z tobą, ani będę jadł chleba, ani będę pił wody na tem miejscu.
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run náà dá ọba lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá tilẹ̀ fún mi ní ìdajì ìní rẹ, èmi kì yóò lọ pẹ̀lú rẹ tàbí kí èmi jẹ oúnjẹ tàbí mu omi ní ibí yìí.
9 Bo mi tak Pan rozkazał słowem swojem, mówiąc: Nie będziesz jadł chleba, ani będziesz pił wody, ani się wrócisz tą drogą, którąś przyszedł.
Nítorí a ti pa á láṣẹ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi tàbí padà ní ọ̀nà náà tí o gbà wá.’”
10 Odszedł tedy inszą drogą, a nie wrócił się tą drogą, którą był przyszedł do Betel.
Bẹ́ẹ̀ ni ó gba ọ̀nà mìíràn, kò sì padà gba ọ̀nà tí ó gbà wá sí Beteli.
11 A prorok niejaki stary mieszkał w Betel, którego syn przyszedłszy, opowiedział mu wszystkę sprawę, którą był uczynił onegoż dnia mąż Boży w Betel, i słowa, które mówił do króla, opowiedzieli ojcu swemu.
Wòlíì àgbà kan wà tí ń gbé Beteli, ẹni tí àwọn ọmọ rẹ̀ dé, tí ó sì ròyìn gbogbo ohun tí ènìyàn Ọlọ́run náà ti ṣe ní Beteli ní ọjọ́ náà fún un. Wọ́n sì tún sọ fún baba wọn ohun tí ó sọ fún ọba.
12 I rzekł im ojciec ich: Którąż drogą poszedł? I pokazali synowie jego drogę, którą poszedł on mąż Boży, który był przyszedł z Judztwa.
Baba wọn sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ọ̀nà wo ni ó gbà?” Àwọn ọmọ rẹ̀ sì fi ọ̀nà tí ènìyàn Ọlọ́run láti Juda gbà hàn án.
13 Zatem rzekł synom swym: Osiodłajcie mi osła; i osiodłali mu osła, i wsiadł nań,
Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un tán, ó sì gùn ún.
14 I jechał za mężem Bożym, a znalazł go siedzącego pod dębem, i rzekł mu: Tyżeś jest on mąż Boży, któryś przyszedł z Judztwa? A on rzekł: Jestem.
Ó sì tẹ̀lé ènìyàn Ọlọ́run náà lẹ́yìn. Ó sì rí i tí ó jókòó lábẹ́ igi óákù kan, ó sì wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá bí?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Èmi ni.”
15 I rzekł do niego: Pójdź zemną do domu, żebyś jadł chleb.
Nígbà náà ni wòlíì náà sì wí fún un pé, “Bá mi lọ ilé, kí o sì jẹun.”
16 Ale mu on rzekł: Nie mogę się wrócić z tobą, ani iść z tobą, ani będę jadł chleba, ani będę pił wody z tobą na tem miejscu;
Ènìyàn Ọlọ́run náà sì wí pé, “Èmi kò le padà sẹ́yìn tàbí bá ọ lọ ilé, tàbí kí èmi kí ó jẹ oúnjẹ tàbí mu omi pẹ̀lú rẹ níhìn-ín.
17 Bo się stała do mnie mowa słowem Pańskiem: Nie będziesz tam jadł chleba, ani pił wody, ani się wrócisz idąc tą drogą, którąś szedł.
A ti sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi níhìn-ín tàbí kí o padà lọ nípa ọ̀nà tí ìwọ bá wá.’”
18 Któremu on odpowiedział: I jam prorok jako i ty; Anioł też rzekł do mnie słowem Pańskiem, mówiąc: Wróć go z sobą do domu twego, aby jadł chleb, i pił wodę. I tak skłamał przed nim.
Wòlíì àgbà náà sì wí fún un pé, “Wòlíì ni èmi náà pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìwọ. Angẹli sì sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Mú un padà wá sí ilé rẹ, kí ó lè jẹ oúnjẹ àti kí ó lè mu omi.’” (Ṣùgbọ́n ó purọ́ fún un ni.)
19 I wrócił się z nim, a jadł chleb w domu jego, i pił wodę.
Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà sì padà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì jẹ oúnjẹ ó sì mu omi ní ilé rẹ̀.
20 A gdy siedzieli u stołu, stało się słowo Pańskie do proroka, który go był wrócił;
Bí wọ́n sì ti jókòó ti tábìlì, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ wòlíì tí ó mú un padà wá pé;
21 I zawołał na męża Bożego, który był przyszedł z Judztwa, mówiąc: Tak mówi Pan: Przeto żeś był odpornym ustom Pańskim, a nie strzegłeś rozkazania, któreć przykazał Pan, Bóg twój:
Ó sì kígbe sí ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́, ìwọ kò sì pa àṣẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́.
22 Aleś się wrócił, i jadłeś chleb, a piłeś wodę na miejscu, o któremem ci był rzekł: Nie będziesz tam jadł chleba, ani pił wody: nie będzie pochowany trup twój w grobie ojców twoich.
Ìwọ padà, ìwọ sì ti jẹ oúnjẹ, ìwọ sì ti mu omi níbi tí ó ti sọ fún ọ pé kí ìwọ kí ó má ṣe jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Nítorí náà, a kì yóò sin òkú rẹ sínú ibojì àwọn baba rẹ.’”
23 A tak gdy się najadł chleba i napił się, osiodłał osła prorokowi onemu, którego był wrócił.
Nígbà tí ènìyàn Ọlọ́run sì ti jẹun tán àti mu omi tan, wòlíì tí ó ti mú u padà sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un.
24 A gdy odjechał, spotkał go lew w drodze, i zabił go. A trup jego był porzucony w drodze, a osieł stał wedle niego, lew także stał podle trupa.
Bí ó sì ti ń lọ ní ọ̀nà rẹ̀, kìnnìún kan pàdé rẹ̀ ní ọ̀nà, ó sì pa á, a sì gbé òkú rẹ̀ sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró tì í lẹ́gbẹ̀ẹ́.
25 A oto mężowie mimo idący ujrzeli trupa porzuconego na drodze i lwa stojącego podle niego: którzy przyszedłszy powiedzieli to w mieście, w którem on stary prorok mieszkał.
Àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá sì rí pé ó gbé òkú náà sọ sí ojú ọ̀nà, kìnnìún náà sì dúró ti òkú náà; wọ́n sì wá, wọ́n sì sọ ọ́ ní ìlú tí wòlíì àgbà náà ń gbé.
26 Co gdy usłyszał on prorok, który go był wrócił z drogi, rzekł: Mąż Boży jest, który był odpornym ustom Pańskim; przetoż podał go Pan lwowi, który go potarł, i zabił go według słowa Pańskiego, które mu był powiedział.
Nígbà tí wòlíì tí ó mú un padà wá láti ọ̀nà rẹ̀ sì gbọ́ èyí, ó sì wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run náà ni tí ó ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́. Olúwa sì ti fi lé kìnnìún lọ́wọ́, tí ó sì fà á ya, tí ó sì pa á, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti kìlọ̀ fún un.”
27 Nadto rzekł do synów swoich, mówiąc: Osiodłajcie mi osła. I osiodłali.
Wòlíì náà sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi,” wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
28 A wyjechawszy znalazł trupa jego porzuconego na drodze, a osła i lwa stojące przy trupie, ale nie jadł lew onego trupa, ani obraził osła.
Nígbà náà ni ó sì jáde lọ, ó sì rí òkú náà tí a gbé sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Kìnnìún náà kò sì jẹ òkú náà, tàbí fa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà ya.
29 Tedy wziął prorok trupa męża Bożego, a włożywszy go na osła, przywiózł go; i przyszedł do miasta swego, aby płakał i pogrzebł go.
Nígbà náà ni wòlíì náà gbé òkú ènìyàn Ọlọ́run náà, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì gbé e padà wá sí ìlú ara rẹ̀ láti ṣọ̀fọ̀ fún un àti láti sin ín.
30 A położył trupa jego w grobie swoim, i płakali go, mówiąc: Ach bracie mój!
Nígbà náà ni ó gbé òkú náà sínú ibojì ara rẹ̀, wọ́n sì ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ó ṣe, arákùnrin mi!”
31 A pochowawszy go, rzekł do synów swoich: Gdy ja umrę. pochowajcie mię w tym grobie, w którym jest mąż Boży pochowany; podle kości jego połóżcie kości moje,
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú rẹ̀ tán, ó sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Nígbà tí mo bá kú, ẹ sin mí ní ibojì níbi tí a sin ènìyàn Ọlọ́run sí; ẹ tẹ́ egungun mi lẹ́bàá egungun rẹ̀.
32 Bo zapewne się to stanie, co obwołał słowem Pańskiem, przeciw ołtarzowi, który jest w Betel, i przeciwko wszystkim domom wyżyn, które są w mieściech Samaryjskich.
Nítorí iṣẹ́ tí ó jẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Olúwa sí pẹpẹ tí ó wà ní Beteli àti sí gbogbo ojúbọ lórí ibi gíga tí ń bẹ ní àwọn ìlú Samaria yóò wá sí ìmúṣẹ dájúdájú.”
33 To gdy się stało, przecież się nie odwrócił Jeroboam od drogi swej złej, ale znowu naczynił z pospolitego ludu kapłanów wyżyn; kto jedno chciał, poświęcał rękę jego, aby był kapłanem wyżyn.
Lẹ́yìn nǹkan yìí, Jeroboamu kò padà kúrò nínú ọ̀nà búburú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún yan àwọn àlùfáà sí i fún àwọn ibi gíga nínú gbogbo àwọn ènìyàn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di àlùfáà, a yà á sọ́tọ̀ fún ibi gíga wọ̀nyí.
34 I była ta rzecz domowi Jeroboamowemu przyczyną do grzechu, aby był wykorzeniony i wygładzony z ziemi.
Èyí sì ni ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó yọrí sí ìṣubú rẹ̀, a sì pa á run kúrò lórí ilẹ̀.