< I Królewska 1 >

1 A gdy się król Dawid zstarzał, i zaszedł w lata, chodź go odziewano szatami, przecię się zagrzać nie mógł.
Nígbà tí Dafidi ọba di arúgbó, ọjọ́ rẹ̀ sì pọ̀, ara rẹ̀ kò le è móoru bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n da ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ bò ó.
2 I rzekli mu słudzy jego: Niech poszukają królowi, panu naszemu młodej panienki, któraby stawała przed królem, i opatrowała go, a sypiając na łonie jego, żeby zagrzewała króla, pana naszego.
Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí fún un pé, “Ẹ jẹ́ kí a wá ọ̀dọ́mọbìnrin wúńdíá kan kí ó dúró ti ọba, kì ó sì máa tọ́jú rẹ̀. Kí ó dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀ kí ara ọba olúwa wa lè móoru.”
3 Szukali tedy panienki pięknej po wszystkich granicach Izraelskich, i znaleźli Abisag Sunamitkę, a przywiedli ją do króla.
Nígbà náà ni wọ́n lọ jákèjádò ilẹ̀ Israẹli láti wá ọ̀dọ́mọbìnrin arẹwà, wọ́n sì rí Abiṣagi, ará Ṣunemu, wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ ọba.
4 A ta panienka była bardzo piękna, i opatrowała króla, i służyła mu; ale jej król nie uznał.
Ọmọbìnrin náà rẹwà gidigidi; ó sì ń ṣe ìtọ́jú ọba, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n ọba kò sì bá a lòpọ̀.
5 Lecz Adonijasz, syn Haggity, wynosił się, mówiąc: Ja będę królował. I nasprawiał sobie wozów i jezdnych, i pięćdziesiąt mężów, którzy biegali przed nim.
Adonijah ẹni tí ìyá rẹ̀ ń ṣe Haggiti sì gbé ara rẹ̀ ga, ó sì wí pé, “Èmi yóò jẹ ọba.” Ó sì ṣètò kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin, pẹ̀lú àádọ́ta ọkùnrin láti máa sáré níwájú rẹ̀.
6 A nie gromił go nigdy ojciec jego, mówiąc: Przeczżeś to uczynił? A był i ten bardzo pięknej urody, którego była porodziła Haggita po Absalomie.
(Baba rẹ̀ kò bà á nínú jẹ́ rí nípa bíbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi hùwà báyìí?” Ó sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin, òun ni a bí lé Absalomu.)
7 A miał zmowę z Joabem, synem Sarwii, i z Abijatarem kapłanem, którzy pomagali za Adonijaszem.
Adonijah sì gbèrò pẹ̀lú Joabu, ọmọ Seruiah àti Abiatari àlùfáà, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
8 Ale Sadok kapłan, i Banajas, syn Jojady, i Natan prorok, i Semej, i Rehy i rycerstwo Dawidowe, nie przestawali z Adonijaszem.
Ṣùgbọ́n Sadoku àlùfáà, Benaiah ọmọ Jehoiada, Natani wòlíì, Ṣimei àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Rei àti olórí ogun Dafidi ni kò darapọ̀ mọ́ Adonijah.
9 Tedy nabił Adonijasz owiec, i wołów, i bydła tłustego u kamienia Zohelet, który był nad źródłem Rogiel, i wezwał wszystkich braci swych, synów królewskich, i wszystkich mężów z Juda, sług królewskich.
Nígbà náà ni Adonijah fi àgùntàn àti màlúù àti ẹran ọ̀sìn tí ó sanra rú ẹbọ níbi Òkúta Soheleti tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ En-Rogeli. Ó sì pe gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ ọba.
10 Ale Natana proroka, i Banajasa, i innego rycerstwa, ani Salomona, brata swego, nie wezwał.
Ṣùgbọ́n kò pe Natani wòlíì tàbí Benaiah tàbí àwọn olórí tàbí Solomoni arákùnrin rẹ̀.
11 Tedy rzekł Natan do Betsaby, matki Salomonowej, mówiąc: A nie słyszałaś, iż króluje Adonijasz, syn Haggity, a Dawid, pan nasz, nie wie o tem?
Nígbà náà ni Natani béèrè lọ́wọ́ Batṣeba, ìyá Solomoni pé, “Ǹjẹ́ ìwọ kò gbọ́ pé Adonijah, ọmọ Haggiti ti jẹ ọba láìjẹ́ pé Dafidi olúwa wa mọ̀ sí i?
12 Przetoż teraz pójdź proszę, dam ci radę, a zachowasz zdrowie twoje i zdrowie syna twego Salomona.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, jẹ́ kí èmi gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn bí ìwọ ṣe lè gba ẹ̀mí rẹ là àti ẹ̀mí ọmọ rẹ Solomoni.
13 Idź, a wnijdź do króla Dawida, i mów do niego: Izaliś ty królu, panie mój, nieprzysiągł służebnicy twojej, mówiąc: Salomon, syn twój, będzie królował po mnie, a on będzie siedział na stolicy mojej? Przeczże tedy króluje Adonijasz?
Lọ sọ́dọ̀ Dafidi ọba, kí o sì wí fún un pé, ‘Olúwa mi ọba, ǹjẹ́ ìwọ kò búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, “Dájúdájú Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi?” Èéṣe nígbà náà tí Adonijah fi jẹ ọba?’
14 A gdy ty jeszcze tam będziesz mówiła z królem, ja przyjdę za tobą, i dopełnię słów twoich.
Níwọ́n ìgbà tí ìwọ sì wà níbẹ̀, tí o sì ń bá ọba sọ̀rọ̀ èmi yóò wá, láti wádìí ohun tí o ti sọ.”
15 A tak weszła Betsaba do króla na pokój; a król się już był bardzo zstarzał, a Abisag Sunamitka posługowała królowi.
Bẹ́ẹ̀ ni Batṣeba lọ rí ọba ní inú yàrá rẹ̀, ọba sì gbó gidigidi níbi tí Abiṣagi ará Ṣunemu ti ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba.
16 Tedy nachyliwszy się Betsaba, pokłoniła się królowi, której rzekł król: Czego chcesz?
Batṣeba sì tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba. Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”
17 A ona mu odpowiedziała: Panie mój, tyś przysiągł przez Pana, Boga twego, służebnicy twojej, że Salomon, syn twój, będzie królował po mnie, a on będzie siedział na stolicy mojej.
Ó sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi; ìwọ fúnra rẹ̀ fi Olúwa Ọlọ́run rẹ búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, ‘Solomoni ọmọ rẹ yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi.’
18 A oto, już Adonijasz króluje, a ty teraz, królu, panie mój, o tem nie wiesz.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Adonijah ti di ọba, ìwọ, ọba olúwa mi kò sì mọ̀ nípa rẹ̀.
19 Albowiem nabił wołów i bydła tłustego, i owiec bardzo wiele, i wezwał wszystkich synów królewskich, i Abijatara kapłana, i Joaba, hetmana wojska; ale Salomona, sługi twego, nie wezwał.
Òun sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran tí ó ní ọ̀rá, àti àgùntàn rú ẹbọ, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, àti Abiatari àlùfáà àti Joabu balógun, ṣùgbọ́n kò sì pe Solomoni ìránṣẹ́ rẹ.
20 Lecz ty królu, panie mój, wiesz, iż się oczy wszystkiego Izraela oglądają na cię, abyś im oznajmił, kto będzie siedział na stolicy króla, pana mego, po tobie.
Olúwa mi ọba, ojú gbogbo Israẹli ń bẹ lára rẹ, láti mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ.
21 Inaczej stanie się, gdy zaśnie król, pan mój, z ojcy swymi, że będziemy ja i Salomon, syn mój, jako grzesznicy.
Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí olúwa mi ọba bá sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, wọn yóò sì ka èmi àti Solomoni sí ẹlẹ́ṣẹ̀.”
22 A oto, gdy ona jeszcze mówiła z królem, przyszedł Natan prorok.
Bí ó sì ti ń bá ọba sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Natani wòlíì sì wọlé.
23 I opowiedziano to królowi, mówiąc: Oto Natan, prorok; który wszedłszy do króla, pokłonił się królowi twarzą swą ku ziemi.
Wọ́n sì sọ fún ọba pé, “Natani wòlíì wà níbí.” Ó sì lọ síwájú ọba, ó wólẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀.
24 Rzekł zatem Natan: Królu, panie mój, zażeś ty rzekł: Adonijasz będzie królował po mnie, a on usiędzie na stolicy mojej?
Natani sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ, olúwa mi ọba, ti sọ pé Adonijah ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn rẹ àti pé òun ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ?
25 Albowiem dziś szedłszy nabił wołów i bydła tłustego, i owiec bardzo wiele, i wezwał wszystkich synów królewskich, i hetmanów wojsk, i Abijatara kapłana, a oto oni jedzą z nim i piją, i mówią: Niech żyje król Adonijasz!
Ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ ní òní, ó sì ti rú ẹbọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran ọlọ́ràá àti àgùntàn. Ó sì ti pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, balógun àti Abiatari àlùfáà. Nísìnsinyìí, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Kí Adonijah ọba kí ó pẹ́!’
26 Ale mnie, sługi twego, i Sadoka kapłana, i Banajasa, syna Jojadowego, i Salomona, sługi twego, nie wezwał.
Ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́ rẹ, àti Sadoku àlùfáà, àti Benaiah ọmọ Jehoiada, àti Solomoni ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè.
27 Izali od króla, pana mego, stała się ta rzecz? a nie oznajmiłeś słudze twemu, kto ma siedzieć na stolicy króla, pana mego, po nim?
Ṣé nǹkan yìí ni olúwa mi ọba ti ṣe láìjẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ?”
28 I odpowiedział król Dawid, mówiąc: Zawołajcie do mnie Betsaby; która przyszedłszy przed obliczność królewską, stanęła przed królem.
Nígbà náà ni Dafidi ọba wí pé, “Pe Batṣeba wọlé wá.” Ó sì wá síwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
29 Tedy przysiągł król, mówiąc: Jako żywy Pan, który wybawił duszę moję z każdego ucisku:
Ọba sì búra pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbà mí kúrò nínú gbogbo wàhálà
30 Iż jakom ci przysiągł przez Pana, Boga Izraelskiego, mówiąc: Że Salomon, syn twój, królować będzie po mnie, a on usiędzie na stolicy mojej miasto mnie, tak dziś uczynię.
Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Israẹli búra fún yọ pé, Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”
31 I nachyliwszy się Betsaba twarzą ku ziemi, ukłoniła się królowi, i rzekła: Niech żyje Dawid król, pan mój, na wieki!
Nígbà náà ni Batṣeba tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí olúwa mi Dafidi ọba kí ó pẹ́!”
32 Zatem rzekł król Dawid: Zawołajcie do mnie Sadoka kapłana, i Natana proroka, i Banajasa, syna Jojadowego. I weszli do króla.
Dafidi ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadoku àlùfáà wọlé fún mi àti Natani wòlíì àti Benaiah ọmọ Jehoiada.” Nígbà tí wọ́n wá síwájú ọba,
33 I rzekł im król: Weźmijcie z sobą sługi pana waszego, a wsadźcie Salomona, syna mego, na mulicę moję, i prowadźcie go do Gihonu.
ọba sì wí fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Solomoni ọmọ mi kí ó gun ìbáaka mi, kí ẹ sì mú un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gihoni.
34 A tam go pomaże Sadok kapłan, i Natan prorok za króla nad Izraelem; potem zatrąbicie w trąbę, a rzeczecie: Niech żyje król Salomon!
Níbẹ̀ ni Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì yóò ti fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!’
35 Potem pójdziecie za nim; a on przyszedłszy, siądzie na stolicy mojej, i będzie królował miasto mnie; bom mu ja rozkazał, aby był wodzem nad Izraelem i nad Judą.
Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jẹ ọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Israẹli àti Juda.”
36 I odpowiedział Banajas, syn Jojada, królowi, mówiąc: Amen. Niech to stwierdzi Pan, Bóg króla, pana mego.
Benaiah ọmọ Jehoiada sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀.
37 Jako był Pan z królem, panem moim, tak niech będzie z Salomonem, a niechaj wywyższy stolicę jego nad stolicę Dawida króla, pana mego.
Bí Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Solomoni kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ olúwa mi Dafidi ọba lọ!”
38 A tak szedł Sadok kapłan, i Natan prorok, i Banajas, syn Jojada, przytem Cheretczycy, i Feletczycy, i wsadzili Salomona na mulicę króla Dawida, a prowadzili go do Gihonu.
Nígbà náà ni Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada, àwọn ará Kereti àti Peleti sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Solomoni gun ìbáaka Dafidi ọba wá sí Gihoni.
39 Tedy wziął Sadok kapłan róg olejku z namiotu, i pomazał Salomona. Potem trąbili w trąbę, i zakrzyknął wszystek lud: Niech żyje król Salomon!
Sadoku àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Solomoni lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!”
40 I szedł wszystek lud za nim. Tenże lud grał na piszczałkach, weseląc się weselem wielkiem, tak iż drżała ziemia od głosu ich.
Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.
41 Co gdy usłyszał Adonijasz, i wszyscy wezwani, którzy byli z nim, (a już się też była dokończyła uczta, ) słysząc też i Joab głos trąby, rzekł: Cóż to za krzyk miasta huczącego?
Adonijah àti gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ìpè, Joabu sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”
42 A gdy on tego domawiał, oto Jonatan, syn Abijatara kapłana, przyszedł. Któremu rzekł Adonijasz: Wnijdź; boś ty mąż stateczny, a powiesz nam co dobrego.
Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani ọmọ Abiatari àlùfáà sì dé, Adonijah sì wí pé, “Wọlé wá, ọkùnrin yíyẹ ìwọ gbọdọ̀ mú ìròyìn rere wá.”
43 Tedy odpowiedział Jonatan, i rzekł Adonijaszowi: Dawid król, pan nasz, postanowił zapewne Salomona królem.
Jonatani sì dáhùn, ó sì wí fún Adonijah pé, “Lóòótọ́ ni olúwa wa Dafidi ọba, fi Solomoni jẹ ọba.
44 Albowiem posłał z nim król Sadoka kapłana, i Natana proroka, i Banajasa, syna Jojadowego, do tego Cheretczyki i Feletczyki, którzy go wsadzili na mulicę królewską;
Ọba sì ti rán Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada àti àwọn ará Kereti àti Peleti pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì ti gbé e gun ìbáaka ọba,
45 I pomazali go Sadok kapłan, i Natan prorok za króla w Gihonie, i szli stamtąd weseląc się, tak, że zadrżało miasto; tenci jest krzyk, któryście słyszeli;
Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gihoni. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, ìlú sì ń hó pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni ariwo tí ẹ̀yin ń gbọ́.
46 I już usiadł Salomon na stolicy królestwa.
Solomoni sì ti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀.
47 Nadto i słudzy królewscy przyszli, aby błogosławili Dawidowi królowi, panu naszemu, mówiąc: Niech sławniejsze uczyni Bóg imię Salomonowe nad imię twoje, a niech wywyższy stolicę jego nad stolicę twoję. I pokłonił się król na łożu swem.
Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì ti tún wá láti bá olúwa wa Dafidi ọba yọ̀, wí pé, ‘Kí Ọlọ́run rẹ̀ mú orúkọ Solomoni lókìkí ju tirẹ̀ lọ àti kí ìtẹ́ rẹ̀ kí ó pọ̀ ju tirẹ̀ lọ!’ Ọba sì tẹ ara rẹ̀ ba lórí ibùsùn rẹ̀,
48 Przytem tak rzekł król: Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, który dał dziś siedzącego na stolicy mojej, na co patrzą oczy moje.
ọba sì wí pé, ‘Ògo ni fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti jẹ́ kí ojú mi rí ẹnìkan tí ó jókòó lórí ìtẹ́ mi lónìí.’”
49 Zlękli się tedy, i wstali wszyscy wezwani, którzy byli z Adonijaszem, i poszli każdy w drogę swą.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ Adonijah dìde ní ìdágìrì, wọ́n sì túká.
50 Adonijasz także, bojąc się Salomona, wstał, i poszedł, a uchwycił się rogów ołtarza.
Ṣùgbọ́n Adonijah sì bẹ̀rù Solomoni, ó lọ, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
51 I oznajmiono Salomonowi, mówiąc: Oto Adonijasz boi się króla Salomona, a oto uchwycił się rogów ołtarza, mówiąc: Niech mi dziś przysięże król Salomon, że nie zabije sługi swego mieczem.
Nígbà náà ni a sì sọ fún Solomoni pé, “Adonijah bẹ̀rù Solomoni ọba, ó sì di ìwo pẹpẹ mú, Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí ọba Solomoni búra fún mi lónìí pé, òun kì yóò fi idà pa ìránṣẹ́ rẹ̀.’”
52 Tedy rzekł Salomon: Jeźli będzie mężem statecznym, nie spadnie i włos z niego na ziemię; ale jeźli się w nim znajdzie co złego, pewnie umrze.
Solomoni sì dáhùn pé, “Bí ó bá fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ ẹni ọ̀wọ̀, irun orí rẹ̀ kan kì yóò sì bọ́ sílẹ̀; ṣùgbọ́n bí a bá rí búburú kan ní ọwọ́ rẹ̀ òun yóò kú.”
53 A tak posłał król Salomon, i przywiedziono go od ołtarza; a gdy przyszedł, ukłonił się królowi Salomonowi, i rzekł mu Salomon: Idź do domu twego.
Nígbà náà ni Solomoni ọba rán àwọn ènìyàn, wọ́n sì mú un sọ̀kalẹ̀ láti ibi pẹpẹ wá. Adonijah sì wá, ó sì foríbalẹ̀ fún Solomoni ọba, Solomoni sì wí pé, “Lọ ilé rẹ.”

< I Królewska 1 >